< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
І було мені слово Господнє таке:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
„Сину лю́дський, зверни́ своє обличчя до Аммо́нових синів, і пророкуй на них.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
І скажеш Аммо́новим синам: Послухайте слова Господа Бога: Так говорить Господь Бог: За те, що ти говориш „Ага!“про Мою святиню, бо вона збезче́щена, і про Ізраїлеву землю, бо спусто́шена, і про Юдин дім, бо пішов у поло́н,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
тому́ ось Я дам тебе синам сходу на спа́док, і поставлять вони в тебе ша́тра свої, і зроблять у тебе місця́ свого пробува́ння. Вони будуть їсти твій плід, і вони будуть пити твоє молоко.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
І дам я Раббу на ста́йню для верблю́дів, а Аммонових синів на лі́гво отари, і ви пізнаєте, що Я — Госпо́дь!
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Бо так Господь Бог промовляє: За твоє пле́скання рукою, і твоє тупотіння ногою, і що в душі ті́шишся ти всією своєю пого́рдою до Ізраілевої землі,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
тому́ ось Я витягну Свою руку на тебе, і дам тебе на здо́бич для наро́дів, і витну тебе з наро́дів, і ви́гублю тебе з краї́в, знищу тебе, і пізнаєш, що Я — Госпо́дь!
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Так сказав Господь Бог: За те, що Моа́в та Сеїр говорять: „Ось Юдин дім — як усі наро́ди“,
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
тому ось Я відкрию Моа́вове узбіччя від міст, від його міст, від його кінця́, пишно́ту землі: Бен-Гаєшімот, Баал-Меон аж до Кір'ятаїму.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Я дам його на спа́док для синів сходу ра́зом з синами Аммо́новими, щоб не згадувались Аммонові сини серед наро́дів.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
А над Моавом зроблю́ при́суди, і пізнають вони, що Я — Госпо́дь!
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Так говорить Господь Бог: За те, що Едо́м мстився мстою над Юдиним домом, і тяжко гріши́ли, через те, що мсти́лися над ними,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
тому так говорить Господь Бог: І витягну Я руку Свою на Едо́ма, і витну з нього люди́ну й скоти́ну, і вчиню́ його руїною, — від Теману й аж до Дедану вони попа́дають від меча!
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
І дам Я Свою по́мсту над Едомом у руку Мого народу Ізраїля, і вчиню́ в Едомі за гнівом Своїм, за лютістю Своєю, і зазнають вони Моєї по́мсти, говорить Господь Бог!
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Так говорить Господь Бог: За те, що филисти́мляни чинили в по́мсті, і мстилися мстою через пого́рду в душі, щоб нищити в вічній не́нависті,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
тому так говорить Господь Вог: Ось Я витягну Свою руку на филисти́млян, і витну кере́тян, і вигублю останок морського берега,
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
і вчиню́ над ними жорсто́кі помсти лютими ка́рами. І пізнають вони, що Я — Господь, коли Я вчиню Свою помсту серед них!“

< Ezekiel 25 >