< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
RAB bana şöyle seslendi:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
“İnsanoğlu, yüzünü Ammonlular'a çevir, onlara karşı peygamberlik et.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Onlara de ki, ‘Egemen RAB'bin sözünü dinleyin! Egemen RAB şöyle diyor: Madem tapınağım kirletildiği, İsrail ülkesi viraneye çevrildiği, Yahuda halkı sürgüne gittiği zaman, Hah, hah! diyerek alay ettiniz,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
ben de sizi miras olarak doğuda yaşayan halka teslim edeceğim. Obalarını, çadırlarını ülkenizde kuracaklar; ürününüzü yiyecek, sütünüzü içecekler.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Rabba Kenti'ni develer için otlak, Ammon ülkesini sürüler için ağıl yapacağım. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaksınız.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Egemen RAB şöyle diyor: Madem İsrail'le alay ederek ellerinizi çırptınız, ayaklarınızı yere vurdunuz, bütün yüreğinizle sevindiniz,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
ben de size karşı elimi uzatacak, çapul malı olarak sizi uluslara teslim edeceğim. Sizi halklar arasından süpürüp atacak, ülkeler arasından söküp çıkaracak, yok edeceğim. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaksınız.’”
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
“Egemen RAB şöyle diyor: ‘Madem Moav ve Seir halkı, Bakın, Yahuda halkının öteki uluslardan farkı yok, dedi,
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
ben de Moav'ın sınırını, ülkenin süsü olan sınır kentlerini, Beytyeşimot, Baal-Meon ve Kiryatayim'i savunmasız bırakacağım.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Ammonlular uluslar arasında bir daha anılmasın diye Moav'ı Ammonlular'la birlikte mülk olarak doğuda yaşayan halka vereceğim.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Böylece Moav'ı cezalandıracağım. O zaman benim RAB olduğumu anlayacaklar.’”
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
“Egemen RAB şöyle diyor: ‘Madem Edom Yahuda halkından öç alarak büyük suç işledi,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
Egemen RAB şöyle diyor: Ben de Edom'a karşı elimi uzatacak, insanları da hayvanları da yok edecek, ülkeyi viraneye çevireceğim. Teman'dan Dedan'a kadar Edomlular kılıçla vurulup yok olacaklar.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Halkım İsrail aracılığıyla Edom'dan öç alacağım. İsrailliler onlara öfkem, kızgınlığım uyarınca davranacak. Böylece Edomlular öcümü anlayacaklar. Egemen RAB böyle diyor.’”
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
“Egemen RAB şöyle diyor: ‘Madem Filistliler Yahuda'ya acımasızca davrandılar, eskiden var olan düşmanlıklarıyla onu yerle bir ederek öç aldılar,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
Egemen RAB şöyle diyor: Elimi Filistliler'e karşı uzatacağım, Keretliler'i söküp atacağım, kıyıda yaşayanlardan sağ kalanlarını yok edeceğim.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
Onlardan ağır bir öç alacak, onları öfkeyle paylayacağım. Kendilerinden öç alınca, benim RAB olduğumu anlayacaklar.’”

< Ezekiel 25 >