< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
És lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Embernek fia! vesd tekintetedet Ammon fiaira, és prófétálj ellenök.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
És mondjad Ammon fiainak: Halljátok az Úr Isten beszédét! így szól az Úr Isten: Mivelhogy ezt mondod: Haha! az én szenthelyemre, hogy megfertéztetett; és Izráel földjére, hogy elpusztíttatott; és Júda házára, hogy fogságba mentek:
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
Ezokáért ímé adlak téged Kelet fiainak örökségül, hogy felüssék sátraikat benned, s felállassák benned lakóhelyeiket, ők eszik meg gyümölcsödet, s ők iszszák meg tejedet.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
És teszem Rabbát tevék legelőjévé, és Ammon fiait nyájak fekvőhelyévé, s megtudjátok, hogy én vagyok az Úr!
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Mert így szól az Úr Isten: Mivelhogy tapsolsz kezeddel és tombolsz lábaddal és örülsz teljes megvetéssel lelkedben Izráel földje felett:
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Ennekokáért ímé kinyújtom kezemet reád, s adlak ragadományul a népeknek, és kiváglak a népségek közül, és elvesztlek a tartományok közül, eltöröllek, hogy megtudjad, hogy én vagyok az Úr.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Azt mondja az Úr Isten: Mivelhogy Moáb és Seir ezt mondta: Ímé, Júda háza is olyan, mint a többi népek:
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
Ezokáért ímé megnyitom Moáb oldalát a városok felől, az ő városai felől mindenfelől, az ország ékességét Beth-Hajesimóthot, Baál-Meont és Kirjátaim felé,
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Megnyitom Kelet fiainak, Ammon fiaival együtt adom örökségül, hogy emlékezetben se legyenek többé Ammon fiai a népek között;
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Moáb fölött is ítéletet tartok: hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Így szól az Úr Isten: Mivelhogy Edom kegyetlen bosszúállást cselekedett Júda házán, és vétkezve vétkezett, hogy bosszút állott rajta:
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
Azért, így szól az Úr Isten, kinyújtom az én kezemet Edomra, és kivágok belőle embert és barmot, és teszem őt pusztasággá Temántól fogva, és Dedánig fegyver miatt hulljanak el.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
És bosszúmat állom Edomon népemnek, Izráelnek keze által és cselekszenek Edommal az én búsulásom és haragom szerint, s megismerik bosszúállásomat, ezt mondja az Úr Isten.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Így szól az Úr Isten: Mivelhogy a Filiszteusok bosszúból cselekedtek s kegyetlen bosszút álltak lelkökben megvetéssel, hogy elveszessék Izráelt örök gyűlölséggel:
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
Ezokáért ezt mondja az Úr Isten: Ímé, én kinyújtom kezemet a Filiszteusokra, és kivágom a Keréteusokat, és elvesztem a tenger partján lakók maradékát;
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
És cselekszem rajtok nagy bosszúállásokat fenyítő haragomban, hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr, ha bosszúmat állom rajtok.

< Ezekiel 25 >