< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
“Mũrũ wa mũndũ, erekeria ũthiũ waku harĩ Aamoni, na ũmarathĩre ũhoro wa kũmookĩrĩra.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Meere atĩrĩ, ‘Iguai kiugo kĩa Mwathani Jehova. Ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga: Tondũ nĩmuoigire, “Aha!” Igũrũ rĩa harĩa-hakwa-haamũre hĩndĩ ĩrĩa haathaahirio, o na igũrũ rĩa bũrũri wa Isiraeli rĩrĩa wanangirwo, na ningĩ igũrũ rĩa andũ a Juda hĩndĩ ĩrĩa maatahirwo-rĩ,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
nĩ ũndũ ũcio nĩngũmũneana kũrĩ andũ a kũu irathĩro mũtuĩke kĩndũ kĩao. Nĩmagaaka kambĩ ciikaro ciao na mambe hema ciao, thĩinĩ wanyu; nĩmakaarĩa matunda manyu, na manyue iria rĩanyu.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Nĩngagarũra Raba gũtuĩke ũrĩithio wa ngamĩĩra, nakuo Amoni gũtuĩke gwa kwarahwo nĩ ngʼondu. Hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Nĩgũkorwo ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga: Tondũ inyuĩ nĩmũhũũrĩte hĩ na mũkaringithia makinya manyu thĩ, mũgĩkenagĩrĩra bũrũri wa Isiraeli mũrĩ na rũmena ruothe rwa ngoro cianyu,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
nĩ ũndũ ũcio nĩngamũtambũrũkĩria guoko gwakwa, ndĩmũũkĩrĩre na ndĩmũneane mũtahwo nĩ ndũrĩrĩ. Nĩngamweherania na ndũrĩrĩ, na ndĩmũniine mabũrũri-inĩ. Nĩngamwananga, na inyuĩ nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
“Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Tondũ Moabi na Seiru moigire atĩrĩ, “Ta rora, nyũmba ya Juda ĩtuĩkĩte o ta ndũrĩrĩ iria ingĩ ciothe,”
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
nĩ ũndũ ũcio nĩngaguũria rũbaru rwa Moabi, nyambĩrĩirie na matũũra makuo ma mĩhaka-inĩ, na nĩmo Bethi-Jeshimothu, na Baali-Meoni, na Kiriathaimu, na nĩmo monagwo marĩ riiri wa bũrũri ũcio.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Nĩnganeana Moabi hamwe na Aamoni moko-inĩ ma andũ a Irathĩro matuĩke indo ciao, nĩgeetha Aamoni acio matikanaririkanwo ndũrĩrĩ-inĩ;
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
na niĩ nĩngaherithia Moabi. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.’”
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
“Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: ‘Tondũ Edomu nĩerĩhĩirie harĩ nyũmba ya Juda na agĩtuĩka mũhĩtia mũno nĩ ũndũ wa gwĩka ũguo-rĩ,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
nĩ ũndũ ũcio Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Nĩngatambũrũkia guoko gwakwa njũkĩrĩre Edomu na njũrage andũ akuo na mahiũ mao. Nĩngakwananga, na kuuma Timani nginya Dedani, nĩmakooragwo na rũhiũ rwa njora.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Nĩngerĩhĩria harĩ Edomu na guoko kwa andũ akwa Isiraeli, nao nĩmageeka Edomu kũringana na marakara makwa na mangʼũrĩ makwa; nĩmakamenya kwĩrĩhĩria gwakwa, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.’”
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
“Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ; ‘Tondũ Afilisti nĩmekire maũndũ ma kwĩrĩhĩria, na makĩĩrĩhĩria marĩ na rũmena ngoro-inĩ ciao na marĩ na muku wa matukũ maingĩ magĩtua atĩ nĩmekwananga Juda,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
nĩ ũndũ ũcio Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Ngirie gũtambũrũkia guoko gwakwa njũkĩrĩre Afilisti, na nĩngeheria Akerethi na nyanange arĩa matigaire ndwere-inĩ cia iria.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
Nĩngerĩhĩria harĩo na rĩĩrĩhĩria inene na ndĩmaherithie ndĩ na mangʼũrĩ. Hĩndĩ ĩyo nĩmakamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, hĩndĩ ĩrĩa ngeerĩhĩria harĩo.’”

< Ezekiel 25 >