< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Fils d’un homme, tourne ta face contre les enfants d’Ammon, et tu prophétiseras sur eux.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Et tu diras aux fils d’Ammon: Ecoutez la parole du Seigneur Dieu: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: À cause que tu as dit: Très bien, très bien, au sujet de mon sanctuaire, parce qu’il a été souillé; et au sujet de la terre d’Israël, parce qu’elle a été désolée; et au sujet de la maison de Juda, parce qu’ils ont été emmenés en captivité;
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
À cause de cela, je te livrerai aux fils de l’Orient en héritage, et ils établiront les parcs de leurs troupeaux en toi, et ils dresseront en toi leurs tentes: ils mangeront eux-mêmes tes fruits, et ils boiront eux-mêmes ton lait.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Et je rendrai Rabbath la demeure des chameaux, et la terre des fils d’Ammon le refuge des troupeaux: et vous saurez que je suis le Seigneur.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Parce que voici ce que dit le Seigneur Dieu: À cause que tu as battu des mains et frappé du pied, et que tu t’es réjouie de tout ton cœur au sujet de la terre d’Israël:
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
À cause de cela, voilà que moi j’étendrai ma main sur toi, et je te livrerai en proie aux nations, et je te retrancherai du milieu des peuples, et je t’effacerai de la terre, et je te briserai, et tu sauras que je suis le Seigneur.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: À cause que Moab et Séïr ont dit: Voilà que comme toutes les nations est la maison de Juda;
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
À cause de cela, voilà que moi j’ouvrirai l’épaule de Moab, du côté des cités, de ses cités, dis-je, et du côté de ses confins j’ouvrirai les illustres cités, de la terre de Bethiésimoth, Béelméon et Cariathaïm,
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Aux fils de l’Orient avec les fils d’Ammon, et je la donnerai en héritage; afin qu’il n’y ait plus souvenir des fils d’Ammon parmi les nations.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Et dans Moab j’exercerai mes jugements; et ils sauront que je suis le Seigneur.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: À cause que l’Idumée a tiré vengeance pour se venger des fils de Juda, et qu’elle a péché grièvement, et qu’elle a désiré avec ardeur de se venger;
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: J’étendrai ma main sur l’Idumée, et j’en enlèverai les hommes et les bêtes, et je la rendrai déserte du côté du midi, et ceux qui sont à Dédan tomberont sous le glaive.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Et j’exercerai ma vengeance sur l’Idumée par la main de mon peuple Israël; et ils agiront en Edom selon ma colère et ma fureur: et ils sauront ma vengeance, dit le Seigneur Dieu.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Voici ce que dit le Seigneur Dieu: À cause que les Philistins ont tiré vengeance, et qu’ils se sont vengés de tout leur cœur, tuant et satisfaisant d’anciennes inimitiés,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi j’étendrai ma main sur les Philistins, et je tuerai ceux qui ont tué, et je perdrai les restes de la contrée maritime;
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
Et j’exercerai sur eux de grandes vengeances, les reprenant dans ma fureur, et ils sauront que je suis le Seigneur, lorsque j’aurai exercé ma vengeance sur eux.

< Ezekiel 25 >