< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Minulle tuli tämä Herran sana:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
"Ihmislapsi, käännä kasvosi ammonilaisia kohti ja ennusta heitä vastaan
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
ja sano ammonilaisille: Kuulkaa Herran, Herran sana: Näin sanoo Herra, Herra: Koska sinä sanoit: 'Kas niin!' minun pyhäköstäni, kun se häväistiin, ja Israelin maasta, kun se hävitettiin, ja Juudan heimosta, kun he menivät pakkosiirtolaisuuteen,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
sentähden, katso, minä annan sinut Idän miehille omaksi, ja he laittavat sinuun leiripaikkansa ja asettavat sinuun asuntonsa. He syövät sinun hedelmäsi ja juovat maitosi.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ja Rabban minä panen kamelien laitumeksi ja ammonilaisten maan lammaslaumojen leposijaksi. Ja te tulette tietämään, että minä olen Herra.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Sillä näin sanoo Herra, Herra: Koska sinä käsiä taputit ja jalkaa poljit ja, sielu täynnä ylenkatsetta, pidit iloa Israelin maasta,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
sentähden, katso, minä ojennan käteni sinua vastaan ja annan sinut pakanain ryöstettäväksi ja hävitän sinut kansojen joukosta ja hukutan sinut maitten luvusta ja tuhoan sinut. Ja sinä tulet tietämään, että minä olen Herra.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Näin sanoo Herra, Herra: Koska Mooab ja Seir ovat sanoneet: 'Katso, Juudan heimon käy samoin kuin kaikkien muitten kansain',
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
sentähden, katso, minä teen avonaiseksi Mooabin vuoriselänteen, paljaaksi kaupungeista-kaupungeista sen rajasta toiseen-jotka ovat maan kaunistus: Beet-Jesimot, Baal-Meon ja Kirjataim.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Idän miehille omaksi minä annan sen ynnä ammonilaiset, niin ettei ammonilaisia enää muisteta kansojen seassa,
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
ja Mooabissa minä panen toimeen tuomiot. Ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Näin sanoo Herra, Herra: Koska Edom menetteli kovin kostonhimoisesti Juudan heimoa kohtaan ja tuli suuresti syynalaiseksi, kostaessansa heille,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Minä ojennan käteni Edomia vastaan ja hävitän siitä ihmiset ja eläimet. Teemanista lähtien minä panen sen raunioiksi, ja Dedania myöten he kaatuvat miekkaan.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ja kostoni, joka Edomia kohtaa, minä annan kansani Israelin käteen, ja he tekevät Edomia kohtaan minun vihani ja kiivauteni mukaan. Ja Edom saa tuntea minun kostoni, sanoo Herra, Herra.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Näin sanoo Herra, Herra: Koska filistealaiset menettelivät kostonhimoisesti ja, ylenkatse sielussaan, kostivat kovasti, ikivihassa tuottaaksensa tuhon,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Katso, minä ojennan käteni filistealaisia vastaan, hävitän kreetit, hukutan, mitä on jäljellä meren rannikolla,
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
ja teen heille suuret kostoteot, rangaisten kiivaudessa. Ja he tulevat tietämään, että minä olen Herra, kun minä annan kostoni heitä kohdata."

< Ezekiel 25 >