< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Sinä, ihmisen poika, aseta kasvos Ammonin lasten puoleen, ja ennusta heitä vastaan,
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Ja sano Ammonin lapsille: kuulkaat Herran, Herran sanaa: näin sanoo Herra, Herra: että te minun pyhääni pitititte, sanoen: jopa se saastutettu on, ja Israelin maata: se on kylmillä, ja Juudan huonetta, että se on vankina viety pois;
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
Sentähden katso, minä tahdon sinun antaa itäisen maan lapsille perinnöksi, että heidän linnojansa sinne rakentaman ja asuinsiansa sinne tekemän pitää; ja heidän pitää sinun hedelmäs syömän, ja sinun rieskas juoman.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Ja tahdon Rabban kamelein huoneeksi tehdä, ja Ammonin lapset lammaspihatoksi; ja teidän pitää tietämän, että minä olen Herra.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Sillä näin sanoo Herra, Herra: että sinä käsiäs paukutit, ja tömistelit jaloillas, ja Israelin maasta kaikesta sydämestäs niin äikistellen iloitsit,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Sentähden katso, minä tahdon minun käteni ojentaa sinun ylitses, ja antaa sinun pakanoille ryöstöksi, ja hävittää sinun kansoista, ja maakunnista surmata; minä kadotan sinun, ja sinun pitää tietämän, että minä olen Herra.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Näin sanoo Herra, Herra: että Moab ja Seir sanovat: katso, Juudan huone on niinkuin kaikki muutkin pakanat;
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
Sentähden katso, niin minä tahdon Moabin kyljen avata kaupungeista, hänen kaupungeistansa ja hänen rajoistansa: sen kalliin maan, Betjesimotin, Baalmeonin ja Kirjataimin,
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Itäisen maan lapsille, Ammonin lapsia vastaan, ja annan heidät heille perinnöksi, ettei Ammonin lapsia enää muistettaman pidä pakanain seassa;
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Ja annan tuomita Moabin: ja heidän pitää tietämän minun olevan Herran.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Näin sanoo Herra, Herra: että Edom Juudan huoneelle ankarasti kostanut on, ja kostamisellansa itsensä vikapääksi saattanut;
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
Sentähden sanoo Herra, Herra näin: minä tahdon käteni ojentaa Edomin päälle, ja tahdon hänestä hävittää sekä ihmiset että eläimet, ja tahdon sen autioksi tehdä Temanista, ja Dedaniin asti pitää heidän miekalla kaatuman.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ja kostan jälleen Edomille minun kansani Israelin kautta, ja heidän pitää Edomin kanssa tekemän minun vihani ja hirmuisuuteni jälkeen; että heidän minun kostoni tunteman pitää, sanoo Herra, Herra.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Näin sanoo Herra, Herra: että Philistealaiset kostaneet ovat ja vanhan vihansa sammuttaneet, kaiketi oman tahtonsa perään (minun kansani) vahingoksi;
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
Sentähden sanoo Herra, Herra näin: katso, minä tahdon minun käteni ojentaa Philistealaisten päälle; ja Kretiläiset hävittää, ja tahdon jääneet meren satamissa surmata;
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
Ja tahdon heille suuresti kostaa, ja vihassa heitä rangaista, että heidän ymmärtämän pitää minun olevan Herran, koska minä heille kostanut olen.

< Ezekiel 25 >