< Ezekiel 25 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
The worde of the Lord came againe vnto me, saying,
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Sonne of man, set thy face against the Ammonites, and prophecie against them,
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
And say vnto the Ammonites, Heare the word of the Lord God, Thus saith the Lord God, Because thou saydest, Ha, ha, against my Sanctuarie, when it was polluted, and against the land of Israel, when it was desolate, and against the house of Iudah, when they went into captiuitie,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
Beholde, therefore I will deliuer thee to the men of the East for a possession, and they shall set their palaces in thee, and make their dwellings in thee: they shall eate thy fruite, and they shall drinke thy milke.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
And I will make Rabbah a dwelling place for camels, and the Ammonites a sheepecote, and ye shall knowe that I am the Lord.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
For thus saith the Lord God, Because thou hast clapped the hands, and stamped with the feete, and reioyced in heart with all thy despite against the land of Israel,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Beholde, therefore I will stretche out mine hand vpon thee, and will deliuer thee to be spoyled of the heathen, and I will roote thee out from the people, and I will cause thee to be destroyed out of the countreys, and I will destroy thee, and thou shalt know that I am the Lord.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Thus saith the Lord God, Because that Moab and Seir doe say, Beholde, the house of Iudah is like vnto all the heathen,
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
Therefore, beholde, I will open the side of Moab, euen of the cities of his cities, I say, in his frontiers with the pleasant countrey, Beth-ieshimoth, Baal-meon, and Karia-thaim.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
I will call the men of the East against the Ammonites, and will giue them in possession, so that the Ammonites shall no more be remembred among the nations,
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
And I will execute iudgements vpon Moab, and they shall knowe that I am the Lord.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Thus sayth the Lord God, Because that Edom hath done euill by taking vengeance vpon the house of Iudah, and hath committed great offence, and reuenged himselfe vpon them,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
Therefore thus saith the Lord God, I will also stretch out mine hand vpon Edom, and destroy man and beast out of it, and I will make it desolate from Teman, and they of Dedan shall fall by the sworde.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
And I will execute my vengeance vpon Edom by the hand of my people Israel, and they shall doe in Edom according to mine anger, and according to mine indignation, and they shall know my vengeance, sayth the Lord God.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Thus sayth the Lord God, Because the Philistims haue executed vengeance, and reuenged themselues with a despitefull heart, to destroy it for the olde hatred,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
Therefore thus sayth the Lord God, Behold, I will stretche out mine hand vpon the Philistims, and I will cut off the Cherethims, and destroy the remnant of the sea coast.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
And I will execute great vengeance vpon them with rebukes of mine indignation, and they shall knowe that I am the Lord, when I shall lay my vengeance vpon them.