< Ezekiel 24 >

1 Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Și în anul al nouălea, în luna a zecea, în [ziua] a zecea a lunii, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
Fiu al omului, scrie-ți numele zilei, al acestei zile: împăratul Babilonului se îndreaptă împotriva Ierusalimului în această zi.
3 Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
Și rostește o parabolă casei răzvrătite și spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pune o oală, pune-[o] și de asemenea toarnă apă în ea;
4 Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
Adună bucățile ei în ea, fiecare bucată bună, coapsa și umărul; umple-[o] cu oase alese.
5 mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
Ia pe cele mai alese din turmă și arde de asemenea oasele sub ea [și] fă-o să fiarbă bine și lasă oasele ei să clocotească în ea.
6 Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vai cetății sângeroase, [vai] de oala a cărei depunere [este] în ea și a cărei depunere nu a ieșit din ea! Scoateți-o bucată cu bucată; să nu cadă niciun sorț pe ea.
7 “‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
Pentru că sângele ei este în mijlocul ei: ea l-a pus pe vârful unei stânci; nu l-a turnat pe pământ pentru a-l acoperi cu țărână;
8 Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
Ca să facă să vină furia pentru a se răzbuna; eu am pus sângele ei pe vârful unei stânci, ca să nu fie acoperit.
9 Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vai cetății sângeroase! Eu, chiar eu voi mări grămada pentru foc.
10 Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
Îngrămădește lemne, aprinde focul, mistuie carnea și înmiresmeaz-o bine și lasă oasele să fie arse.
11 Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
Apoi pune-o goală pe cărbunii ei, ca arama ei să fie fierbinte și să ardă [și ca] murdăria ei să fie topită în ea, [ca] depunerea ei să fie mistuită.
12 Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
Ea [s]-a ostenit cu minciuni și depunerea ei mare nu a ieșit din ea; depunerea ei [va fi] în foc.
13 “‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
În murdăria ta [este] desfrânare; deoarece eu te-am curățit și tu nu ai fost curățată, nu vei mai fi curățată de murdăria ta, până nu îmi voi fi făcut furia mea să se odihnească asupra ta.
14 “‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Eu DOMNUL am vorbit [aceasta]: se va întâmpla și eu [o] voi face; nu mă voi întoarce, nici nu voi cruța, nici nu mă voi pocăi; conform cu căile tale și conform cu facerile tale, te vor judeca ei, spune Domnul DUMNEZEU.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
De asemenea cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
16 “Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
Fiu al omului, iată, eu iau de la tine dorința ochilor tăi cu o lovitură; totuși să nu jelești nici să nu plângi, nici să nu îți curgă lacrimile.
17 Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
Abține-te să plângi, să nu jelești pentru morți, leagă-ți tiara capului tău pe tine și pune-ți sandalele în picioare și nu [îți] acoperi buzele și nu mânca pâinea oamenilor.
18 Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
Astfel am vorbit poporului dimineața; și seara soția mea a murit; iar eu am făcut dimineața precum mi se poruncise.
19 Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
Și poporul mi-a spus: Nu ne vei spune ce [sunt] aceste [lucruri] pentru noi, pe care [astfel] le faci?
20 Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Atunci le-am răspuns: Cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
21 Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
Vorbește casei lui Israel: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, voi spurca sanctuarul meu, maiestatea puterii voastre, dorința ochilor voștri și pe aceea de care se îndură sufletul vostru; și fiii voștri și fiicele voastre, pe care i-ați lăsat vor cădea prin sabie.
22 Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
Și veți face precum eu am făcut: nu [vă] veți acoperi buzele, nici nu veți mânca pâinea oamenilor.
23 Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
Și tiarele voastre [vor fi] pe capetele voastre și sandalele voastre în picioarele voastre; nu veți jeli nici nu veți plânge; ci veți lâncezi pentru nelegiuirile voastre și veți jeli unul față de altul.
24 Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
Astfel Ezechiel este un semn pentru voi: conform cu toate câte el a făcut veți face voi; și când acest [lucru] va veni, veți cunoaște că eu [sunt] Domnul DUMNEZEU.
25 “Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
De asemenea, tu, fiu al omului, nu [se va întâmpla aceasta] în ziua când voi lua de la ei puterea lor, bucuria gloriei lor, dorința ochilor lor și spre ce își îndreaptă mințile, pe fiii lor și pe fiicele lor,
26 ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
[Că] cel care scapă în acea zi va veni la tine, pentru a [te] face să auzi [aceasta] cu urechile [tale]?
27 Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”
În acea zi gura ta va fi deschisă spre cel scăpat și vei vorbi și nu vei mai fi mut; și vei fi un semn pentru ei; iar ei vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.

< Ezekiel 24 >