< Ezekiel 24 >

1 Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
La neuvième année, au dixième mois, le dixième jour du mois, la parole de l'Éternel me fut adressée en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
« Fils d'homme, écris le nom du jour, ce jour-là. En ce jour, le roi de Babylone s'est approché de Jérusalem.
3 Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
Raconte une parabole à la maison rebelle, et dis-leur: « Le Seigneur Yahvé dit, « Mets le chaudron sur le feu. Mettez-le, et aussi verser de l'eau dedans.
4 Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
Rassemblez ses pièces en elle, même chaque bon morceau: la cuisse et l'épaule. Remplissez-le avec les os de choix.
5 mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
Prenez le choix du troupeau, et aussi un tas de bois pour les os sous le chaudron. Faites-le bien bouillir. Oui, que ses os soient bouillis en son sein. »
6 Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
"'C'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « Malheur à cette ville sanglante, au chaudron dont la rouille est à l'intérieur, et dont la rouille n'a pas disparu! En retirer morceau après morceau sans tirer au sort.
7 “‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
"''Car le sang qu'elle a versé est au milieu d'elle. Elle l'a posé sur la roche nue. Elle ne l'a pas versé sur le sol, pour le recouvrir de poussière.
8 Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
afin de faire monter la colère pour se venger, J'ai mis son sang sur la roche nue, qu'il ne devrait pas être couvert. »
9 Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
"'C'est pourquoi le Seigneur Yahvé dit: « Malheur à cette ville sanglante! Je vais aussi faire en sorte que la pile soit grande.
10 Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
Entassez le bois. Faites chauffer le feu. Faites bien bouillir la viande. Rendez le bouillon épais, et que les os soient brûlés.
11 Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
Puis on le pose vide sur ses charbons, pour qu'il soit chaud, et son bronze peut brûler, et que sa souillure soit fondue en elle, pour que sa rouille soit consommée.
12 Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
Elle est fatiguée par le labeur; pourtant sa grande rouille, la rouille par le feu, ne la quitte pas.
13 “‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
"''Dans votre souillure, il y a de la débauche. Parce que je t'ai purifié et que tu n'as pas été purifié, tu ne seras plus purifié de ta souillure, jusqu'à ce que j'aie fait cesser ma colère contre toi.
14 “‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
"''Moi, Yahvé, je l'ai dit. Cela arrivera, et je le ferai. Je ne reviendrai pas en arrière. Je n'épargnerai pas. Je ne me repentirai pas. Selon vos voies et selon vos actes, on vous jugera, dit le Seigneur Yahvé.''"
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
La parole de Yahvé me fut adressée en ces termes:
16 “Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
« Fils d'homme, voici que je vais t'ôter d'un seul coup le désir de tes yeux; mais tu ne te lamenteras pas, tu ne pleureras pas, et tes larmes ne couleront pas.
17 Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
Soupirez, mais pas à haute voix. Ne portez pas le deuil des morts. Attache ta coiffe sur toi, et mets tes sandales à tes pieds. Ne couvre pas tes lèvres, et ne mange pas de pain de deuil. »
18 Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
J'ai donc parlé au peuple le matin, et le soir ma femme est morte. J'ai donc fait le matin ce qu'on m'avait ordonné.
19 Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
Le peuple me demanda: « Ne vas-tu pas nous dire ce que cela signifie pour nous, que tu agisses ainsi? »
20 Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Puis je leur dis: « La parole de Yahvé m'a été adressée en ces termes:
21 Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
Parle à la maison d'Israël: « Le Seigneur Yahvé dit: 'Voici que je vais profaner mon sanctuaire, l'orgueil de ta puissance, le désir de tes yeux et ce qui fait la joie de ton âme, et tes fils et tes filles que tu as laissés tomber par l'épée.
22 Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
Tu feras comme moi. Vous ne couvrirez pas vos lèvres et ne mangerez pas de pain de deuil.
23 Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
Vos turbans seront sur vos têtes, et vos sandales à vos pieds. Vous ne vous lamenterez pas, vous ne pleurerez pas, mais vous vous morfondrez dans vos iniquités, et vous gémirez les uns sur les autres.
24 Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
Ainsi, Ézéchiel sera pour vous un signe; vous ferez tout ce qu'il a fait. Quand cela sera arrivé, alors vous saurez que je suis le Seigneur Yahvé.'"""
25 “Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
« Toi, fils d'homme, n'est-ce pas au jour où je leur enlèverai leur force, la joie de leur gloire, le désir de leurs yeux, et ce sur quoi ils ont jeté leur dévolu - leurs fils et leurs filles -
26 ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
qu'en ce jour-là, celui qui échappe viendra à toi, pour que tu l'entendes de tes oreilles?
27 Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”
En ce jour-là, ta bouche s'ouvrira à celui qui s'échappe, tu parleras et tu ne seras plus muet. Tu seras pour eux un signe. Ils sauront alors que je suis Yahvé. »

< Ezekiel 24 >