< Ezekiel 24 >

1 Ní ọdún kẹsànán, oṣù kẹwàá, ọjọ́ kẹwàá, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Ja Herran sana tapahtui minulle, yhdeksäntenä vuonna, kymmenentenä päivänä kymmenennestä kuusta, ja sanoi:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ọjọ́ náà sílẹ̀, ọjọ́ náà gan an, nítorí ọba Babeli náà ti da ojú ti Jerusalẹmu ní ọjọ́ yìí gan an.
Sinä, ihmisen poika, kirjoita sinulles tämän päivän nimi, juuri tämä päivä; sillä Babelin kuningas on juuri tänäpäivänä Jerusalemia vastaan hankinnut.
3 Sì pa òwe yìí fún ilé ọlọ́tẹ̀ náà, sọ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Gbé ìkòkò ìdáná náà ka iná, gbé e ka iná kí o sì da omi sí i nínú.
Ja pane tottelemattoman kansan eteen vertaus, ja sano heille: näin sanoo Herra, Herra: pane pata ja valmista, ja pane siihen vettä.
4 Kó àwọn ègé ẹran tí a gé náà sínú rẹ̀, gbogbo àwọn ègé ẹran tí ó tóbi, itan àti apá. Kó àwọn egungun tí ó dára jù sínú rẹ̀,
Pane kappaleet siihen kokoon, kaikki ne parhaat kappaleet, reisi ja lapa; ja täytä se parhailla luukappaleilla.
5 mú àwọn tí ó jọjú nínú agbo ẹran. Kó àwọn egungun sí abẹ́ ẹ rẹ̀; sì jẹ́ kí ó hó dáradára sì jẹ́ kí àwọn egungun náà bọ̀ nínú rẹ̀.
Ota paras laumasta, ja tee valkia alle luukappaleita keittääkses; ja anna vahvasti kiehua, ja luukappaleet hyviä kypsyä.
6 Nítorí báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà, fún ìkòkò náà tí èérí rẹ̀ wà nínú rẹ̀, tí èérí kò dà kúrò lójú rẹ̀! Mú ẹran náà jáde ní ekìrí ekìrí má ṣe ṣà wọ́n mú.
Sentähden näin sanoo Herra, Herra: voi murhakaupunkia! joka senkaltainen pata on, jossa ruoste riippuu kiinni, niin ettei sen ruoste tahdo eritä. Ota kappale kappaleen jälkeen siitä ulos, sillä ei tarvita siitä arpaa heittää.
7 “‘Nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ó ta sílẹ̀ wà ní àárín rẹ̀; à á sí orí àpáta kan lásán kò dà á sí orí ilẹ̀, níbi ti erùpẹ̀ yóò ti bò ó.
Sillä hänen verensä on siellä, joka paljaalle kalliolle pantu on, ja ei maan päälle vuodatettu, että se mullalla peitettäisiin.
8 Láti bá à le jẹ́ kí ìbínú kí ó dé láti gbẹ̀san mo da ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sí orí àpáta kan lásán, kí o ma bà á wà ni bíbò.
Ja minä olen myös sentähden heidän antanut sen veren paljaalle kalliolle vuodattaa, ettei se peitettäisi, että viha tulis heidän päällensä, ja heille kostettaisiin.
9 Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ègbé ni fún ìlú ẹlẹ́jẹ̀ náà! Èmi pàápàá yóò jẹ́ kí òkìtì iná náà tóbi.
Sentähden sanoo Herra, Herra näin: voi murhakaupunkia! jonka minä suureksi valkiaksi teen.
10 Nítorí náà kó igi náà jọ sí i, kí o sì fi iná sí i. Ṣe ẹran náà dáradára, fi tùràrí dùn ún; kí o sì jẹ́ kí egungun náà jóná.
Kanna vaivoin paljo puita, sytytä tuli, että liha kypsäksi tulis, ja pane hyvin yrttejä sen päälle, että luukappaleet palaisivat.
11 Lẹ́yìn náà gbé òfìfo ìkòkò náà lórí ẹyin iná kí idẹ rẹ̀ lè gbóná, kí ó lè pọ́n àti ki ìfófó rẹ̀ le di yíyọ́ nínú rẹ̀ kí èérí rẹ̀ le jó dànù.
Pane myös pata tyhjänä hiilille, että se kuumaksi tulis, ja sen vaski palais, jos sen saastaisuus sulais, ja sen ruoste läksis.
12 Ó ti ba gbogbo akitiyan jẹ: èérí rẹ̀ kò sì jáde kúrò lára rẹ̀, èérí náà gan an yóò wà nínú iná.
Vaan ruoste, ehkä se kuinka kovin poltetaan, ei tahdo lähteä, sillä se on aivan kovin ruostunut, se pitää tulessa sulattaman.
13 “‘Nísinsin yìí èérí rẹ̀ ni ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wà. Nítorí mo gbìyànjú láti wẹ̀ ọ́ mọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò sì mọ́ kúrò nínú ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, a kì yóò sì tún wẹ̀ ọ mọ́ kúrò nínú èérí rẹ, títí èmi yóò fi jẹ́ kí ìbínú mi balẹ̀ sórí rẹ̀.
Sinun saastaisuutes on sula ilkeys, että vaikka minä sinua mielelläni puhdistaisin, et kuitenkaan sinä tahdo itsiäs puhdistaa antaa; sinun saastaisuudestas et sinä tästedes enää taida puhdistettaa, siihenasti että minun hirmuisuuteni sinussa sammunut on.
14 “‘Èmi Olúwa ni ó sọ ọ́, yóò sì ṣe, èmi yóò sì ṣe é. Èmi kì yóò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò dá sí i, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò yí ọkàn mi padà; gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ, ni wọn yóò dá ọ lẹ́jọ́, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Minä Herra olen sen puhunut; se pitää tuleman, minä tahdon tehdä, ja en viivyttää, en minä tahdo armahtaa, enkä kadu; vaan heidän pitää sinun tuomitseman, niinkuin sinä elänyt ja tehnyt olet, sanoo Herra, Herra.
15 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá pé:
Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
16 “Ọmọ ènìyàn, kíyèsi i, mo mú ìfẹ́ ojú rẹ kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, nípa lílù kan. Ṣùgbọ́n ìwọ kò gbọdọ̀ gbààwẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ sọkún, bẹ́ẹ̀ ni omijé ojú rẹ kò gbọdọ̀ kán sílẹ̀.
Sinä ihmisen poika, katso, minä tahdon sinulta silmäis himon ottaa pois rangaistuksen kautta; mutta ei sinun pidä valittaman, eikä itkemän, eikä kyyneleitä vuodattaman.
17 Má ṣe sọkún, má ṣe gbààwẹ̀ fún òkú. Wé ọ̀já sí orí rẹ, sì bọ bàtà sí ẹsẹ̀ rẹ, má ṣe bo ètè ìsàlẹ̀ rẹ, ma ṣe jẹ oúnjẹ tí àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.”
Salaa sinä mahdat huoata, mutta kuolleen valitusta ei sinun pidä pitämän, vaan sinun pitää kaunistukses paneman päälles, ja kengät jalkaas kenkimän; ei sinun pidä suutas peittämän, eikä murheellisten leipää syömän.
18 Báyìí ni mo sọ̀rọ̀ fún àwọn ènìyàn ní òwúrọ̀, ní àṣálẹ́ ìyàwó mi sì kú. Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo ṣe bí a ti pàṣẹ fún mi.
Ja kuin minä huomeneltain varhain kansalle puhuin, kuoli minulta ehtoona minun emäntäni. Ja minä tein toisena huomenna, kuin minulle käsketty oli.
19 Lẹ́yìn náà àwọn ènìyàn bi mí léèrè pé, “Ṣe o kò ni sọ fún wa ohun ti nǹkan wọ̀nyí ní láti ṣe pẹ̀lú wa?”
Ja kansa sanoi minulle: etkös siis ilmoita meille, mitä tämä meille ennustaa, minkä sinä teet?
20 Mo sọ báyìí fún wọn pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Ja minä sanoin heille: Herra on minun kanssani puhunut ja sanonut:
21 Sọ fún ilé Israẹli, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi i, èmi yóò sọ ibi mímọ́ mi di ibi àìmọ́ tayọ agbára yín, ìfẹ́ ojú yín, ìkáàánú yín, àti ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin tí ẹ̀yin fi sílẹ̀ sẹ́yìn yóò ṣubú nípa idà.
Sano Israelin huoneelle, että Herra näin sanoo: katso, minä tahdon minun pyhäni, teidän korkeimman lohdutuksenne, teidän silmäinne himon ja teidän sydämenne toivon saastuttaa; ja teidän poikanne ja tyttärenne, jotka teidän hylkäämän pitää, lankeevat miekan kautta.
22 Ẹyin yóò sì ṣe bí mo ti ṣe. Ẹ̀yin kì yóò bo ìsàlẹ̀ ojú yín tàbí jẹ oúnjẹ ti àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ń jẹ gẹ́gẹ́ bí àṣà.
Ja teidän täytyy tehdä, niinkuin minä tehnyt olen: teidän suutanne ei teidän pidä peittämän, eikä murheellisen leipää syömän.
23 Ẹ̀yin yóò fi àwọn ọ̀já wé àwọn orí yín àti àwọn bàtà ni ẹsẹ̀ yín, ẹ̀yin kì yóò ṣọ̀fọ̀ tàbí sọkún, ṣùgbọ́n ẹ̀yin yóò ṣòfò dànù nítorí àwọn àìṣedéédéé yín, ẹ̀yin yóò sì máa kérora láàrín ara yín.
Vaan pitää teidän kaunistuksenne teidän päähänne paneman, ja kenkimän itsenne; ei teidän pidä valittaman eikä itkemän, vaan teidän synnissänne nääntymän, ja keskenänne toinen toisenne kanssa huokaileman.
24 Esekiẹli yóò jẹ àmì fún un yín; ẹ̀yin yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe. Nígbà tí èyí bá ṣẹlẹ̀, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.’
Ja pitää niin Hesekiel teillle ihmeeksi oleman, että teidän tekemän pitää kaiken sen jälkeen, minkä hän tehnyt on; että kuin se tulee, te ymmärtäisitte, että minä Herra, Herra olen.
25 “Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ, Ọmọ ènìyàn, kì yóò ha jẹ́ pé, ní ọjọ́ náà, nígbà ti mo bá gba agbára wọn, ayọ̀ wọn àti ògo wọn, ìfẹ́ ojú wọn, ohun tí wọn gbé ọkàn wọn lé, àti àwọn ọmọ ọkùnrin wọn pẹ̀lú àwọn ọmọ obìnrin wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn,
Ja sinä, ihmisen poika, silloin kuin minä heiltä olen ottava pois heidän voimansa ja lohdutuksensa, heidän silmäinsä himon ja heidän sydämensä toivon, heidän poikansa ja tyttärensä;
26 ní ọjọ́ náà ẹni tí ó bá sálà yóò tọ̀ ọ́ wá láti sọ ìròyìn náà fún ọ.
Silloin pitää yksi, joka päässyt on, tuleman sinun tykös, ja sinulle ilmoittaman.
27 Ní ọjọ́ náà ẹnu rẹ yóò sì ṣí; ìwọ yóò sọ̀rọ̀, ìwọ kì yóò sì yadi mọ́. Báyìí ìwọ yóò jẹ́ àmì fún wọn; wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ní Olúwa.”
Silloin pitää sinun suus avattaman, ja sen joka päässyt on, että sinun puhuman pitää, ja ei enää vaikeneman. Ja sinun pitää heille ihmeeksi oleman, että he ymmärtäisivät minun olevan Herran.

< Ezekiel 24 >