< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Cuvântul DOMNULUI a venit din nou la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
Fiu al omului, erau două femei, fiicele unei singure mame;
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
Și ele au comis curvie în Egipt; au comis curvie în tinerețea lor; acolo le-au fost strânși sânii și acolo și-au lovit sânul fecioriei lor.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
Și numele lor [erau] Ohola, cea mare și Oholiba sora ei; și ele erau ale mele și au născut fii și fiice. Astfel [erau] numele lor: Samaria [este] Ohola și Ierusalimul [este] Oholiba.
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
Și Ohola a făcut pe curva când era a mea; și s-a aprins după iubiții ei, după asirienii, vecinii [ei],
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
[Care erau] îmbrăcați în albastru, căpetenii și conducători, cu toții tineri de dorit, călăreți, călărind pe cai.
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
Astfel ea și-a curvit cu aceia, cu toți bărbații aleși ai Asiriei și cu toți după care se aprindea; cu toți idolii lor se pângărea.
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Și nu și-a părăsit curviile [aduse] din Egipt, pentru că în tinerețea ei s-au culcat cu ea și i-au lovit sânii fecioriei ei și și-au turnat curvia lor peste ea.
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Pentru aceea am dat-o în mâna iubiților ei, în mâna asirienilor, după care se aprinsese.
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
Aceștia i-au dezvelit goliciunea; au luat pe fiii ei și pe fiicele ei, iar pe ea au ucis-o cu sabia; și ea a devenit faimoasă printre femei; fiindcă au făcut judecată asupra ei.
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
Și când sora ei Oholiba a văzut [aceasta, ] ea a fost mai coruptă în iubirea ei necumpătată decât ea și în curviile ei mai mult decât sora ei în curviile [ei].
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
Ea s-a aprins după asirieni, vecinii [ei], căpetenii și conducători îmbrăcați în măreție, călăreți călărind pe cai, cu toții tineri de dorit.
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
Atunci am văzut că ea s-a pângărit, [că] ele amândouă [au luat] o singură cale,
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
Și [că] ea și-a înmulțit curviile, pentru că atunci când a văzut bărbați gravați pe perete, chipurile caldeenilor desenate cu roșu aprins,
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
Încinși cu brâie peste coapsele lor, preafrumoși în tiare vopsite pe capetele lor, cu toții prinți [frumoși] la privit, după felul babilonienilor din Caldeea, țara lor de naștere;
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
Și îndată ce i-a văzut cu ochii ei, s-a aprins după ei și a trimis mesageri la ei în Caldeea.
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
Și babilonienii au venit la ea, în patul de dragoste, și au pângărit-o cu curvia lor și ea s-a murdărit cu ei și mintea ei s-a înstrăinat de ei.
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Astfel ea și-a dezvelit curviile ei și și-a dezvelit goliciunea; atunci mintea mea s-a înstrăinat de ea, precum mintea mea s-a înstrăinat de sora ei.
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
Totuși ea și-a înmulțit curviile ei, aducându-și aminte de zilele tinereții ei, în care făcea pe curva în țara Egiptului.
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
Fiindcă ea s-a aprins după concubinii ei, a căror carne [este ca și] carnea măgarilor și a căror scurgere [este ca și] scurgerea cailor.
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
Astfel ți-ai adus aminte desfrânarea tinereții tale, când sânii tăi erau loviți de egipteni, pentru pieptul tinereții tale.
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
De aceea, Oholiba, astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, voi ridica împotriva ta pe iubiții tăi, de care mintea ta s-a înstrăinat și îi voi aduce împotriva ta de fiecare parte;
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
Pe babilonieni și pe toți caldeenii, Pecodul și Șoa și Coah [și] pe toți asirienii împreună cu ei; cu toții tineri de dorit, căpetenii și conducători, domni mari și renumiți, cu toții călărind pe cai.
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
Și ei vor veni împotriva ta cu care, căruțe și roți și cu o adunare de popoare, [care] vor pune împotriva ta pavăză și scut și coif, de jur împrejur; și voi pune judecată înaintea lor și conform cu judecățile lor ei te vor judeca.
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
Și îmi voi întoarce gelozia împotriva ta și ei se vor purta furios cu tine; îți vor lua nasul și urechile; și rămășița ta va cădea prin sabie, ei vor lua pe fiii tăi și pe fiicele tale; și rămășița ta va fi nimicită prin foc.
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
De asemenea te vor dezbrăca de hainele tale și îți vor lua bijuteriile tale frumoase.
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
Astfel voi face eu să înceteze desfrânarea ta din tine și curvia ta [adusă] din țara Egiptului; astfel încât să nu îți ridici ochii spre ei, nici să nu îți mai amintești de Egipt.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
Pentru că astfel spune DOMNUL Dumnezeu: Iată, te voi da în mâna [celor] pe care îi urăști, în mâna [celor] de care mintea ta s-a înstrăinat;
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
Și ei se vor purta cu tine cu ură și îți vor lua toată munca și te vor lăsa goală și fără haine; și goliciunea curviilor tale va fi dezvelită, deopotrivă desfrânarea ta și curviile tale.
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
Îți voi face aceste [lucruri], pentru că ai curvit după păgâni [și] pentru că ești murdărită cu idolii lor.
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Ai umblat în calea surorii tale; de aceea voi pune paharul ei în mâna ta.
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Vei bea din adâncul și largul pahar al surorii tale; se va râde de tine în batjocură și vei fi luată în derâdere; el conține mult.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
Vei fi umplută cu beție și întristare, cu paharul înmărmuririi și a pustiirii, cu paharul surorii tale, Samaria.
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Îl vei bea și [îl] vei goli de tot și îi vei sparge cioburile și îți vei smulge sânii, pentru că eu am vorbit [aceasta], spune Domnul DUMNEZEU.
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că m-ai uitat și m-ai lepădat înapoia spatelui tău, de aceea poartă-ți și tu desfrânarea și curviile tale.
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
DOMNUL mi-a mai spus: Fiu al omului, vei judeca tu pe Ohola și pe Oholiba? Da, vestește-le urâciunile lor;
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
Pentru că ele au curvit și sânge [este] în mâinile lor; și cu idolii lor au comis adulter și de asemenea au făcut pe fiii lor, pe care mi i-au născut, să treacă pentru ele prin [foc], pentru a-[i] mânca.
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
Mai mult, aceasta mi-au făcut: au spurcat sanctuarul meu în aceeași zi și au pângărit sabatele mele.
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
Pentru că atunci când au ucis pe copiii lor pentru idolii lor, atunci au intrat în aceeași zi în sanctuarul meu pentru a-l spurca; și, iată, astfel au făcut ei în mijlocul casei mele.
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
Și mai mult, ați trimis după bărbați să vină de departe, la care un mesager [a fost] trimis; și, iată, ei au venit; pentru ei te-ai spălat, ți-ai vopsit ochii și te-ai împodobit cu ornamente,
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
Și ai șezut pe un pat maiestos și o masă pregătită înaintea lui, pe care ai pus tămâia mea și untdelemnul meu.
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
Și vocea unei mulțimi tihnite [era] cu ea; și cu bărbații de rând [au fost] aduși sabeeni din pustie, care au pus brățări pe mâinile lor și coroane frumoase pe capetele lor.
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
Atunci [i]-am spus [celei] îmbătrânite în adultere: Vor curvi cu ea și ea [cu ei]?
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
Totuși ei au intrat la ea precum intră la o femeie care face pe curva; astfel au intrat ei la Ohola și la Oholiba, femeile desfrânate.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
Și bărbații drepți, le vor judeca după felul celor adultere și după felul femeilor care varsă sânge, pentru că [sunt] adultere și sânge [este] în mâinile lor.
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
Pentru că astfel spune Domnul DUMNEZEU: Voi aduce o ceată asupra lor și le voi da să fie alungate și prădate.
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
Și ceata le va ucide cu pietre și le va tăia cu săbiile lor; ei vor ucide pe fiii lor și pe fiicele lor și le vor arde casele cu foc.
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
Astfel voi face desfrânarea ta să înceteze din țară, ca toate femeile să fie învățate să nu facă după desfrânarea voastră.
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
Și ei vor întoarce desfrânarea voastră asupra voastră și voi veți purta păcatele idolilor voștri; și veți cunoaște că eu [sunt] Domnul DUMNEZEU.

< Ezekiel 23 >