< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
Synu człowieczy, były dwie kobiety, córki jednej matki;
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
One uprawiały nierząd w Egipcie, w swojej młodości uprawiały nierząd; tam ściskano ich piersi i tam przygniatano piersi ich dziewictwa.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
A ich imiona: starsza Ohola, a jej siostra – Oholiba. One były moje i urodziły synów i córki. Ich imiona: Samaria to Ohola, a Jerozolima to Oholiba.
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
Ohola uprawiała nierząd, będąc moją, zapałała namiętnością do swoich kochanków, do Asyryjczyków, sąsiadów;
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
Którzy byli odziani w błękit, dowódcy i rządcy, wszyscy oni to powabni młodzieńcy, jeźdźcy dosiadający koni;
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
Popełniała z nimi nierząd, ze wszystkimi najlepszymi synami Asyrii i ze wszystkimi, do których pałała namiętnością; plamiła się wszystkimi ich bożkami.
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Nie porzuciła też swego nierządu z Egiptu, bo spali z nią w jej młodości, przygniatali piersi jej dziewictwa i wylali na nią swój nierząd.
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Dlatego wydałem ją w ręce jej kochanków, w ręce Asyryjczyków, do których pałała namiętnością.
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
Oni odsłonili jej nagość, zabrali jej synów i córki, a ją samą zabili mieczem. I stała się osławiona wśród kobiet, gdy wykonano na niej sąd.
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
A choć widziała to jej siostra Oholiba, bardziej niż ona zapałała [rozwiązłą] miłością, a jej nierząd był [jeszcze] większy niż nierząd jej siostry.
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
Do swych sąsiadów Asyryjczyków pałała namiętnością, do dowódców i rządców, i władców, ubranych w kosztowne szaty, do jeźdźców dosiadających konie, wszyscy oni to powabni młodzieńcy.
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
I widziałem, że się hańbiła [i że] obydwie [kroczyły] tą samą drogą.
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
Ale ta posunęła się jeszcze dalej w swoich nierządnych czynach, bo widząc mężczyzn wymalowanych na ścianie, obrazy Chaldejczyków malowane farbami;
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
Opasanych wokół bioder pasami, z zawojami ufarbowanymi na głowach – [a] wszyscy oni z wyglądu jak bohaterowie, podobni do Babilończyków pochodzących z ziemi Chaldei;
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
Pałała do nich namiętnością, jak tylko spojrzała na nich swymi oczami, i wyprawiła do nich posłańców, do Chaldei.
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
Wtedy Babilończycy weszli do niej, na łoże miłości, i plamili ją swoim nierządem; a gdy się skalała z nimi, jej dusza odwróciła się od nich.
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
I gdy ujawniła swoje czyny nierządne i odsłoniła swoją nagość, moja dusza odwróciła się od niej, tak jak odwróciła się moja dusza od jej siostry.
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
Lecz ona mnożyła swoje czyny nierządne, przypominając sobie dni swojej młodości, kiedy uprawiała nierząd w ziemi Egiptu.
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
I pałała namiętnością do ich kochanków, których ciała [są jak] ciała osłów, a ich wytrysk jak wytrysk koni.
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
Tak powróciłaś do rozwiązłości swojej młodości, gdy Egipcjanie przygniatali twoje piersi dla piersi twojej młodości.
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
Dlatego, Oholibo, tak mówi Pan BÓG: Oto pobudzę przeciwko tobie twoich kochanków, tych, od których odwróciła się twoja dusza, i sprowadzę ich zewsząd przeciwko tobie;
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
Babilończyków, wszystkich Chaldejczyków, Pekod, Szoa, Koa, a z nimi wszystkich Asyryjczyków. Oni wszyscy to powabni młodzieńcy, dowódcy i rządcy, dostojnicy i zacni [ludzie], wszyscy jeżdżący na koniach.
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
I wyruszą przeciwko tobie na rydwanach, na wozach żelaznych, na furmankach i z gromadą narodów. Zewsząd rozłożą się przeciwko tobie z puklerzami, tarczami i hełmami. I dam im prawo, aby cię sądzili według swoich praw.
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
I wyleję na ciebie swoją zazdrość, i obejdą się z tobą z gniewem. Odetną ci nos i uszy, a twoja resztka polegnie od miecza. Wezmą twoich synów i twoje córki, a to, co z ciebie zostanie, strawi ogień.
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
I zdejmą z ciebie twoje szaty, i zabiorą ci twoje piękne klejnoty.
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
Tak położę kres twojej rozwiązłości i twojemu nierządowi, [które przyniosłaś] z ziemi Egiptu. Nie podniesiesz [już] ku nim swych oczu ani nie będziesz więcej wspominać Egiptu.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
Tak bowiem mówi Pan BÓG: Oto wydam cię w ręce tych, których nienawidzisz, w ręce tych, od których odwróciła się twoja dusza.
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
I postąpią z tobą z nienawiścią, zabiorą ci cały twój dorobek, zostawią cię nagą i obnażoną i zostaną odkryte nagość twego nierządu, twoja rozwiązłość i twoje czyny nierządne.
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
To ci się przydarzy, dlatego że uprawiałaś nierząd, naśladując pogan; dlatego że skalałaś się ich bożkami.
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Chodziłaś drogą swojej siostry, dlatego dam jej kielich w twoją rękę.
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
Tak mówi Pan BÓG: Będziesz pić z kielicha swojej siostry, głębokiego i szerokiego, będziesz pośmiewiskiem i szyderstwem, bo on wiele zmieści.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
Będziesz napełniona pijaństwem i bólem, kielichem spustoszenia i smutku, kielichem twojej siostry Samarii.
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Wypijesz go i wychylisz do dna, potem go rozbijesz na kawałki, a swoje piersi poobrywasz. Ja bowiem to powiedziałem, mówi Pan BÓG.
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Ponieważ zapomniałaś o mnie i rzuciłaś mnie za swoje plecy, ty także znoś swoją rozwiązłość i swój nierząd.
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
I PAN powiedział do mnie: Synu człowieczy, czy będziesz sądził Oholę i Oholibę? Uświadom im ich obrzydliwości;
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
Że cudzołożyły i krew jest na ich rękach; z bożkami cudzołożyły, także swych synów, których mi urodziły, przeprowadziły [przez ogień], by byli strawieni.
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
I jeszcze to mi uczyniły, że moją świątynię splugawiły w tym samym dniu i zbezcześciły moje szabaty.
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
Gdy bowiem zabiły swoje dzieci dla swoich bożków, wchodziły do mojej świątyni w tym samym dniu, aby ją zbezcześcić; oto tak czyniły wewnątrz mego domu.
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
Ponadto posyłały po mężczyzn, aby przyszli z daleka; wysłano więc posłańca, a oni przyszli. Dla nich się myłaś, barwiłaś swoje oczy i stroiłaś się w ozdoby;
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
Siadałaś na wspaniałym łożu, przed którym był przygotowany stół i na którym kładłaś moje kadzidło i mój olejek.
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
I rozległ się u niej głos beztroskiego tłumu, a wraz z ludem pospolitym przyprowadzono z pustyni Sabejczyków, którzy wkładali bransolety na ich ręce i ozdobne korony na ich głowy.
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
I powiedziałem do tej cudzołożnicy zestarzałej: Czy oni będą uprawiać nierząd z nią, a ona z nimi?
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
I obcowali z nią, jak się obcuje z nierządnicą. Tak właśnie obcowali z Oholą i Oholibą, kobietami rozwiązłymi.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
Dlatego mężowie sprawiedliwi będą je sądzić, jak się sądzi cudzołożnice i jak się sądzi przelewających krew, gdyż one są cudzołożnicami, a krew jest na ich rękach.
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
Tak bowiem mówi Pan BÓG: Sprowadzę na nie wojsko i wydam je na wysiedlenie i na łup.
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
I ta gromada ukamienuje je, i rozsiecze swymi mieczami, zabije ich synów i córki, a ich domy spali ogniem.
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
Tak usunę rozwiązłość z tej ziemi, aby wszystkie kobiety otrzymały ostrzeżenie i nie czyniły według waszej rozwiązłości.
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
I będzie nałożona na was wasza rozwiązłość, i poniesiecie grzechy waszych bożków. I poznacie, że ja jestem Panem BOGIEM.

< Ezekiel 23 >