< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
Synu człowieczy! były dwie niewiasty, córki jednej matki;
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
Te nierząd płodziły w Egipcie, w młodości swojej nierząd płodziły; tam są omacane piersi ich, i tam są zgniecione piersi panieństwa ich.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
Imiona ich te są: Większej Ahola, a siostry jej Aholiba. Teć były moje, i zrodziły synów i córki; imiona, mówię, ich są, Samaryja Ahola, a Jeruzalem Aholiba.
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
Ale Ahola płodziła wszeteczeństwo przy mnie, a nierządu pilnowała z miłośnikami swojemi, z Assyryjkczykami bliskimi,
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
Którzy byli obleczeni w hijacynt, z książętami, i panami, i ze wszystkimi młodzieńcami udatnymi, i z jezdnymi jeżdżącymi na koniach;
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
Udała się, mówię, na wszeteczeństwo swoje z nimi, ze wszystkimi najprzedniejszymi synami Assyryjskimi, i ze wszystkimi, za którymi miłością pałała, a splugawiała się wszystkiemi plugawemi bałwanami ich.
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
A tak wszeteczeństw swoich egipskich nie zaniechała: bo z nią sypiali w młodości jej, a oni omacali piersi panieństwa jej, i wylali wszeteczeństwo swe na nią.
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Dlatego podałem ją w rękę zalotników jej, w rękę synów Assyryjskich, za którymi miłością pałała.
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
Oni odkryli nagość jej, synów jej i córki jej zabrali, a samę mieczem zabili; i stała się osławioną między niewiastami, gdy sądy wykonali przy niej.
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
To widząc siostra jej Aholiba, bardziej się niż ona zapaliła miłością, a wszeteczeństwo jej większe było niżeli siostry jej.
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
Za synami Assyryjskimi pałała miłością, za książętami, i panami bliskimi, ubranymi w szaty kosztowne, za jezdnymi jeżdżącymi na koniach, i za wszystkimi młodzieńcami urodziwymi.
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
I widziałem, że się splugawiła, a iż jednaka droga obu była.
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
Ale ta jeszcze to przydała do wszeteczeństw swoich, że widząc mężów wymalowanych na ścianie, obrazy Chaldejczyków malowane farbami,
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
Opasane pasami na biodrach ich, i kołpaki farbowane na gowach ich, a że wszyscy na wejrzeniu byli jako hetmani, podobni synom Babilońskim, w ziemi Chaldejskiej zrodzonym;
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
I pałała miłością ku nim, ujrzawszy ich oczyma swemi, a wyprawiła posłów do nich do ziemi Chaldejskiej.
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
Tedy weszli do niej synowie Babilońscy do komory nierządu, i zmazali ją wszeteczeństwem swojem; a gdy się splugawiła z nimi, odstąpiła dusza jej od nich.
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
I gdy odkryła wszeteczeństwa swe, odkryła i nagość swoję; odstąpiła dusza moja od niej, jako była odstąpiła dusza moja od siostry jej.
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
Bo rozmnożyła wszeteczeństwa swoje, wspominając na dni młodości swojej, których nierządu patrzyła w ziemi Egipskiej.
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
I pałała miłością przeciwko nierządnikom ich, których ciała są jako ciała osłów, a przyrodzenie ich jako przyrodzenie końskie.
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
A takeś się zaś nawróciła do sprośności młodości twojej, gdy macali Egipczanie piersi twoje dla piersi młodości twojej.
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
Przetoż, o Aholibo! tak mówi panujący Pan: Oto ja pobudzę zalotników twoich przeciwko tobie, tych, od których odstąpiła dusza twoja, i przywiodę ich na cię zewsząd;
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
Synów Babilońskich, i wszystkich Chaldejczyków z Pekot, i z Soby, i z Kohy, i wszystkich synów Assyryjskich z nimi, młodzieńców udatnych, książąt i panów wszystkich, hetmanów i ludzi zacnych, wszystkich jeżdżących na koniach;
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
I przyjadą przeciwko tobie na wozach żelaznych, i na rydwanach, i na karach, a to z zgrają narodów, z tarczami, i z pancerzami, i z przyłbicami, położą się przeciwko tobie zewsząd; i dam im prawo, aby cię sądzili według praw swoich.
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
I wyleję gorliwość moję na cię, i obejdą się z tobą zapalczywie, nos twój i uszy twoje oberżną, a ostatek twój od miecza polegnie; oni synów twoich i córki twoje pojmają, a ostatek twój ogniem pożarty będzie;
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
I zewloką cię z szat twoich, a pobiorą strój ozdoby twojej.
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
A tak uczynię koniec sprośności twojej przy tobie, i wszeteczeństwu twemu, któreś przyniosła z ziemi Egipskiej, a nie podniesiesz oczów twych do nich, ani na Egipt nie wspomnisz więcej.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
Bo tak mówi panujący Pan: Oto cię Ja podaję w ręce tych, których masz w nienawiści, w ręce tych, od których odstąpiła dusza twoja;
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
I obejdą się z tobą według nienawiści, i zabiorą wszystkę pracę twoję, a zostawią cię nagą i obnażoną, i będzie jawna nagość wszeteczeństw twoich, i sprośności twojej, i nierządów twoich.
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
Toć się stanie przeto, żeś nierząd płodziła naśladując pogan, przeto, żeś się zmazała plugawemi bałwanami ich;
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Chodziłaś drogą siostry swej, dlatego dam kubek jej w rękę twoję.
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
Tak mówi panujący Pan: Kubek siostry twojej głęboki i szeroki pić będziesz, spory będzie; pośmiech także i igrzysko będą mieli z ciebie.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
Pijaństwem i boleścią napełniona będziesz, kubkiem spustoszenia i smutku, kubkiem siostry swej Samaryi!
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
I wypijesz go i wysączysz, potem go pokruszysz, a piersi swe poobrywasz; bom Ja rzekł, mówi panujący Pan.
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
Dlatego tak mówi panujący Pan: Ponieważeś zapomniała na mię, a zarzuciłaś mię za tył swój, i ty też ponoś niecnotę, swoję, i wszeteczeństwa swoje.
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
I rzekł Pan do mnie: Synu człowieczy! izali się będziesz zastawiał za Aholę albo za Aholibę? Oznajmij im raczej obrzydliwości ich:
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
Że cudzołożyły, a krew jest na rękach ich, i z plugawemi bałwanami swemi cudzołożyły; nadto i synów swych, których mi narodziły, przez ogień przeporowadzały im na pożarcie.
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
Więc i to mi uczyniły, że świątnicę moję splugawiły dnia onego, a sabaty moje pogwałciły.
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
Bo gdy ofiarowały synów swych plugawym bałwanom swoich, wchodziły do świątnicy mojej onegoż dnia, aby ją zmazały; oto takci czyniły w pośrodku domu mego.
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
Nadto posyłały też do mężów, aby przyszli z daleka; którzy zaraz przychodzili, kiedy poseł do nich wysłany był. Tymeś kwoli się ty umywała, farbowałaś twarz swoję, i zdobiłaś się ochędóstwem swojem.
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
Siadałaś na łożu zacnem, przed którym był stół przygotowany, na któremeś i kadzeniw moje i olejek mój pokładała.
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
A gdy głos onego mnóstwa ucichł, tedy i do mężów ludu pospolitego posyłały, których przywodzono ożartych z puszczy, i kładli manele na ręce ich, i korony ozdobne ne ręce ich.
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
A chociażem przymawiał onej cudzołożnicy zastarzałej, a iż oni raz z jedną, raz z drugą nierząd płodzą,
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
I że każdy z nich wchodzi do niej, jako wchodzą do niewiasty wszetecznej: przecie jednak wchodzili do Aholi i do Aholiby, niewiast niecnotliwych.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
Przetoż sprawiedliwi mężowie, ci je osądzą sądem cudzołożnic, i sądem wylewających krew, przeto, że cudzołożyły, a krew jest na rękach ich.
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
Bo tak mówi panujący Pan: Przywiodę na nie wojsko, a poddam je na potłukanie i na łup;
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
I ukamionuje je ono zgromadzenie kamieniem, i rozsieką je mieczami swemi, synów ich i córki ich pobiją, a domy ich ogniem spalą.
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
A tak uprzątnę sprośność z tej ziemi, i będą się tem karać wszystkie niewiasty, a nie uczynią według niecnoty waszej.
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
Bo włożona będzie na was niecnota wasza, a grzechy plugawych bałwanów waszych poniesiecie, i poznacie, żem Ja panujący Pan.

< Ezekiel 23 >