< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
و کلام خداوند بر من نازل شده، گفت:۱
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
«ای پسر انسان دو زن دختر یک مادربودند.۲
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
و ایشان در مصر زنا کرده، در جوانی خودزناکار شدند. در آنجا سینه های ایشان را مالیدند وپستانهای بکارت ایشان را افشردند.۳
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
و نامهای ایشان بزرگتر اهوله و خواهر او اهولیبه بود. وایشان از آن من بوده، پسران و دختران زاییدند. واما نامهای ایشان اهوله، سامره می‌باشد و اهولیبه، اورشلیم.۴
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
و اهوله از من رو تافته، زنا نمود و برمحبان خود یعنی بر آشوریان که مجاور او بودندعاشق گردید؛۵
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
کسانی که به آسمانجونی ملبس بودند؛ حاکمان و سرداران که همه ایشان جوانان دلپسند و فارسان اسب‌سوار بودند.۶
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
و به ایشان یعنی به جمیع برگزیدگان بنی آشور فاحشگی خود را بذل نمود و خود را از جمیع بتهای آنانی که بر ایشان عاشق می‌بود نجس می‌ساخت.۷
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
وفاحشگی خود را که در مصر می‌نمود، ترک نکرد. زیرا که ایشان در ایام جوانیش با او همخواب می‌شدند و پستانهای بکارت او را افشرده، زناکاری خود را بر وی می‌ریختند.۸
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
لهذا من او رابه‌دست عاشقانش یعنی به‌دست بنی آشور که اوبر ایشان عشق می‌ورزید، تسلیم نمودم.۹
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
که ایشان عورت او را منکشف ساخته، پسران ودخترانش را گرفتند. و او را به شمشیر کشتند که در میان زنان عبرت گردید و بر وی داوری نمودند.۱۰
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
«و چون خواهرش اهولیبه این را دید، درعشقبازی خویش از او زیادتر فاسد گردید وبیشتر از زناکاری خواهرش زنا نمود.۱۱
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
و بر بنی آشور عاشق گردید که جمیع ایشان حاکمان وسرداران مجاور او بودند و ملبس به آسمانجونی و فارسان اسب‌سوار و جوانان دلپسند بودند.۱۲
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
ودیدم که او نیز نجس گردیده و طریق هردوی ایشان یک بوده است.۱۳
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
پس زناکاری خود رازیاد نمود، زیرا صورتهای مردان که بر دیوارهانقش شده بود یعنی تصویرهای کلدانیان را که به شنجرف کشیده شده بود، دید.۱۴
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
که کمرهای ایشان به کمربندها بسته و عمامهای رنگارنگ برسر ایشان پیچیده بود. و جمیع آنها مانند سرداران و به شبیه اهل بابل که مولد ایشان زمین کلدانیان است بودند.۱۵
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
و چون چشم او بر آنها افتاد، عاشق ایشان گردید. و رسولان نزد ایشان به زمین کلدانیان فرستاد.۱۶
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
و پسران بابل نزد وی در بسترعشق بازی درآمده، او را از زناکاری خود نجس ساختند. پس چون خود را از ایشان نجس یافت، طبع وی از ایشان متنفر گردید.۱۷
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
و چون که زناکاری خود را آشکار کرد و عورت خود رامنکشف ساخت، جان من از او متنفر گردید، چنانکه جانم از خواهرش متنفر شده بود.۱۸
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
امااو ایام جوانی خود را که در آنها در زمین مصر زناکرده بود به یاد آورده، باز زناکاری خود را زیادنمود.۱۹
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
و بر معشوقه های ایشان عشق ورزید که گوشت ایشان، مثل گوشت الاغان و نطفه ایشان چون نطفه اسبان می‌باشد.۲۰
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
و قباحت جوانی خود را حینی که مصریان پستانهایت را به‌خاطرسینه های جوانیت افشردند به یاد آوردی.۲۱
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
«بنابراین‌ای اهولیبه خداوند یهوه چنین می‌فرماید: اینک من عاشقانت را که جانت ازایشان متنفر شده است به ضد تو برانگیزانیده، ایشان را از هر طرف برتو خواهم آورد.۲۲
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
یعنی پسران بابل و همه کلدانیان را از فقود و شوع وقوع. و همه پسران آشور را همراه ایشان که جمیع ایشان جوانان دلپسند و حاکمان و والیان و سرداران و نامداران هستند و تمامی ایشان اسب‌سوارند.۲۳
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
و با اسلحه و کالسکه‌ها و ارابه‌ها وگروه عظیمی بر تو خواهند آمد و با مجن‌ها وسپرها و خودها تو را احاطه خواهند نمود. و من داوری تو را به ایشان خواهم سپرد تا تو را برحسب احکام خود داوری نمایند.۲۴
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
و من غیرت خود را به ضد تو خواهم برانگیخت تا با تو به غضب عمل نمایند. و بینی و گوشهایت راخواهند برید و بقیه تو با شمشیر خواهند افتاد وپسران و دخترانت را خواهند گرفت و بقیه تو به آتش سوخته خواهند شد.۲۵
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
و لباس تو را از توکنده، زیورهای زیبایی تو را خواهند برد.۲۶
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
پس قباحت تو و زناکاریت را که از زمین مصرآورده‌ای، از تو نابود خواهم ساخت. و چشمان خود را بسوی ایشان بر نخواهی افراشت و دیگرمصر را به یاد نخواهی آورد.۲۷
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
زیرا خداوندیهوه چنین می‌گوید: اینک تو را به‌دست آنانی که از ایشان نفرت داری و به‌دست آنانی که جانت ازایشان متنفر است، تسلیم خواهم نمود.۲۸
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
و با تواز راه بغض رفتار نموده، تمامی حاصل تو راخواهند گرفت و تو را عریان و برهنه وا خواهم گذاشت. تا آنکه برهنگی زناکاری تو و قباحت وفاحشه گری تو ظاهر شود.۲۹
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
و این کارها را به توخواهم کرد، از این جهت که در عقب امت‌ها زنانموده، خویشتن را از بتهای ایشان نجس ساخته‌ای.۳۰
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
و چونکه به طریق خواهر خودسلوک نمودی، جام او را به‌دست تو خواهم داد.۳۱
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
و خداوند یهوه چنین می‌فرماید: جام عمیق وبزرگ خواهر خود را خواهی نوشید. و محل سخریه و استهزا خواهی شد که متحمل آن نتوانی شد.۳۲
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
و از مستی و حزن پر خواهی شد. از جام حیرت و خرابی یعنی از جام خواهرت سامره.۳۳
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
و آن را خواهی نوشید و تا ته خواهی آشامید و خورده های آن را خواهی خایید وپستانهای خود را خواهی کند، زیرا خداوند یهوه می‌گوید که من این را گفته‌ام.۳۴
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
بنابراین خداوندیهوه چنین می‌فرماید: چونکه مرا فراموش کردی و مرا پشت سر خود انداختی، لهذا تو نیز متحمل قباحت و زناکاری خود خواهی شد.»۳۵
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
و خداوند مرا گفت: «ای پسر انسان! آیابراهوله و اهولیبه داوری خواهی نمود؟ بلکه ایشان را از رجاسات ایشان آگاه ساز.۳۶
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
زیرا که زنا نموده‌اند و دست ایشان خون آلود است و بابتهای خویش مرتکب زنا شده‌اند. و پسران خودرا نیز که برای من زاییده بودند، به جهت آنها ازآتش گذرانیده‌اند تا سوخته شوند.۳۷
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
و علاوه برآن این را هم به من کرده‌اند که در همانروز مقدس مرا بی‌عصمت کرده، سبت های مرا بی‌حرمت نموده‌اند.۳۸
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
زیرا چون پسران خود را برای بتهای خویش ذبح نموده بودند، در همان روز به مقدس داخل شده، آن را بی‌عصمت نمودند و هان این عمل را در خانه من بجا آوردند.۳۹
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
بلکه نزدمردانی که از دور آمدند، فرستادید که نزد ایشان قاصدی فرستاده شد. و چون ایشان رسیدند، خویشتن را برای ایشان غسل دادی و سرمه به چشمانت کشیدی و خود را به زیورهایت آرایش دادی.۴۰
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
و بر بستر فاخری که سفره پیش آن آماده بود نشسته، بخور و روغن مرا بر آن نهادی.۴۱
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
و در آن آواز گروه عیاشان مسموع شد. وهمراه آن گروه عظیم صابیان از بیابان آورده شدندکه دستبندها بر دستها و تاجهای فاخر بر سر هردوی آنها گذاشتند.۴۲
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
و من درباره آن زنی که در زناکاری فرسوده شده بود گفتم: آیا ایشان الان بااو زنا خواهند کرد و او با ایشان؟۴۳
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
و به اودرآمدند به نهجی که نزد فاحشه‌ها درمی آیند. همچنان به آن دو زن قباحت پیشه یعنی اهوله واهولیبه درآمدند.۴۴
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
پس مردان عادل بر ایشان قصاص زنان زناکار و خونریز را خواهند رسانید، زیرا که ایشان زانیه می‌باشند و دست ایشان خون آلود است.۴۵
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
زیرا خداوند یهوه چنین می‌فرماید: من گروهی به ضد ایشان خواهم برانگیخت. و ایشان را مشوش ساخته، به تاراج تسلیم خواهم نمود.۴۶
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
و آن گروه ایشان را به سنگها سنگسار نموده، به شمشیرهای خود پاره خواهند کرد. و پسران و دختران ایشان را کشته، خانه های ایشان را به آتش خواهند سوزانید.۴۷
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
وقباحت را از زمین نابود خواهم ساخت. پس جمیع زنان متنبه خواهند شد که مثل شما مرتکب قباحت نشوند.۴۸
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
و سزای قباحت شما را بر شماخواهند رسانید. و متحمل گناهان بتهای خویش خواهید شد و خواهید دانست که من خداوندیهوه می‌باشم.»۴۹

< Ezekiel 23 >