< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ:
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
“Mũrũ wa mũndũ, nĩ kwarĩ na andũ-a-nja eerĩ, airĩtu a nyina ũmwe.
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
Nĩmatuĩkire ahũũri maraya kũu bũrũri wa Misiri, makĩambĩrĩria ũmaraya kuuma marĩ ethĩ. Marĩ kũu bũrũri-inĩ ũcio nĩmahutagio nyondo, na makahambatwo ithũri cia ũirĩtu wao.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
Ũrĩa mũkũrũ eetagwo Ohola, nake mwarĩ wa nyina eetagwo Oholiba. Maarĩ akwa, nao magĩciara aanake na airĩtu. Ohola nĩwe Samaria, nake Oholiba nĩwe Jerusalemu.
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
“Ohola nĩahũũraga ũmaraya o na arĩ wakwa; nake nĩeriragĩria endwa ake, na nĩo andũ a Ashuri, o acio maarĩ njamba cia ita
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
mehumbĩte nguo cia rangi wa bururu, na aathani na anene a ita, acio othe maarĩ andũ ethĩ ciĩrorerwa, o arĩa maathiiaga mahaicĩte mbarathi.
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
Nĩeneanire ta mũmaraya harĩ andũ othe arĩa atĩĩku thĩinĩ wa Ashuri, na agĩĩthaahia na mĩhianano yothe ya mũndũ o wothe ũrĩa eeriragĩria.
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Ndaatiganire na ũmaraya ũcio aambĩrĩirie arĩ bũrũri wa Misiri, rĩrĩa andũ maakomaga nake arĩ mwĩthĩ na makahambataga gĩthũri kĩa ũirĩtu wake, o na magĩkĩrĩrĩria kũhũũra ũmaraya nake.
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
“Nĩ ũndũ ũcio ngĩmũneana harĩ endwa ake, nĩo andũ a Ashuri o acio eeriragĩria.
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
Nĩmamũrutire nguo, makĩmũtunya ariũ na aarĩ ake, na makĩmũũraga na rũhiũ rwa njora. Nĩatuĩkire wa kuunagwo thimo gatagatĩ-inĩ ka andũ-a-nja, nake nĩ aaherithirio.
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
“Mwarĩ wa nyina Oholiba nĩeyoneire maũndũ macio, no merirĩria-inĩ make o na ũmaraya-inĩ wake nĩeekire mĩtugo mĩaganu gũkĩra mwarĩ wa nyina.
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
O nake nĩeriragĩria andũ a Ashuri, arĩa maarĩ aathani na anene a ita, na njamba cia ita ciĩhumbĩte nguo irĩ riiri, o arĩa maathiiaga mahaicĩte mbarathi, acio othe maarĩ andũ ethĩ ciĩrorerwa.
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
Nĩndonire atĩ o nake nĩethaahĩtie; eerĩ maathiiaga na mĩthiĩre ĩhaanaine.
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
“No rĩrĩ, we nĩakĩrĩrĩirie kũhũũra ũmaraya. Nĩoonire arũme makururĩtwo rũthingo-inĩ, nayo yarĩ mĩhiano ya Akalidei ĩkururĩtwo na rangi mũtune,
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
meeohete mĩcibi njohero na iremba mĩtwe icunjuurĩte; othe monekaga mahaana ta atwarithia a ngaari cia mbarathi cia ita a Babuloni, andũ a gũciarĩrwo Kalidei.
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
O rĩrĩa aamoonire, nĩamerirĩirie, akĩmatũmĩra andũ kũu Kalidei.
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
Ningĩ andũ a Babuloni magĩũka kũrĩ we, kũu kĩrĩrĩ-inĩ kĩa wendo, nao makĩmũthaahia nĩ ũndũ wa merirĩria mao. Thuutha wa gũthaahio nĩo, agĩtigana nao, akĩira ngoro nĩo.
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Rĩrĩa aathiire na mbere na ũmaraya wake atekũhitha, na akĩguũria njaga yake, niĩ na niĩ nĩndatiganire nake ngĩmũmena, ngĩtigana nake o ta ũrĩa ndaatiganire na mwarĩ wa nyina.
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
No rĩrĩ, we aakĩrĩrĩirie kũhũũra ũmaraya aaririkana matukũ marĩa aarĩ mwĩthĩ, rĩrĩa aarĩ mũmaraya kũu bũrũri wa Misiri.
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
Arĩ kũu, akĩĩrirĩria endwa ake, arĩa ciĩga ciao ciatariĩ ta cia ndigiri, na hinya wao wa ũndũrũme woimaga ta wa mbarathi.
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
Nĩ ũndũ ũcio ũkĩĩrirĩria ũũra-thoni wa wĩthĩ waku, rĩrĩa wahambatagwo gĩthũri na ũkahutio nyondo ciaku cia ũirĩtu ũrĩ kũu bũrũri wa Misiri.
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
“Nĩ ũndũ ũcio, wee Oholiba, Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Nĩngarahũra endwa aku magũũkĩrĩre, acio watiganire nao ũkĩmamena, ndĩmarehe magũũkĩrĩre kuuma mĩena yothe,
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
andũ a Babuloni na Akalidei othe, na andũ a kuuma Pekodi, na Shoa, na Koa, marĩ hamwe na andũ a Ashuri othe, aanake arĩa ciĩrorerwa, arĩa othe matuĩtwo abarũthi na anene a ita, na anene a ngaari cia mbarathi cia ita na andũ arĩa marĩ igweta inene, nao othe mathiiaga mahaicĩte mbarathi.
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
Nĩmagagũũkĩrĩra marĩ na matharaita, na ngaari cia mbarathi cia ita, na makaari, na marĩ na kĩrĩndĩ kĩingĩ; nao mabange magũũkĩrĩre kuuma mĩena yothe, marĩ na ngo iria nene na iria nini, na mekĩrĩte ngũbia cia kĩgera mĩtwe. Nĩngakũneana kũrĩ o ũherithio, nao nĩmagakũherithia kũringana na ũrĩa matuuanagĩra ciira.
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
Nĩngerekeria marakara makwa ndĩ na ũiru ngũũkĩrĩre, nao nĩmagakũherithia marĩ na marakara manene. Nĩmagagũtinia maniũrũ na matũ, nao andũ anyu arĩa magaatigara nĩmakaniinwo na rũhiũ rwa njora. Magaataha ariũ anyu na aarĩ anyu, nao arĩa anyu magaatigara nĩmakaniinwo na mwaki.
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
Ningĩ nĩmagakũruta nguo na makuue mathaga maku marĩa mega.
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
Nĩ ũndũ ũcio nĩnganiina ũũra-thoni na ũmaraya ũrĩa wee waambĩrĩirie ũrĩ kũu bũrũri wa Misiri. Ndũkarora maũndũ macio ũmerirĩrie, kana ũririkane bũrũri wa Misiri rĩngĩ.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
“Nĩgũkorwo Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Ndĩ hakuhĩ gũkũneana kũrĩ acio ũthũire, ngũneane kũrĩ acio wamenire ũkĩmahutatĩra.
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
Magaakũherithia marĩ na rũthũũro, na magũtunye indo ciaku ciothe iria ũnogeire. Magaagũtiga njaga, ũrĩ ũtheri, nacio thoni cia ũmaraya waku nĩikaguũrio. Naguo ũũra-thoni na ũmaraya waku.
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
nĩcio ikũreheire maũndũ macio, nĩgũkorwo nĩwerirĩirie ndũrĩrĩ icio, na ũgĩĩthaahia na mĩhianano yacio.
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Wee ũrũmĩrĩire mĩthiĩre ya mwarĩ wa nyũkwa; nĩ ũndũ ũcio nĩngakũnengera gĩkombe gĩake ũkĩnyiite na guoko gwaku.
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
“Mwathani Jehova ekuuga ũũ: “Wee ũkaanyuĩra gĩkombe kĩa mwarĩ wa nyũkwa, gĩkombe kĩnene na kĩriku; nĩgĩkarehe kĩnyararo na itheko, nĩgũkorwo nĩkĩiyũrĩrĩru mũno.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
Wee nĩũkaiyũrwo nĩ ũrĩĩu na kĩeha, gĩkombe kĩu kĩa mwanangĩko na ihooru, gĩkombe kĩu kĩa mwarĩ wa nyũkwa Samaria.
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Ũgaakĩnyuĩra na ũkĩinĩkĩrĩre; ũgaakĩringithia thĩ, kĩenyũkange icere, na wĩtarũrange nyondo. Nĩ niĩ njarĩtie ũhoro ũcio, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
“Nĩ ũndũ ũcio Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Kuona atĩ wee nĩũriganĩirwo nĩ niĩ na ũkanjikia na thuutha waku, no nginya ũcookererwo nĩ maciaro ma ũũra-thoni waku na ũmaraya waku.”
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
Jehova aanjĩĩrire atĩrĩ: Mũrũ wa mũndũ, nĩũgũtuĩra Ohola na Oholiba ciira? Nĩ ũndũ ũcio marũithie nĩ ũndũ wa mĩtugo yao ĩrĩ magigi,
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
nĩgũkorwo nĩmatharĩtie, namo moko mao maiyũrĩte thakame. Matharĩtie na mĩhianano yao; o na makamĩrutĩra ciana ciao magongona, iria manjiarĩire, ituĩke irio ciayo.
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
O na ningĩ ũndũ ũngĩ manjĩkĩte nĩ ũyũ: Ihinda o rĩu nĩmathaahirie handũ-hakwa-harĩa-haamũre, na magĩthũkia Thabatũ ciakwa.
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
Mũthenya o ro ũcio maarutire ciana ciao igongona kũrĩ mĩhianano yao-rĩ, noguo maatoonyire handũ-hakwa-harĩa-haamũre na makĩhathaahia. Ũguo nĩguo meekire thĩinĩ wa nyũmba yakwa.
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
“O na ningĩ magĩtũmanĩra arũme arĩa mookire kuuma kũraya, na hĩndĩ ĩrĩa maakinyire, mũgĩĩthamba nĩ ũndũ wao, na mũkĩĩhaka rangi maitho, na mũkĩĩgemia na mathaga.
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
Ningĩ mũgĩikarĩra ũrĩrĩ warĩtwo na ũkagemio mũno, na hau mbere yaguo hakaigwo metha ĩrĩa mwaigagĩrĩra ũbumba na maguta marĩa maarĩ makwa.
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
“Nake nĩarigiicĩirio nĩ kĩrĩndĩ kĩingĩ kĩanegenaga gĩtekũmaka; andũ a Sabea makĩrehwo kuuma werũ-inĩ, marĩ hamwe na gĩkundi kĩa andũ matarĩ igweta, nao magĩĩkĩra mũtumia ũcio na mwarĩ wa nyina bangiri moko, na makĩmekĩra tanji thaka mĩtwe.
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
Ningĩ ngĩaria ũhoro wa ũcio waniinĩtwo hinya nĩ ũtharia, ngiuga atĩrĩ, ‘Rĩu nĩmarekwo mamũhũthĩre ta mũmaraya, nĩgũkorwo ũguo nĩguo atariĩ.’
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
Nao magĩkoma nake. O ta ũrĩa arũme makomaga na mũmaraya, ũguo nĩguo maakomire na andũ-a-nja acio maagĩte thoni, nao nĩo Ohola na Oholiba.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
No andũ arĩa athingu nĩmakamaherithia na iherithia rĩa andũ-a-nja arĩa matharagia na magaitithia thakame, tondũ nĩmatharagia, na moko mao maiyũrĩte thakame.
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
“Mwathani Jehova ekuuga ũũ: Mareherei kĩrĩndĩ kĩmookĩrĩre, na mũmaneane maguoyohithio na matahwo.
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
Kĩrĩndĩ kĩu nĩgĩkamahũũra na mahiga nyuguto na kĩmatemange na hiũ ciao cia njora; gĩkooraga aanake na airĩtu ao, na gĩcine nyũmba ciao.
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
“Nĩ ũndũ ũcio nĩnganiina ũũra-thoni kũu bũrũri ũcio nĩguo andũ-a-nja othe makaanio, matikaneke maũndũ ma ũtharia ta inyuĩ.
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
Inyuĩ nĩmũkaherithio nĩ ũndũ wa ũũra-thoni wanyu, na mũcookererwo nĩ maciaro ma mehia manyu ma kũhooya mĩhianano. Na inyuĩ hĩndĩ ĩyo nĩmũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Mwathani Jehova.”

< Ezekiel 23 >