< Ezekiel 23 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ja minulle tuli tämä Herran sana:
2 “Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
"Ihmislapsi, oli kaksi naista, saman äidin tyttäriä.
3 Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
He harjoittivat haureutta Egyptissä; nuoruudessaan he haureutta harjoittivat. Siellä heidän rintojansa likisteltiin ja heidän neitsyellisiä nisiänsä puristeltiin.
4 Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
Heidän nimensä olivat: vanhemman Ohola ja hänen sisarensa Oholiba. Sitten he tulivat minun omikseni ja synnyttivät poikia ja tyttäriä. -Heidän nimensä: Samaria on Ohola ja Jerusalem Oholiba.
5 “Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
Mutta Ohola harjoitti haureutta, vaikka oli minun, ja himoitsi rakastajiansa, assurilaisia, naapureita,
6 Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
jotka olivat punasiniseen purppuraan puettuja ja olivat käskynhaltijoita ja päämiehiä, komeita nuorukaisia kaikki, ratsumiehiä, hevosen selässä ajajia.
7 O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
Ja hän antautui haureuteen näiden kanssa, jotka olivat Assurin valiopoikia kaikki; ja keitä vain hän himoitsi, niiden kaikkien kanssa hän saastutti itsensä kaikilla heidän kivijumalillaan.
8 kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Mutta Egyptin-aikaista haureuttansa hän ei jättänyt, sillä he olivat maanneet hänen kanssansa hänen nuoruudessaan, olivat puristelleet hänen neitsyellisiä nisiänsä ja vuodattaneet hänen ylitsensä haureuttaan.
9 “Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
Sentähden minä annoin hänet rakastajainsa käsiin, Assurin poikain käsiin, joita hän oli himoinnut.
10 Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
He paljastivat hänen häpynsä ja ottivat hänen poikansa ja tyttärensä ja tappoivat hänet itsensä miekalla, niin että hänestä tuli varoittava esimerkki muille naisille, ja panivat hänessä toimeen tuomiot.
11 “Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
Mutta hänen sisarensa Oholiba, vaikka näki tämän, oli himossaan vielä häntäkin riettaampi ja oli haureudessaan vielä riettaampi, kuin hänen sisarensa oli ollut haureudessaan.
12 Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
Hän himoitsi Assurin poikia, jotka olivat käskynhaltijoita, päämiehiä, naapureita, pulskasti puettuja, ratsumiehiä, hevosen selässä ajajia, komeita nuorukaisia kaikki.
13 Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
Silloin minä näin, että hän saastutti itsensä: sama oli tie kumpaisellakin.
14 “Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
Mutta hän meni vielä pitemmälle haureudessaan; kun hän näki seinään piirrettyjä miehiä, kaldealaisten kuvia, punavärillä piirrettyjä,
15 pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
vyö vyötettynä kupeille, päässä muhkea päähine, sankarien näköisiä kaikki, Baabelin poikain muotoisia, joiden synnyinmaa on Kaldea,
16 Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
niin hän silmän näkemältä sai himon heihin ja lähetti lähettiläitä heidän luoksensa Kaldeaan.
17 Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
Niin Baabelin pojat tulivat ja makasivat hänen kanssaan hekumassa ja saastuttivat hänet haureudellaan, niin että hän saastui heistä. Sitten hänen sielunsa vieraantui heistä.
18 Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Mutta kun hän paljasti haureutensa ja paljasti häpynsä, niin minun sieluni vieraantui hänestä, niinkuin minun sieluni oli vieraantunut hänen sisarestansa.
19 Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
Mutta hän yhä enensi haureuttaan, kun muisti nuoruutensa päivät, jolloin oli haureutta harjoittanut Egyptin maassa.
20 Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
Ja hän sai himon heidän hekumoitsijoihinsa, joilla on jäsen kuin aaseilla ja vuoto kuin orheilla.
21 Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
Ja sinä etsit nuoruutesi iljettävyyttä, jolloin egyptiläiset puristelivat nisiäsi nuorekkaiden rintojesi tähden.
22 “Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
Sentähden, Oholiba, näin sanoo Herra, Herra: Katso, minä nostatan sinun kimppuusi rakastajasi, joista sielusi on vieraantunut, ja tuon heidät sinun kimppuusi joka taholta:
23 àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
Baabelin pojat ja kaikki kaldealaiset, Pekodin, Sooan ja Kooan ja heidän kanssaan kaikki Assurin pojat-komeita nuorukaisia, käskynhaltijoita ja päämiehiä kaikki, sankareita ja mainioita miehiä, ratsumiehiä, hevosten selässä ajajia kaikki.
24 Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
He tulevat sinun kimppuusi, mukanaan paljon vaunuja ja rattaita ja suuret joukot kansoja; suurine ja pienine kilpineen ja kypäreineen he käyvät sinua vastaan joka taholta. Minä annan heille tuomiovallan, ja he tuomitsevat sinut oikeuksiensa mukaan.
25 Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
Minä osoitan sinussa kiivauteni, niin että he kohtelevat sinua tuimasti: he leikkaavat sinulta pois nenän ja korvat, ja sinun jälkeläisesi kaatuvat miekkaan. He ottavat sinun poikasi ja tyttäresi, ja sinun jälkeläisesi kuluttaa tuli.
26 Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
He raastavat sinulta vaatteesi ja ottavat korukalusi.
27 Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
Niin minä teen lopun sinun iljettävyydestäsi, jo Egyptin-aikaisesta haureudestasi; etkä sinä sitten luo silmiäsi heihin etkä enää muistele Egyptiä.
28 “Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
Sillä näin sanoo Herra, Herra: Katso, minä annan sinut niitten käsiin, joita vihaat, niitten käsiin, joista sielusi on vieraantunut.
29 Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
Ja he kohtelevat sinua vihamielisesti, ottavat kaiken vaivannäkösi ja jättävät sinut alastomaksi ja paljaaksi; ja sinun haureellinen häpysi ja iljettävyytesi ja haureutesi paljastuu.
30 Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
Näin sinulle tehdään sentähden, että uskottomana juoksit pakanain perässä, että saastutit itsesi heidän kivijumalillansa.
31 Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
Sinä vaelsit sisaresi tietä, ja minä annan hänen maljansa sinun käteesi.
32 “Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
Näin sanoo Herra, Herra: Sisaresi maljan sinä juot, syvän ja laajan ja paljon vetävän. Sinä tulet nauruksi ja pilkaksi.
33 Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
Tulet juopumusta ja murhetta täyteen: kauhun ja häviön malja on sinun sisaresi Samarian malja.
34 Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
Sen sinä juot ja särvit, sen sirpaleita sinä kaluat ja niillä rintasi revit. Sillä minä olen puhunut, sanoo Herra, Herra.
35 “Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
Sentähden, näin sanoo Herra, Herra: Koska sinä olet minut unhottanut, minut selkäsi taakse heittänyt, niin kanna myös iljettävyytesi ja haureutesi."
36 Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
Ja Herra sanoi minulle: "Ihmislapsi, etkö tuomitse Oholaa ja Oholibaa? Ilmoita heille heidän kauhistuksensa.
37 nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
Sillä he ovat rikkoneet avion, ja heidän käsissään on verta; kivijumalainsa kanssa he ovat avion rikkoneet, ja myös lapsensa, jotka he olivat minulle synnyttäneet, he ovat polttaneet, ruuaksi niille.
38 Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
Vielä tämänkin he ovat minulle tehneet: ovat samana päivänä saastuttaneet minun pyhäkköni ja rikkoneet minun sapattini.
39 Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
Teurastettuaan lapsiansa kivijumalilleen he samana päivänä tulivat minun pyhäkkööni ja niin häpäisivät sen. Katso, näin he ovat tehneet keskellä minun huonettani.
40 “Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
Vieläpä he lähettivät sanan miehille, jotka tulivat kaukaa: katso, ne tulivat siinä samassa, kun sana oli lähetetty, nuo, joita varten sinä peseydyit ja maalasit silmäluomesi ja panit päällesi korut.
41 Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
Ja sinä istuit komealle vuoteelle, sen ääressä oli katettu pöytä, ja sille sinä panit minun suitsukkeeni ja öljyni.
42 “Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
Sitten sieltä kuului suruton melu. Ihmisjoukosta otettujen miesten lisäksi tuotiin erämaasta juomareita, ja ne panivat noiden naisten käsiin rannerenkaat ja heidän päähänsä kauniit kruunut.
43 Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
Mutta minä sanoin: 'Tuollekin kuihtuneelle kelpaa aviorikos! Hänen kanssaan nyt harjoitetaan haureutta-ja vielä hänkin!'
44 Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
Hänen luoksensa tultiin, aivan kuin tullaan porttonaisen luo: niin tultiin Oholan ja Oholiban luokse-noiden iljettävien naisten.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
Mutta vanhurskaat miehet tulevat tuomitsemaan heidät sen mukaan, mitä on säädetty avionrikkoja-naisista ja mitä on säädetty verenvuodattaja-naisista; sillä he ovat rikkoneet avion, ja heidän käsissään on verta.
46 “Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
Sillä näin sanoo Herra, Herra: Nostatettakoon kansanjoukko heitä vastaan, ja heidät pantakoon kauhistukseksi ja ryöstettäköön.
47 Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
Ja kansanjoukko kivittäköön heidät ja hakatkoon kappaleiksi miekoillansa; tappakoot ne heidän poikansa ja tyttärensä ja polttakoot heidän talonsa tulella.
48 “Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
Niin minä lopetan iljettävän menon maasta. Ja kaikki naiset ottavat siitä ojentuakseen, niin etteivät harjoita iljettävää menoa, niinkuin te.
49 Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”
Teidän iljettävyytenne pannaan teidän päällenne, ja te saatte kantaa kivijumalainne kanssa tehdyt syntinne. Ja te tulette tietämään, että minä olen Herra, Herra."

< Ezekiel 23 >