< Ezekiel 22 >
Poleg tega je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
2 “Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
»Torej, človeški sin, ali boš sodil, ali boš sodil krvoločno mesto? Da, pokazal mu boš vse njegove ogabnosti.
3 Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
Potem reci: ›Tako govori Gospod Bog: ›Mesto v svoji sredi preliva kri, da lahko pride njegov čas in zoper sebe izdeluje malike, da se omadežuje.
4 Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
Postalo si krivo v svoji krvi, ki si jo prelilo; in omadeževalo si se s svojimi maliki, ki si jih naredilo; in svojim dnevom si povzročilo, da so se približali in prišlo si celó k svojim letom. Zato sem te naredil za grajo poganom in zasmeh vsem deželam.
5 Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
Tisti, ki so blizu in tisti, ki so daleč od tebe, te bodo zasmehovali, ki so neslavni in precej nadležni.
6 “‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
Glej, Izraelovi princi, vsak je bil v tebi k njihovi moči, da preliva kri.
7 Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
V tebi so prezirali očeta in mater. V tvoji sredi so z zatiranjem postopali s tujcem. V tebi so nadlegovali osirotelega in vdovo.
8 Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
Preziralo si moje svete stvari in oskrunilo moje šabate.
9 Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
V tebi so ljudje, ki prenašajo govorice, da prelijejo kri; in v tebi jedo po gorah. V tvoji sredi zagrešujejo nespodobnost.
10 Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
V tebi so odkrili nagoto svojih očetov. V tebi so ponižali tisto, ki je bila oddvojena zaradi oskrunitve.
11 Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
In nekdo je zagrešil ogabnost z ženo svojega soseda; in drugi je opolzko omadeževal svojo snaho; in drugi je v tebi ponižal svojo sestro, hčer svojega očeta.
12 Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
V tebi so jemali darila, da prelijejo kri. Jemalo si obresti in donos in z izsiljevanjem si lakomno pridobivalo od svojih sosedov in si me pozabilo, ‹ govori Gospod Bog.
13 “‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
›Glej, zato sem udaril svojo roko ob tvoj nepošten dobiček, ki si ga naredilo in pri tvoji krvi, ki je bila v tvoji sredi.
14 Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
Ali tvoje srce lahko prenese, ali so tvoje roke lahko močne v dneh, ko bom obračunal s teboj? Jaz, Gospod sem to govoril in bom to storil.
15 Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
In razkropil te bom med pogane in te razpršil v dežele in iz tebe použil tvojo umazanost.
16 Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
In vzelo boš svojo dediščino v sebi, pred očmi poganov in vedelo boš, da jaz sem Gospod.‹«
17 Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
In k meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
18 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
»Človeški sin, Izraelova hiša mi je postala žlindra. Vsi so bron, kositer, železo in svinec v sredi talilne peči; so celó srebrova žlindra.
19 Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
Zato tako govori Gospod Bog: ›Ker ste vsi postali žlindra, glejte, zato vas bom zbral v sredi [prestolnice] Jeruzalem.
20 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
Kakor oni zbirajo srebro in bron in železo in svinec in kositer v sredi talilne peči, da nanjo pihajo ogenj, da to raztalijo; tako vas bom jaz zbral v svoji jezi in svoji razjarjenosti in vas bom pustil tam in vas raztalil.
21 Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
Da, zbral vas bom in pihal nad vas v ognju svojega besa in vi boste raztaljeni v njeni sredi.
22 Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
Kakor je srebro raztaljeno v sredi talilne peči, tako boste raztaljeni v njeni sredi in spoznali boste, da sem jaz, Gospod, nad vas izlil svojo razjarjenost.‹«
23 Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
In k meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
24 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
»Človeški sin, reci ji: ›Ti si dežela, ki ni očiščena niti ni nanjo deževalo na dan ogorčenja.
25 Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
Tam je zarota njenih prerokov v njeni sredi, podobna rjovenju leva, željnega plena. Požrli so duše, vzeli so zaklad in dragocene stvari; v njeni sredi so naredili mnogo vdov.
26 Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
Njeni duhovniki so prekršili mojo postavo in oskrunili moje svete stvari. Niso pokazali nobene razlike med svetim in oskrunjenim niti niso pokazali razlike med nečistim in čistim in svoje oči so skrili pred mojimi šabati in jaz sem med njimi oskrunjen.
27 Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
Njeni princi v njeni sredi so podobni volkovom, željnim plena, da prelijejo kri in da uničijo duše, da pridobijo nepošten dobiček.
28 Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
In njeni preroki so jih ometali z neutrjeno malto, gledoč ničnost in vedeževali so jim laži, rekoč: ›Tako govori Gospod Bog, ‹ ko Gospod ni govoril.
29 Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
Ljudstvo dežele je uporabljalo zatiranje in izvajalo rop in jezilo revne in pomoči potrebne; da, krivično so zatirali tujca.
30 “Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
In iskal sem človeka med njimi, ki bi naredil ograjo in stal v razpoki pred menoj za deželo, da je ne bi uničil, toda nikogar nisem našel.
31 Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Zato sem nadnje izlil svoje ogorčenje; použil sem jih z ognjem svojega besa. Njihovo lastno pot sem poplačal na njihovih glavah, ‹ govori Gospod Bog.‹«