< Ezekiel 22 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
Și tu, fiu al omului, vei judeca, vei judeca tu cetatea sângeroasă? Da, fă-o să cunoască toate urâciunile ei.
3 Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
Atunci să spui: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Cetatea varsă sânge în mijlocul ei, ca să vină timpul ei și își face idoli împotriva ei însăși pentru a se pângări.
4 Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
Tu ai devenit vinovată în sângele tău pe care l-ai vărsat; și te-ai pângărit în idolii tăi pe care i-ai făcut; și ai făcut ca zilele tale să se apropie și ai ajuns la anii tăi; de aceea te-am făcut ocară pentru păgâni și batjocură pentru toate țările.
5 Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
[Cei de] aproape și [cei de] departe de tine te vor batjocori, [pe tine care ești] mârșavă [și] mult chinuită.
6 “‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
Iată, prinții lui Israel, fiecare, au fost în tine ca să verse sânge după puterea lor.
7 Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
În tine au disprețuit pe tată și pe mamă; în mijlocul tău s-au purtat cu oprimare cu străinul; în tine au chinuit pe cel fără tată și pe văduvă.
8 Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
Ai disprețuit lucrurile mele sfinte și ai pângărit sabatele mele.
9 Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
În tine sunt oameni defăimători pentru a vărsa sânge; și în tine ei mănâncă pe munți; în mijlocul tău ei lucrează cu desfrânare.
10 Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
În tine au descoperit ei goliciunea tatălui lor; în tine au umilit pe cea care era pusă deoparte din cauza murdăriei.
11 Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
Și unul a făcut urâciune cu soția aproapelui său; și un altul a pângărit-o cu desfrânare pe nora lui; iar un altul în tine a umilit-o pe sora sa, pe fiica tatălui său.
12 Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
În tine au luat ei daruri pentru a vărsa sânge; ai luat camătă și dobândă și ai câștigat cu lăcomie de la aproapele tău prin jecmănire și pe mine m-ai uitat, spune Domnul DUMNEZEU.
13 “‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
Iată, de aceea am bătut din mâna mea la câștigul tău necinstit pe care l-ai câștigat și la sângele tău care a fost în mijlocul tău.
14 Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
Poate inima ta să îndure sau pot mâinile tale să fie tari, în zilele în care mă voi ocupa de tine? Eu DOMNUL am vorbit aceasta și [o] voi face.
15 Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
Și te voi împrăștia printre păgâni și te voi risipi în țări și voi mistui necurăția din tine.
16 Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
Și îți vei lua moștenirea în tine însuți înaintea ochilor păgânilor și vei cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
17 Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Și cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
18 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
Fiu al omului, casa lui Israel a devenit pentru mine [ca o] zgură; ei toți [sunt] aramă și cositor și fier și plumb în mijlocul cuptorului; ei sunt zgura argintului.
19 Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că toți ați devenit zgură, iată, de aceea vă voi aduna în mijlocul Ierusalimului.
20 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
[Precum] ei adună argint și aramă și fier și plumb și cositor în mijlocul cuptorului, pentru a sufla focul asupra lor, să [le] topească; tot astfel vă [voi] aduna în mânia mea și în furia mea și vă [voi] lăsa [acolo] și vă voi topi.
21 Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
Da, vă voi aduna și voi sufla asupra voastră în focul mâniei mele și veți fi topiți în mijlocul lui.
22 Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
Precum este topit argintul în mijlocul cuptorului, tot astfel veți fi topiți în mijlocul lui; și veți cunoaște că eu, DOMNUL, mi-am turnat furia asupra voastră.
23 Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Și cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
24 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
Fiu al omului, spune-i ei: Tu [ești] țara necurățită, fără ploaie în ziua indignării.
25 Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
[Este] o uneltire a profeților ei în mijlocul ei, ca un leu care răcnește, sfâșiind prada; ei au mâncat suflete; au luat tezaurul și lucrurile prețioase; i-au făcut multe văduve în mijlocul ei.
26 Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
Preoții ei au violat legea mea și au spurcat lucrurile mele sfinte; nu au făcut deosebire între [ce este] sfânt și [ce] nu [este] sfânt, nici nu au arătat [deosebire] dintre necurat și curat și și-au ascuns ochii de la sabatele mele și eu sunt spurcat printre ei.
27 Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
Prinții ei în mijlocul ei [sunt] ca lupi sfâșiind prada, pentru a vărsa sânge [și] pentru a nimici suflete, pentru a obține câștig necinstit.
28 Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
Și profeții ei i-au tencuit cu [mortar] nestins, văzând deșertăciune și ghicindu-le minciuni, spunând: Astfel spune Domnul DUMNEZEU, când DOMNUL nu a vorbit.
29 Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
Poporul țării a lucrat cu oprimare și a practicat hoția și au chinuit pe cel sărac și pe cel nevoiaș; da, ei au oprimat pe străin pe nedrept.
30 “Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
Și eu am căutat un om printre ei, care să facă îngrăditura și să stea neclintit în spărtură, înaintea mea, pentru țară, ca să nu o distrug; dar nu am găsit pe nimeni.
31 Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
De aceea mi-am turnat indignarea asupra lor; i-am mistuit cu focul mâniei mele; le-am întors calea asupra capului lor, spune Domnul DUMNEZEU.

< Ezekiel 22 >