< Ezekiel 22 >
Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces mots:
2 “Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
Et toi, fils de l'homme, jugeras-tu, jugeras-tu la ville sanguinaire? et fais-lui connaître toutes ses abominations
3 Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
et dis: Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Ville, qui verses le sang dans ton sein, pour que ton moment arrive, et qui fais, des idoles pour te souiller!
4 Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
Par le sang que tu as versé, tu t'es rendue coupable, et par les idoles que tu as faites, tu t'es souillée, et as fait avancer le terme de tes jours, et tu es parvenue au terme de tes années. C'est pourquoi je te livre aux outrages des nations, et à la dérision de tous les pays;
5 Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
lointains et rapprochés ils te tourneront en dérision, comme portant un nom souillé, comme pleine de trouble.
6 “‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
Voici, les princes d'Israël sont au dedans de toi, chacun selon son pouvoir occupés à répandre le sang.
7 Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
Pour père et pour mère ils montrent du mépris au dedans de toi; à l'étranger ils font sentir l'oppression dans ton sein; envers l'orphelin et la veuve ils sont violents au milieu de toi.
8 Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
Tu méprises mes sanctuaires, et profanes mes sabbats.
9 Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
Il se trouve en toi des calomniateurs pour répandre le sang; et sur les montagnes ils prennent part aux banquets au milieu de toi; ils commettent le crime dans ton sein.
10 Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
On découvre au milieu de toi la nudité d'un père, ils jouissent des femmes pendant leur souillure au milieu de toi.
11 Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
Chacun commet des infamies avec la femme de son prochain, et chacun souille sa bru par l'inceste, et chacun jouit de sa sœur, fille de son père, au milieu de toi.
12 Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
Dans ton sein ils reçoivent des présents, pour répandre le sang; tu reçois une usure et un intérêt, et portes dommage à ton prochain par des exactions, et moi tu m'oublies, dit le Seigneur, l'Éternel.
13 “‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
Voici, je frappe dans mes mains à cause de la cupidité à laquelle tu te livres, et du sang versé qui est dans ton sein.
14 Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
Ton cœur tiendra-t-il? tes mains resteront-elles fermes dans les jours où j'agirai contre toi? Moi, l'Éternel, je le dis et le ferai:
15 Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
je te disperserai parmi les peuples et te disséminerai dans les pays divers, et du milieu de toi j'exterminerai ta souillure,
16 Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
et ce sera par toi que tu seras souillée aux yeux des peuples, et tu sauras que je suis l'Éternel.
17 Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces mots:
18 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
Fils de l'homme, la maison d'Israël est devenue pour moi une scorie; tous ils sont de l'airain, et de l'étain, et du fer, et du plomb dans le fourneau; ils sont une scorie d'argent.
19 Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
Aussi ainsi parle le Seigneur, l'Éternel: Parce que vous êtes tous devenus scories, pour cela, voici, je vous ramasserai au milieu de Jérusalem.
20 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
De même qu'on rassemble l'argent, et l'airain, et le fer, et le plomb, et l'étain dans le fourneau, pour y souffler le feu afin d'en faire la fusion; ainsi je vous rassemblerai dans ma colère et dans mon courroux, et je vous y mettrai pour vous fondre.
21 Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
Oui, je vous ramasserai, et soufflerai contre vous le feu de ma fureur, afin que vous y fondiez.
22 Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
Comme on fond l'argent au fourneau, ainsi vous serez fondus au milieu d'elle, afin que vous sachiez que c'est moi, l'Éternel, qui verse ma fureur sur vous.
23 Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Et la parole de l'Éternel me fut adressée en ces mots:
24 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
Fils de l'homme, dis à la ville: Tu es une terre qui n'est pas nettoyée, et n'aura pas ses pluies au jour de la colère.
25 Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
Il y a conspiration de ses prophètes au milieu d'elle; pareils au lion rugissant déchirant une proie, ils dévorent des âmes, prennent ce qui est riche et précieux, et font au milieu d'elle un grand nombre de veuves.
26 Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
Ses prêtres violent ma loi et profanent mes sanctuaires; entre ce qui est sacré et ce qui est profane, ils ne font nulle différence, et n'enseignent pas la différence qui est entre le pur et l'immonde, et sur mes sabbats ils ferment les yeux, et je suis déshonoré au milieu d'eux.
27 Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
Ses princes sont au milieu d'elle comme des loups ravissants, ils versent le sang, perdent les âmes, par l'avidité du gain.
28 Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
Et ses prophètes les recouvrent de plâtre, ont de fausses visions et leur donnent des présages menteurs, disant: « Ainsi parle le Seigneur, l'Éternel! » tandis que l'Éternel ne leur a point parlé.
29 Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
Le peuple du pays commet des violences, exerce des rapines, opprime l'affligé et l'indigent, et sur l'étranger commet des violences injustement.
30 “Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
J'ai cherché parmi eux un homme qui élevât une muraille, et montât à la brèche au-devant de moi en faveur du pays, pour que je ne le détruise pas, mais je ne l'ai pas trouvé.
31 Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
Aussi vais-je verser ma colère sur eux, les consumer par le feu de mon courroux, et faire retomber leurs œuvres sur leur tête, dit le Seigneur, l'Éternel.