< Ezekiel 22 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
And the word of the Lord was maad to me,
2 “Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
and he seide, And thou, sone of man, whether thou demest not the citee of bloodis?
3 Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
And thou schalt schewe to it alle hise abhomynaciouns, and thou schalt seie, The Lord God seith these thingis, This is a citee schedinge out blood in the myddis of it silf, that the tyme therof come; and which made idols ayens it silf, that it shulde be defoulid.
4 Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
In thi blood which is shed out of thee, thou trespassidist, and thou art defoulid in thin idols whiche thou madist; and thou madist thi daies to neiye, and thou brouytist the time of thi yeeris. Therfor Y yaf thee schenschipe to hethene men, and scornyng to alle londis that ben niy thee,
5 Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
and that ben fer fro thee; thou foul citee, noble, greet in perisching, thei schulen haue victorie of thee.
6 “‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
Lo! princes of Israel, alle in her arm, weren in thee, to schede out blood.
7 Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
Thei punyschiden with wrongis fadir and modir in thee, thei calengiden falsli a comelyng in the myddis of thee, thei maden sori a fadirles child and a widewe at thee.
8 Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
Ye dispisiden my seyntuaries, and ye defouliden my sabatis.
9 Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
Men bacbiteris weren in thee, to schede out blood, and eten on hillis in thee; thei wrouyten greet trespas in the myddis of thee.
10 Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
Thei vnhiliden the schamefulere thingis of the fadir in thee, thei maden low in thee the vnclenesse of a womman in vnclene blood.
11 Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
And ech man wrouyte abhomynacioun ayens the wijf of his neiybore, and the fadir of the hosebonde defoulide his sones wijf vnleuefuli; a brother oppresside in thee his sister, the douytir of his fadir.
12 Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
Thei token yiftis at thee, to schede out blood; thou tokist vsure and ouerabundaunce, and thou calengidist greedili thi neiyboris, and thou hast foryete me, seith the Lord God.
13 “‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
Lo! Y haue smyte togidere myn hondis on thin aueryce, which thou didist, and on the blood which is sched out in the myddis of thee.
14 Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
Whether thin herte schal susteyne, ether thin hondis schulen haue power in the daies whiche Y schal make to thee? For Y the Lord spak, and Y schal do.
15 Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
And Y schal scatere thee in to naciouns, and Y schal wyndewe thee in to londis; and Y schal make thin vnclennesse to faile fro thee,
16 Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
and Y schal welde thee in the siyt of hethene men; and thou schalt wite, that Y am the Lord.
17 Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
And the word of the Lord was maad to me, and he seide,
18 “Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
Thou, sone of man, the hous of Israel is turned to me in to dros, ether filthe of irun; alle these ben bras, and tyn, and irun, and leed, in the myddis of furneis, thei ben maad the dros of siluer.
19 Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
Therfor the Lord God seith these thingis, For that alle ye ben turned in to dros, lo! Y schal gadere you togidere in the myddis of Jerusalem,
20 Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
bi gadering togidere of siluer, and of latoun, and of irun, and of tyn, and of leed, in the myddis of furneis; and Y schal kindle ther ynne a fier, to welle togidere; so Y schal gadere you togidere in my strong veniaunce, and in my wraththe, and Y schal reste. And Y schal welle you togidere,
21 Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
and Y schal gadere you togidere, and Y schal sette you a fier in the fier of my strong veniaunce, and ye schulen be wellid togidere in the myddis therof.
22 Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
As siluer is wellid togidere in the myddis of a furneis, so ye schulen be in the myddis therof; and ye schulen wite, that Y am the Lord, whanne Y haue sched out myn indignacioun on you.
23 Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
And the word of the Lord was maad to me,
24 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
and he seide, Sone of man, seie thou to it, Thou art a lond vncleene, and not bireyned in the dai of strong veniaunce.
25 Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
Sweringe togidere, ether conspiringe of profetis is in the myddis therof; as a lioun roringe and takinge prei, thei deuouriden men, thei token richessis and prijs; thei multiplieden widewis therof in the myddis therof.
26 Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
Preestis therof dispisiden my lawe, and defouliden my seyntuaries; thei hadden not difference bitwixe hooli thing and vnhooli, thei vndurstoden not bitwixe defoulid thing and cleene thing; and thei turneden awei her iyen fro my sabatis, and Y was defoulid in the myddis of hem.
27 Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
The princes therof in the myddis therof weren as wolues rauyschinge prey, to schede out blood, and to leese men, and in suynge lucris gredili.
28 Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
Forsothe the profetis therof pargetiden hem with out temperure, and seyen veyn thingis, and dyuyneden leesingis to hem, and seiden, The Lord God seith these thingis, whanne the Lord spak not.
29 Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
The puples of the lond calengiden fals caleng, and rauyschiden bi violence; thei turmentiden a nedi man and pore, and oppressiden a comeling bi fals caleng, with out doom.
30 “Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
And Y souyte of hem a man, that schulde sette an hegge bitwixe, and stonde set ayens me for the lond, that Y schulde not distrie it, and Y foond not.
31 Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
And Y schedde out on hem myn indignacioun, and Y wastide hem in the fier of my wraththe; Y yeldide the weie of hem on the heed of hem, seith the Lord God.

< Ezekiel 22 >