< Ezekiel 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
In k meni je prišla Gospodova beseda, rekoč:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
»Človeški sin, naravnaj svoj obraz proti Jeruzalemu in spusti svojo besedo proti svetim krajem in prerokuj zoper Izraelovo deželo
3 Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
in reci Izraelovi deželi: ›Tako govori Gospod: ›Glej, jaz sem zoper tebe in izvlekel bom svoj meč iz nožnice in iz tebe bom iztrebil pravičnega in zlobnega.
4 Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
Ker bom iz tebe iztrebil pravičnega in zlobnega, bo zato moj meč šel iz nožnice zoper vse meso od juga do severa,
5 Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
da bo lahko vse meso vedelo, da sem jaz, Gospod, izvlekel svoj meč iz nožnice. Ta se ne bo več vrnil.
6 “Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
Zdihuj torej, ti, človeški sin, s trganjem svojih ledij; in z grenkim vzdihom pred njihovimi očmi.
7 Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
In zgodilo se bo, ko ti bodo rekli: ›Zakaj vzdihuješ?‹ da boš odgovoril: ›Zaradi novic, ker le-te prihajajo.‹ In vsako srce se bo stopilo in vse roke bodo slabotne in vsak duh bo medlel in vsa kolena bodo šibka kakor voda. Glej, to prihaja in se bo zgodilo, ‹ govori Gospod Bog.«
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
Ponovno je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
9 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
»Človeški sin, prerokuj in reci: ›Tako govori Gospod: ›Reci: ›Meč, meč je nabrušen in tudi zglajen.
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
Nabrušen je, da naredi boleč pokol; zglajen je, da se lahko lesketa. Naj bi se mi potem razveseljevali? Ta zaničuje palico mojega sina kakor vsako drevo.
11 “‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
In on ga je dal zgladiti, da bi lahko z njim rokoval. Ta meč je nabrušen in zglajen, da ga da v roko ubijalca.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
Jokaj in tuli, človeški sin, kajti ta bo nad mojim ljudstvom, ta bo nad Izraelovimi princi. Strahote zaradi meča bodo nad mojim ljudstvom. Udari torej na svoje stegno.
13 “‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
Ker je to preizkušnja in kaj če meč zaničuje celo palico? To ne bo več, ‹ govori Gospod Bog.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
›Ti torej, človeški sin, prerokuj in zaploskaj s svojima rokama in naj bo meč tretjič podvojen, meč umorjenih. To je meč velikih ljudi, ki so umorjeni, ki vstopa v njihove skrivne sobe.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
Konico meča sem naravnal zoper vsa njihova velika vrata, da bo njihovo srce lahko slabelo in [bodo] njihovi propadi pomnoženi. Ah! Narejen je [da se] lesketa, zavit je za pokol.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
Pojdi eno pot ali drugo, ali na desno ali na levo, kamor je naravnan tvoj obraz.
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
Tudi jaz bom plosknil s svojima rokama in bom umiril svojo razjarjenost. Jaz, Gospod, sem to govoril.‹«
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
Ponovno je prišla k meni Gospodova beseda, rekoč:
19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
»Tudi ti, človeški sin, si določi dve poti, da bo lahko prišel meč babilonskega kralja. Obe bosta izšli iz ene dežele in izberi kraj, izberi ga ob začetku poti v mesto.
20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
Določi pot, da lahko pride meč v Rabo Amóncev in v Juda in zaščiteno [prestolnico] Jeruzalem.
21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
Kajti babilonski kralj je stal pri razpotju poti, ob začetku dveh poti, da uporabi vedeževanje. Svoje puščice je posvetlil, posvetoval se je z družinskimi maliki, gledal je v jetra.
22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
Pri njegovi desni roki je bilo vedeževanje za [prestolnico] Jeruzalem, da določi častnike, da odpre usta v pokol, da povzdigne glas s kričanjem, da določi oblegovalne ovne proti velikim vratom, da nasuje nasip in da zgradi utrdbo.
23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
In to jim bo kakor napačno vedeževanje v njihovem pogledu, tistim, ki so prisegli prisege, toda v spomin bo priklical krivičnost, da bodo lahko zajeti.‹
24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
Zato tako govori Gospod Bog: ›Ker ste storili, da se bo spominjalo vaše krivičnosti v tem, da so vaši prestopki odkriti, tako da se pri vseh vaših dejanjih pojavijo vaši grehi; ker jaz pravim, da ste prišli v spomin, boste zajeti z roko.
25 “‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
In ti, oskrunjen, zloben Izraelov princ, katerega dan je prišel, ko se krivičnosti naredi konec, ‹
26 èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
tako govori Gospod Bog: ›Odstrani diadem in snemi krono. To ne bo [več] isto. Povišaj tistega, ki je nizek in ponižaj tistega, ki je visok.
27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
Jaz bom to preobrnil, preobrnil, preobrnil in tega ne bo nič več, dokler ne pride tisti, katerega pravica je to in njemu jo bom izročil.‹
28 “Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
Ti pa, človeški sin, prerokuj in reci: ›Tako govori Gospod Bog glede Amóncev in glede njihove graje; celo reci: ›Meč, meč je izvlečen. Za pokol je zglajen, da použiva zaradi lesketanja.
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
Medtem ko zate vidijo ničnost, medtem ko ti vedežujejo laž, da te privedejo nad vratove tistih, ki so umorjeni izmed zlobnih, katerih dan je prišel, ko bo njihova krivičnost končana.
30 “‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
Ali mu bom povzročil, da se vrne v svojo nožnico? Sodil te bom na kraju, kjer si bil ustvarjen, v deželi tvojega rojstva.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
In nate bom izlil svoje ogorčenje in zoper tebe bom pihal v ognju svojega besa in te izročil v roko brutalnežev in veščih, da uničujejo.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”
Ti boš za gorivo ognju; tvoja kri bo v sredi dežele; ne bo se te več spominjalo, kajti jaz, Gospod, sem to govoril.‹«

< Ezekiel 21 >