< Ezekiel 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
Synu człowieczy, odwróć swoją twarz w stronę Jerozolimy i krop [swoją mowę] ku świętym miejscom, i prorokuj przeciwko ziemi Izraela;
3 Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
Powiedz ziemi Izraela: Tak mówi Pan BÓG: Oto ja [jestem] przeciwko tobie i dobędę swój miecz z pochwy, i wytnę spośród ciebie sprawiedliwego i bezbożnego.
4 Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
Ponieważ wytnę spośród ciebie sprawiedliwego i bezbożnego, mój miecz wyjdzie ze swej pochwy przeciwko wszelkiemu ciału od południa [aż] do północy.
5 Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
I pozna wszelkie ciało, że ja, PAN, dobyłem swój miecz z pochwy i już [do niej] nie wróci.
6 “Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
A ty, synu człowieczy, wzdychaj, jakbyś miał złamane biodro, w goryczy wzdychaj na ich oczach.
7 Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
A gdy zapytają: Dlaczego wzdychasz? – to odpowiesz: Z powodu wieści, która nadchodzi, bo każde serce się rozpłynie, wszystkie ręce osłabną, wszelki duch omdleje i wszystkie kolana rozpłyną się [jak] woda. Oto nadchodzi to i stanie się, mówi Pan BÓG.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
I doszło do mnie słowo PANA:
9 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
Synu człowieczy, prorokuj i mów: Tak mówi PAN. Mów: Miecz, miecz jest wyostrzony i wypolerowany.
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
Wyostrzony, aby dokonać rzezi, wypolerowany, aby lśnił. Czy mamy się cieszyć? Gdyż gardzi rózgą mego syna jak każdym drzewem.
11 “‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
Dał go na wypolerowanie, aby mógł być ujęty w dłoń, ten miecz jest wyostrzony, jest też wypolerowany, aby dać go w ręce zabójcy.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
Wołaj i zawódź, synu człowieczy, gdyż ten [miecz] będzie przeciwko memu ludowi, przeciwko wszystkim książętom Izraela. Strach miecza przyjdzie na mój lud, dlatego uderz się w biodro.
13 “‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
Jest to bowiem próba, a cóż jeśli [miecz] będzie gardzić rózgą? Już jej nie będzie, mówi Pan BÓG.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
Ty więc, synu człowieczy, prorokuj i bij dłonią o dłoń. Niech przyjdzie miecz drugi i trzeci raz, miecz zabitych, ten wielki miecz zabitych, przenikający aż do ich komnat.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
Postawiłem strach miecza we wszystkich ich bramach, aby ich serce się rozpłynęło i pomnożyły się ich upadki. Ach! [Jest] wypolerowany, aby błyszczeć, wyostrzony, aby zabić.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
Zbierz się, [mieczu], udaj się w prawo i w lewo, dokądkolwiek twoja twarz jest zwrócona.
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
Ja również uderzę dłonią o dłoń i uspokoję swoją zapalczywość. Ja, PAN, [to] powiedziałem.
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
Potem [znowu] doszło do mnie słowo PANA mówiące:
19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
A ty, synu człowieczy, wyznacz sobie dwie drogi, którymi ma przyjść miecz króla Babilonu. Obie niech wychodzą z jednej ziemi, wybierz miejsce na rozstaju dróg wiodących do miasta, wybierz je.
20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
Wyznacz drogę, którą ma przyjść miecz: do Rabby synów Ammona i do Judy w obwarowanej Jerozolimie.
21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
Król Babilonu bowiem stanął na rozdrożu, na początku dwóch dróg, aby zasięgnąć wróżby: polerował strzały, radził się bożków, patrzył na wątrobę.
22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
Wyrocznia wskazała na jego prawą rękę, na Jerozolimę, aby szykował dowódców, którzy mieli wydać rozkaz rzezi i podnieść okrzyk bojowy, aby ustawić tarany pod bramami, aby usypać wał i budować szańce.
23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
I w ich oczach będzie to fałszywa wróżba, gdyż zobowiązali się przysięgami, lecz on im przypomni ich nieprawość, aby zostali pojmani.
24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Ponieważ przypominacie mi swoją nieprawość, odsłaniając wasze przestępstwo tak, że wasze grzechy są jawne we wszystkich waszych czynach – ponieważ przypominacie mi [o tym], zostaniecie pojmani tą ręką.
25 “‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
A ty, nieczysty bezbożniku, księciu Izraela, którego dzień nadejdzie, gdy nastanie koniec ich nieprawości;
26 èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
Tak mówi Pan BÓG: Zdejmij diadem, zrzuć koronę. Ta już nigdy taka nie będzie. To, co niskie, będzie wywyższone, a to, co wysokie, będzie poniżone.
27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
Wniwecz, wniwecz, wniwecz ją obrócę. I już jej nie będzie, aż przyjdzie ten, który [do niej] ma prawo, i jemu ją oddam.
28 “Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
Ale ty, synu człowieczy, prorokuj i mów: Tak mówi Pan BÓG o synach Ammona i o ich hańbie. Powiedz: Miecz, miecz jest dobyty, jest wypolerowany na rzeź, błyszczy, aby wytracić wszystko;
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
Chociaż opowiadają ci złudne widzenia i wróżą kłamstwo, aby cię przyłożyć do szyi bezbożnych pobitych, których dzień nadejdzie, gdy nastanie koniec ich nieprawości.
30 “‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
Schowaj [jednak miecz] do pochwy. Będę cię sądził w miejscu, gdzie zostałeś stworzony, w ziemi twego pochodzenia.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
I wyleję na ciebie swoją zapalczywość, tchnę przeciwko tobie ogniem swojego gniewu i wydam cię w ręce okrutnych ludzi i wprawnych w wytraceniu.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”
Staniesz się strawą dla ognia, twoja krew będzie [rozlana] po całej ziemi, nie będziesz [już] wspominany, bo ja, PAN, to powiedziałem.

< Ezekiel 21 >