< Ezekiel 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
Da kom Herrens ord til mig, og det lød så:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
Menneskesønn! Vend ditt åsyn mot Jerusalem og prek mot helligdommene og spå mot Israels land!
3 Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
Og si til Israels land: Så sier Herren: Se, jeg kommer over dig og drar mitt sverd av skjeden, og jeg vil utrydde både rettferdige og ugudelige i dig.
4 Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
Fordi jeg vil utrydde både rettferdige og ugudelige i dig, derfor skal mitt sverd fare ut av skjeden mot alt kjød, fra syd til nord.
5 Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
Og alt kjød skal kjenne at jeg, Herren, har draget mitt sverd av skjeden; det skal ikke mere vende tilbake.
6 “Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
Men du, menneskesønn, skal sukke så det bryter i dine lender; i sår verk skal du sukke for deres øine.
7 Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Og når de da sier til dig: Hvorfor sukker du? - da skal du svare: Over en tidende; for den kommer, og da skal hvert hjerte smelte og alle hender synke og hver ånd bli sløv og alle knær bli som vann; se, det kommer, og det skal skje, sier Herren, Israels Gud.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
9 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
Menneskesønn! Spå og si: Så sier Herren: Si: Et sverd, et sverd er hvesset, og slipt er det og.
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
Til å slakte er det hvesset, til å lyne er det slipt. Eller skulde vi glede oss, du min sønns stamme som forakter alt tre?
11 “‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
Det skulde slipes for å tas i hånd; det er hvesset dette sverd, og det er slipt for å gis i en drapsmanns hånd.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
Skrik og hyl, menneskesønn! For det kommer over mitt folk, det kommer over alle Israels fyrster; de blir overgitt til sverdet sammen med mitt folk. Derfor slå dig på lenden!
13 “‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
For en prøvelse er for hånden, og hvad skulde den ramme, om ikke den stamme som forakter tukt? sier Herren, Israels Gud.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
Og du menneskesønn, spå og slå hendene sammen! Dobbelt, ja tredobbelt kommer sverdet, det sverd som slår mange ihjel, dette sverd som slår den store ihjel, det som truer dem på alle kanter.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
Forat hjertene skal smelte og anstøtene bli mange, setter jeg et blinkende sverd mot alle dets porter; akk, det er gjort til å lyne, skjerpet til å slakte.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
Ta dig sammen og hugg til høire! Vend dig og hugg til venstre! Dit hvor din egg er bestemt!
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
Også jeg vil slå hendene sammen og stille min harme; jeg, Herren, har talt.
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
Og du menneskesønn, gjør dig to veier, som kongen av Babels sverd kan fare frem på! Fra ett land skal de begge gå ut, og du skal risse en hånd - risse den ved begynnelsen av veien til hver by!
20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
En vei skal du gjøre som sverdet kan fare frem på til Rabba i ammonittenes land, og en til Juda, inn i Jerusalem, den faste by.
21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
For Babels konge står på veiskjellet, ved begynnelsen av de to veier, for å la sig spå; han ryster pilene, han spør husgudene, han ser på leveren.
22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
I sin høire hånd får han loddet: Jerusalem; der skal han stille op murbrekkere, åpne munnen til krigsskrik, lufte røsten med hærrop - stille op murbrekkere mot portene, kaste op en voll og bygge skanser.
23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
Men dette er i deres øine bare en tom spådom; de har jo de helligste eder. Men han minner om deres misgjerning, forat de skal gripes.
24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Fordi I selv minner om eders misgjerning, idet eders overtredelser åpenbares, så eders synder viser sig i alle eders gjerninger - fordi jeg således blir minnet om eder, skal I gripes med hånden.
25 “‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
Og du dødsdømte, du ugudelige, du Israels fyrste, hvis dag er kommet når den misgjerning er skjedd som fører til undergang!
26 èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
Så sier Herren, Israels Gud: Ta huen bort og løft kronen av! Det som nu er, skal ikke være mere; det lave skal ophøies, og det høie skal fornedres.
27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
Jeg vil vende op ned, op ned, op ned på det som er; heller ikke ved dette skal det bli, inntil han kommer hvem retten tilhører, og jeg gir ham den.
28 “Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
Og du menneskesønn, spå og si: Så sier Herren, Israels Gud, om Ammons barn og om deres hånsord: Du skal si: Et sverd, et sverd er draget, slipt til å slakte, til å fortære, til å lyne,
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
mens de skuer falske syner for dig og spår dig løgn, for å legge dig ved siden av de ihjelslåtte ugudeliges halser, hvis dag er kommet når den misgjerning er skjedd som fører til undergang.
30 “‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
Stikk sverdet i skjeden igjen! På det sted hvor du blev skapt, i det land hvorfra du er oprunnet, der vil jeg dømme dig.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
Og jeg vil utøse min harme over dig, min vredes ild vil jeg la lue mot dig, og jeg vil gi dig i ville menneskers hånd, som er mestere i å ødelegge.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”
Du skal bli til føde for ilden, ditt blod skal bli utøst i ditt land, ingen skal mere komme dig i hu; for jeg, Herren, har sagt det.

< Ezekiel 21 >