< Ezekiel 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
"Fils de l’homme, dirige ta face vers Jérusalem, prêche sur les sanctuaires et prophétise sur la terre d’Israël.
3 Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
Tu diras au pays d’Israël: Ainsi parle l’Eternel: Me voici contre toi, je sortirai mon épée de son fourreau et j’extirperai de toi justes et impies.
4 Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
Parce que je veux extirper de toi justes et impies, c’est pourquoi mon épée sortira de son fourreau contre toute chair du Sud au Nord.
5 Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
Et toute chair saura que c’est moi, l’Eternel, qui ai tiré mon épée du fourreau: elle n’y rentrera plus.
6 “Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
Et toi, fils de l’homme, pousse des soupirs: les reins brisés, dans l’amertume, pousse des soupirs à leurs yeux.
7 Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
Alors s’ils te disent: "Pourquoi soupires-tu?" tu répondras: "C’Est à cause de la nouvelle qui arrive, qui fait fondre tous les coeurs, défaillir toutes les mains, se troubler tous les esprits, s’en aller en eau tous les genoux; elle arrive et s’accomplit dit le Seigneur Dieu."
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
9 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
"Fils de l’homme, prophétise et dis: Ainsi parle le Seigneur: Dis qu’une épée, une épée a été aiguisée et polie.
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
C’Est pour procéder à la tuerie qu’elle a été aiguisée, c’est pour qu’elle jette des éclairs qu’elle a été polie. Ou se peut-il que nous connaissions encore la joie? La verge qui frappe mon fils voit avec dédain tout instrument de bois.
11 “‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
Il l’a donnée à polir pour qu’on la saisisse par la main; on l’a aiguisée, l’épée, et on l’a polie pour la mettre en la main du meurtrier.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
Crie et lamente-toi, fils de l’homme, car cette épée a sévi sur mon peuple, elle a sévi sur tous les princes d’Israël; ils ont été livrés à l’épée avec mon peuple, c’est pourquoi frappe-toi la hanche.
13 “‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
C’Est une épreuve. Et que sera-ce s’il s’y ajoute la verge dédaigneuse? Rien ne sera plus, dit le Seigneur Dieu.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
Et toi, fils de l’homme, prophétise et frappe d’une main contre l’autre et que l’épée redouble ses coups par trois fois! C’Est une épée de massacres, l’épée de la grande victime qui les pourchasse.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
C’Est afin de faire fondre les coeurs et de multiplier les chutes auprès de toutes leurs portes, que j’ai brandi le brillant de l’épée; ah! Elle est préparée pour étinceler et aiguisée pour tuer.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
Sois tranchante à droite, avance à gauche, partout où tes lames sont dirigées.
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
Et moi aussi, je frapperai d’une main contre l’autre et j’assouvirai ma colère, moi, l’Eternel, je l’ai dit."
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
"O toi, fils de l’homme, fais-toi deux chemins par où vienne l’épée du roi de Babylone; ils doivent partir tous deux d’un même pays; et grave une main indicatrice, grave-la au point de départ du chemin de la ville.
20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
Fais un chemin par où vienne l’épée contre Rabba capitale des fils d’Ammon et contre Juda dans Jérusalem la forte.
21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
Car le roi de Babylone s’est porté à la naissance du chemin, au commencement des deux chemins, pour consulter le sort; il a agité les flèches, interrogé les Teraphim, examiné le foie.
22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
Dans sa main droite se trouvait le sort "Jérusalem" pour y dresser des béliers, y proclamer la tuerie, pour y proférer des cris de guerre, pour dresser des béliers contre (es portes, pour y jeter une chaussée et bâtir des ouvrages de siège.
23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
Mais cela paraîtra à leurs yeux un sort mensonger, on leur a fait serments sur serments; mais lui leur rappellera leur crime, pour qu’ils soient capturés.
24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
C’Est pourquoi, ainsi parle le Seigneur Dieu, puisque vous avez réveillé le souvenir de votre crime, en dévoilant vos fautes, en montrant à nu vos péchés dans toutes vos actions, puisqu’il est fait mention de vous, vous serez capturés par la main.
25 “‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
Et toi, impie, désigné à la mort, prince d’Israël dont le jour est venu, à l’heure où ton crime prend fin,
26 èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
ainsi parle le Seigneur Dieu: Bas la tiare, plus de couronne! Tout à l’inverse! Que ce qui est bas s’élève, que ce qui est élevé s’abaisse!
27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
Ruine, ruine, ruine, voilà ce que j’en ferai; cela non plus n’existe plus, jusqu’à ce que vienne celui qui y a droit et à qui je le donnerai.
28 “Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
Et toi, fils de l’homme, prophétise et dis: "Ainsi parle le Seigneur Dieu à l’égard des fils d’Ammon et de leurs outrages: Dis: Epée, épée dégainée, affilée pour la tuerie, pour briller comme l’éclair,
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
tandis qu’on t’adresse des prophéties vaines et des oracles de mensonge, on te pose sur le cou des cadavres des méchants dont le jour est venu, à l’heure où l’iniquité prend fin!
30 “‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
Qu’elle rentre dans son fourreau! A l’endroit où tu fus créée, en ton pays d’extraction je te jugerai.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
J’Épancherai sur, toi ma colère; le feu de ma fureur, je le soufflerai sur toi et je te livrerai dans les mains de sauvages, artisans de la destruction.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”
Tu seras la proie du feu; ton sang coulera par tout le pays; on ne fera plus mention de toi, car moi, l’Eternel, j’ai parlé."

< Ezekiel 21 >