< Ezekiel 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
And the word of the Lord came unto me, saying,
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí ìhà Jerusalẹmu, kí o sì wàásù lòdì sí ibi mímọ́. Sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí ilẹ̀ Israẹli.
Son of man, direct thy face toward Jerusalem, and preach toward the holy places, and prophesy against the land of Israel,
3 Kí ó sì sọ fún un pe, ‘Èyí yìí ni Olúwa wí, Èmi lòdì sí ọ. Èmi yóò fa idà mi yọ kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀, Èmi yóò sì ké olódodo àti ènìyàn búburú kúrò ni àárín yín.
And say to the land of Israel, Thus hath said the Lord, Behold, I will be against thee, and will draw forth my sword out of its sheath; and I will cut off from thee the righteous and the wicked.
4 Nítorí pé, èmi yóò ké olódodo àti olùṣe búburú kúrò, idà mi yóò jáde láti inú àkọ̀ rẹ̀ lòdì sí gbogbo ènìyàn láti gúúsù títí dé àríwá.
But because I shall have cut off from thee the righteous and the wicked: therefore shall my sword go forth out of its sheath against all flesh from the south to the north;
5 Nígbà náà gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti yọ idà mi kúrò nínú àkọ̀ rẹ̀; kì yóò sì padà sínú rẹ̀ mọ́.’
That all flesh may know that I the Lord have drawn forth my sword out of its sheath; it shall not return any more.
6 “Nítorí náà, mí ìmí ẹ̀dùn ìwọ ọmọ ènìyàn! Mí ìmí ẹ̀dùn pẹ̀lú ọkàn ìbànújẹ́ àti ẹ̀dùn ọkàn kíkorò ní iwájú wọn.
But thou, son of man, do thou sigh: as though with broken loins, and with bitterness [of grief] shalt thou sigh before their eyes.
7 Bí wọ́n bá sì bi ọ́, wí pé, ‘Kí ni ó dé tí ìwọ fi ń mí ìmí ẹ̀dùn?’ Ìwọ yóò wí pé, ‘Nítorí ìròyìn tí ó ń bẹ. Gbogbo ọkàn ni yóò yọ́, gbogbo ọwọ́ ni yóò sì di aláìlera; gbogbo ọkàn ní yóò dákú, gbogbo eékún ni yóò sì di aláìlera bí omi?’ Ó ń bọ̀! Yóò sì wa sí ìmúṣẹ dandan, ni Olúwa Olódùmarè wí.”
And it shall be, when they say unto thee, Wherefore sighest thou? that thou shalt say, For the report, because it cometh, when every heart shall melt, and all hands shall be made feeble, and every spirit shall become faint, and all knees shall be changed into water: behold, it cometh, and shall be brought to pass, saith the Lord Eternal.
8 Ọ̀rọ̀ Olúwa si tún tọ̀ mí wá pé:
And the word of the Lord came unto me, saying,
9 “Ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ wí pé, èyí yìí ní Olúwa wí pé, “‘Idà kan, idà kan, tí a pọ́n, tí a sì dán pẹ̀lú,
Son of man, prophesy, and say, Thus hath said the Lord, Say, The sword, the sword is sharpened, and also polished;
10 a pọ́n láti pa ènìyàn púpọ̀, a dán an láti máa kọ mọ̀nà! “‘Àwa o ha máa ṣe àríyá ọ̀gọ ọmọ mi? Idà gán gbogbo irú igi bẹ́ẹ̀.
In order to make a thorough slaughter is it sharpened; in order that it may glitter is it polished: how can we now rejoice, [when] the rod which reacheth my son excelleth in hardness every tree?
11 “‘Idà ní a yàn láti pọ́n, kí ó lè ṣe é gbámú; a pọ́n ọn, a sì dán an, ó ṣetán fún ọwọ́ àwọn apani.
And he hath given it to be polished, to make it fit to grasp it in the hand: it is the sword which is sharpened, and it is polished, to place it into the hand of the slayer.
12 Sọkún síta, kí ó sì pohùnréré ẹ̀kún, ọmọ ènìyàn, nítorí yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi; yóò wá sórí gbogbo ọmọ-aládé Israẹli ìbẹ̀rù ńlá yóò wá sórí àwọn ènìyàn mi nítorí idà náà; nítorí náà lu oókan àyà rẹ.
Cry aloud and wail, O son of man; for it cometh against my people, it cometh against all the princes of Israel; brought together for the sword are they with my people: therefore strike [thy hand] upon thy thigh.
13 “‘Ìdánwò yóò dé dandan. Tí ọ̀pá aládé Juda èyí tí idà kẹ́gàn, kò bá tẹ̀síwájú mọ́ ń kọ́? Ni Olúwa Olódùmarè wí.’
For a purification taketh place: and what if the irresistible rod will also come? [my son] would not be able to exist, saith the Lord Eternal.
14 “Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́. Jẹ́ kí idà lu ara wọn lẹ́ẹ̀méjì, kódà ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Ó jẹ́ idà fún ìpànìyàn idà fún ìpànìyàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀, tí yóò sé wọn mọ́ níhìn-ín àti lọ́hùnnún.
But thou, son of man, prophesy, and strike thy hands together, and let “The sword” be repeated the third time, the sword of the slain: it is the sword of the great that are slain, which lieth in wait for them everywhere.
15 Kí ọkàn kí ó lè yọ́ kí àwọn tí ó ṣubú le pọ̀, mo ti gbé idà sí gbogbo bodè fún ìparun. Háà! A mú kí ó kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná, a gbá a mú fún ìparun.
In order to make timid the heart, and to multiply the stumbling-blocks, do I bring the howling of the sword against all their gates: ah! it is made bright, it is made thin-edged for the slaughter.
16 Ìwọ idà, jà sí ọ̀tún kí o sì jà sí òsì lọ ibikíbi tí ẹnu rẹ bá dojúkọ.
Gather up thy strength, go to the right hand, direct thyself, go to the left, whithersoever thy edge is turned.
17 Èmi gan an yóò pàtẹ́wọ́ ìbínú mi yóò sì rẹlẹ̀. Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀.”
And I also, —I will strike my hands together, and I will cause my fury to be assuaged: I the Lord have spoken it.
18 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mi wá:
And the word of the Lord came unto me, saying,
19 “Ọmọ ènìyàn la ọ̀nà méjì fún idà ọba Babeli láti gbà, kí méjèèjì bẹ̀rẹ̀ láti ìlú kan náà. Ṣe àmì sí ìkóríta ọ̀nà tí ó lọ sí ìlú náà.
But thou, O son of man, appoint thee two ways, that the sword of the king of Babylon may come; out of one land shall both of them come forth: and select a place; at the head of the way to a city do thou select it.
20 La ọ̀nà kan fún idà láti wá kọlu Rabba ti àwọn ará Ammoni kí òmíràn kọlu Juda, kí ó sì kọlu Jerusalẹmu ìlú olódi.
A way shalt thou appoint, that the sword may come against Rabbah of the children of 'Ammon, and [the other] against Judah [dwelling] in Jerusalem the fortified.
21 Nítorí ọba Babeli yóò dúró ni ìyànà ní ojú ọ̀nà, ní ìkóríta, láti máa lo àfọ̀ṣẹ. Yóò fi ọfà di ìbò, yóò béèrè lọ́wọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀, òun yóò ṣe àyẹ̀wò ẹ̀dọ̀.
For the king of Babylon hath halted at the parting of the way, at the commencement of the two ways, to use divination: he shaketh the arrows, he consulteth with images, he looketh at the liver.
22 Nínú ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni ìbò Jerusalẹmu yóò ti wá, ní ibi tí yóò ti gbé afárá kalẹ̀, láti pàṣẹ fún àwọn apànìyàn, láti mú ki wọn hó ìhó ogun láti gbé òòlù dí ẹnu-ọ̀nà ibodè, láti mọ odi, àti láti kọ́ ilé ìṣọ́.
At his right hand was the divination for Jerusalem, to erect battering-rams, to open the mouth with the [cry for] murder, to lift up the voice with shouting, to place battering-rams against the gates, to cast up a mound, and to build works of attack.
23 Àfọ̀ṣẹ náà yóò dàbí àmì èké sí àwọn tí ó ti búra ìtẹríba fún un, ṣùgbọ́n òun yóò ran wọn létí ẹbí wọn yóò sì mú wọn lọ sí ìgbèkùn.
And it will appear unto them as a false divination in their eyes, to those that had sworn oaths; but he will bring to remembrance their iniquity, that they may be caught.
24 “Nítorí náà èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí ti ẹ̀yin ti mú ẹ̀bi yín wá sí ìrántí nípa ìṣọ̀tẹ̀ ní gbangba, ní ṣíṣe àfihàn àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nínú gbogbo ohun tí ó ṣe, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí, a yóò mú yín ní ìgbèkùn.
Therefore thus hath said the Lord Eternal, Because ye have brought your iniquity to remembrance, as your transgressions are discovered, so that your sins do appear in all your doings: because ye are thus brought to remembrance, ye shall be caught by [his] hand.
25 “‘Ìwọ aláìmọ́ àti ẹni búburú ọmọ-aládé Israẹli, ẹni ti ọjọ́ rẹ̀ ti dé, ẹni tí àsìkò ìjìyà rẹ̀ ti dé góńgó,
And thou, death-deserving wicked one, prince of Israel, whose day is come, at the time of the iniquity of the end, —
26 èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, tú ìwérí kúrò kí o sì gbé adé kúrò. Kò ní rí bí ti tẹ́lẹ̀, ẹni ìgbéga ni a yóò sì rẹ̀ sílẹ̀.
Thus hath said the Lord Eternal, Remove the mitre, and take off the crown: this shall not be always so; exalt him that is low, and make him low that is high.
27 Ìparun! Ìparun! Èmi yóò ṣé e ni ìparun! Kì yóò padà bọ̀ sípò bí kò ṣe pé tí ó bá wá sí ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ni in; òun ni èmi yóò fi fún.’
Overthrown, overthrown, overthrown will I render it: also this shall not belong [to any one], until he come whose right it is, and I will give it him.
28 “Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nípa àwọn ará Ammoni àti àbùkù wọn: “‘Idà kan idà kan tí á fa yọ fún ìpànìyàn tí a dán láti fi ènìyàn ṣòfò àti láti kọ bí ìmọ̀nàmọ́ná!
And thou, son of man, prophesy, and say, Thus hath said the Lord Eternal concerning the children of 'Ammon, and concerning their reproach: even say thou, The sword, the sword is drawn; for the slaughter is it polished, to destroy, that it may continue to glitter;
29 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí èké nípa yín àti àfọ̀ṣẹ èké nípa yín a yóò gbé e lé àwọn ọrùn ènìyàn búburú ti a ó pa, àwọn tí ọjọ́ wọn ti dé, àwọn tí ọjọ́ ìjìyà wọn ti dé góńgó.
While they foresee unto thee falsehood, while they divine unto thee lies, to lay thee by the necks of the slain wicked, whose day is come, at the time of the iniquity of the end.
30 “‘Dá idà padà sínú àkọ̀ rẹ̀. Níbi tí a gbé ṣẹ̀dá yín, ní ibi tí ẹ̀yin ti ṣẹ̀ wá.
Put back [the sword] into its sheath! in the place where thou wast created, in the land of thy origin, will I judge thee.
31 Níbẹ̀ ni èmi yóò ti ṣe ìdájọ́ yín, èmi o sì fi èémí ìbínú gbígbóná mi bá yín jà.
And I will pour out over thee my indignation, with the fire of my wrath will I blow against thee, and I will give thee up into the hand of brutish men, skilful in destroying.
32 Ẹ̀yin yóò jẹ́ èpò fún iná náà, a yóò ta ẹ̀jẹ̀ yin sórí ilẹ̀ yín, a kì yóò rántí yín mọ́; nítorí Èmi Olúwa ní ó ti wí bẹ́ẹ̀.’”
To the fire shalt thou be given to be devoured; thy blood shall be in the midst of the land: thou shalt not be remembered [any more]; for I the Lord have spoken it.

< Ezekiel 21 >