< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
Och det begaf sig i sjunde årena, på tionde dagen i femte månadenom, kommo någre af de äldsta i Israel till att fråga Herran, och satte sig neder för mig.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Då skedde Herrans ord till mig, och sade:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Du menniskobarn, tala med Israels äldsta, och säg till dem: Detta säger Herren Herren: Ären I komne till att fråga mig? Så sant som jag lefver, jag vill intet svar gifva eder, säger Herren Herren.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Men vill du menniskobarn straffa dem, så må du straffa dem alltså: Håll dem före deras fäders styggelse;
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Och säg till dem: Detta säger Herren Herren: På den tid jag utvalde Israel, upphof jag mina hand till Jacobs hus säd, och lät dem känna mig uti Egypti land; ja, jag upphof mina hand till dem, och sade: Jag är Herren edar Gud.
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Men jag upphof på samma tid mina hand, att jag skulle föra, dem utur Egypti land, in uti ett land som jag dem försett hade, det med mjölk och hannog flyter; ett ädla land för all land;
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Och sade till dem: Hvar och en kaste bort styggelsen för sin ögon, och orener icke eder på Egypti afgudar; ty jag är Herren edar Gud.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Men de voro mig ohörsamme, och ville intet höra mig, och ingen af dem kastade sin styggelse bort för sin ögon, och öfvergåfvo icke Egypti afgudar; då tänkte jag utgjuta mina grymhet öfver dem, och låta alla mina vrede gå öfver dem, midt uti Egypti land;
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Men jag lät det tillbaka, för mitt Namns skull, att det icke skulle ohelgadt varda för Hedningomen, ibland hvilka de voro, och för hvilkom jag hade gifvit mig dem tillkänna, att jag dem utur Egypti land föra ville.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Och då jag; dem utur Egypti land fört hade, och låtit dem komma in uti öknena;
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Gaf jag dem min bud, och lärde dem mina rätter, genom hvilka menniskan lefver, den dem håller.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Jag gaf dem ock min Sabbath, till ett tecken emellan mig och dem, på det de skulle lära, att jag är Herren, som dem helgar.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Men Israels hus var mig också ohörsamt uti öknene, och lefde intet efter min bud, och föraktade mina rätter, genom hvilka menniskan lefver, som dem håller, och ohelgade min Sabbath ganska svårliga; då tänkte jag utgjuta mina grymhet öfver dem uti öknene, och platt förgöra dem;
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Men jag lät det tillbaka, för mitt Namns skull, att det icke skulle ohelgadt varda ibland Hedningarna, för hvilkom jag dem utfört hade.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Ock hof jag mina hand upp emot dem i öknene, att jag icke ville låta dem komma in uti det land, som jag dem gifvit hade, det med mjölk och hannog flyter; ett ädla land för alla land;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
Derföre, att de föraktade mina rätter, och lefde icke efter min bud, och mina Sabbather ohelgade; ty de vandrade efter deras hjertas afgudar.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Men mitt öga skonade dem, att jag icke förderfvade eller platt förgjorde dem i öknene.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Och jag sade till deras barn i öknene: I skolen icke lefva efter edra fäders bud, och icke hålla deras rätter, och icke orena eder uppå deras afgudar.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Ty jag är Herren edar Gud; efter min bud skolen I lefva, och mina rätter skolen I hålla, och göra derefter;
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Och mina Sabbather skolen I helga, att de skola vara ett tecken emellan mig och eder, på det I veta skolen att jag, Herren, är edar Gud.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Men barnen voro mig ock ohörsam, lefde icke efter min bud, höllo ock icke mina rätter, så att de gjorde derefter, genom hvilka menniskan lefver, den dem håller, och ohelgade mina Sabbather; då tänkte jag utgjuta mina grymhet öfver dem, och låta alla mina vrede gå öfver dem i öknene;
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Men jag vände mina hand, och lät det tillbaka, för mitt Namns skull, att det icke skulle ohelgadt varda för Hedningomen, för hvilkom jag dem utfört hade.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Jag hof ock mina hand upp emot dem i öknene, att jag skulle förströ dem ibland Hedningarna, och förskingra dem i landen;
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
Derföre, att de icke höllo min bud, och föraktade mina rätter, och ohelgade mina Sabbather, och sågo efter deras fäders afgudar.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Derföre gaf jag dem den lära, som intet god är; och de rätter, uti hvilka de intet lif hafva kunna;
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Och förkastade dem med deras offer då de uppbrände i eld all förstföding; på det jag skulle bedröfva dem, och de lära skulle, att jag är Herren.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Derföre tala, du menniskobarn, med Israels hus, och säg till dem: Detta säger Herren Herren: Edra fäder hafva ännu mer försmädat och trotsat mig.
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Ty då jag hade låtit dem komma in uti landet, öfver hvilket jag mina hand upphäfvit hade, att jag skulle det gifva dem; hvar de någorstäds sågo en hög backa, eller tjockqvistadt trä, der offrade de sitt offer, och båro dit sina obehageliga gåfvor, och rökte der sin söta rök, och utgöto der sitt drickoffer.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Men jag sade till dem: Hvad skall dock den höjden, dit I gån? Och så kallades det en höjd, allt intill denna dag.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Derföre säg till Israels hus: Detta säger Herren Herren: I orenen eder uti edra fäders väsende, och bedrifven horeri med edor styggelse;
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
Och besmitten eder på edra afgudar, hvilkom I offren edra gåfvor, och uppbrännen edra söner och döttrar i eld, allt intill denna dag; och jag skulle gifva eder af Israels hus svar? Så sant som jag lefver, säger Herren Herren, jag skall intet svar gifva eder.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
Dertill, då I tänken: Vi vilje göra lika som Hedningarna, och såsom annor folk i landen, och tillbedja stockar och stenar, skall det fela eder.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Så sant som jag lefver, säger Herren Herren, jag skall råda öfver eder med starka hand och uträcktom arm, och med utgjuten grymhet;
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Och skall föra eder ifrå folken, och församla eder utu de land, dit I förströdde ären, med starka hand, med uträcktom arm, och med utgjuten grymhet;
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Och skall låta eder komma uti folks öken, och der vara i rätta med eder, ansigte emot ansigte.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Lika som jag med edra fäder uti öknene vid Egypten i rätta var, rätt så skall jag vara i rätta med eder, säger Herren Herren.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Jag skall låta komma eder under riset, och tvinga eder uti förbundsens bandom.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
Och jag skall utfäja de affälliga, och de som emot mig öfverträda, ibland eder; ja, jag skall föra dem utu det land, der I nu bon, och intet låta dem komma in uti Israels land, att I lära skolen, att jag är Herren.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Derföre, I af Israels hus, detta säger Herren Herren: Efter I ju intet viljen höra mig, så görer som eder täckes, och hvar edra tjene sinom afgud; men mitt helga Namn låter härefter oskämdt vara, med edor offer och afgudar.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Ty detta säger Herren Herren: På mino heligo berge, på de höga bergena Israel, der skall hela Israels hus, och alle de som i landet äro, tjena mig; der skola de vara mig tacknämlige, och der skall jag äska uppå edor häfoffer och edars offers förstling, med allt det I mig helgen.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
I skolen varda mig tacknämlige med sötom rök, när jag låter eder komma ifrå folken, och varder eder församlande utu landen, dit I förströdde ären, och jag skull varda helgad i eder för Hedningomen.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Och I skolen förnimma, att jag är Herren, när jag hafver låtit eder komma in uti Israels land, uti det land, om hvilket jag upphof mina hand, att jag det edra fäder gifva skulle.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Der skolen I tänka uppå edart väsende, och uppå all edar handel, der I utinnan orenade ären, och skolen hafva ett misshag till all edor ondsko, som I bedrifvit hafven;
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Och skolen förnimma, att jag är Herren, när jag gör med eder för mitt Namns skull, och icke efter edart onda väsende och skadeliga handel, du Israels hus, säger Herren Herren.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Och Herrans ord skedde till mig, och sade:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Du menniskobarn, ställ ditt ansigte emot Theman, och tala söderut, och prophetera emot den skogen i den markene söderut.
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
Och säg till den skogen söderut: Hör Herrans ord. Detta säger Herren Herren: Si, jag skall upptända i dig en eld, han skall förtära både färsk trä och torr, så att man icke skall kunna utsläcka hans låga; utan allt det som ifrå sunnan norråt står, det skall uppbrändt varda.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Och allt kött skall se att jag, Herren, det upptändt hafver, och ingen det utsläcka kan.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Och jag sade: Ack Herre Herre! de säga om mig: Denne talar icke annat än förtäckt ord:

< Ezekiel 20 >