< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
Și s-a întâmplat în al șaptelea an, în [luna] a cincea, [în] a zecea [zi] a lunii, [că] anumiți dintre bătrânii lui Israel au venit să întrebe pe DOMNUL și au șezut înaintea mea.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Atunci a venit cuvântul DOMNULUI la mine, spunând:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Fiu al omului, vorbește bătrânilor lui Israel și spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Ați venit să mă luați la întrebări? [Precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU, nu mă voi lăsa întrebat de voi.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Îi vei judeca tu, fiu al omului, [îi] vei judeca? Fă-i să cunoască urâciunile părinților lor;
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Și spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: În ziua când l-am ales pe Israel și mi-am ridicat mâna către sămânța casei lui Iacob și m-am făcut cunoscut lor în țara Egiptului, când mi-am ridicat mâna către ei, spunând: Eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul vostru;
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
În ziua [în care] mi-am ridicat mâna către ei, pentru a-i aduce din țara Egiptului într-o țară pe care o cercetasem pentru ei, în care curge lapte și miere, care [este] gloria tuturor țărilor;
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Atunci le-am spus: Lepădați, fiecare om urâciunile ochilor săi, și nu vă pângăriți cu idolii Egiptului; Eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul vostru.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Dar ei s-au răzvrătit împotriva mea și au refuzat să îmi dea ascultare; nu au lepădat, niciun om, urâciunile ochilor lor, nici nu au părăsit idolii Egiptului; atunci am spus: Îmi voi turna furia asupra lor, ca să îmi împlinesc mânia împotriva lor în mijlocul țării Egiptului.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Dar am lucrat pentru numele meu, ca acesta să nu fie murdărit înaintea păgânilor, printre care ei [erau], înaintea ochilor cărora m-am făcut cunoscut, scoțându-i din țara Egiptului.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Pentru aceea i-am făcut să iasă din țara Egiptului și i-am adus în pustie.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Și le-am dat statutele mele și le-am arătat judecățile mele, pe care [dacă] un om le împlinește, va trăi în ele.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Mai mult, le-am dat de asemenea sabatele mele, să fie un semn între mine și ei, ca să știe că eu [sunt] DOMNUL care îi sfințește.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Dar casa lui Israel s-a răzvrătit împotriva mea în pustie, nu au umblat în statutele mele și au disprețuit judecățile mele, pe care, [dacă] un om le împlinește, va trăi în ele; și au murdărit sabatele mele foarte mult; atunci am spus: Îmi voi turna furia asupra lor în pustie, pentru a-i mistui.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Dar am lucrat pentru numele meu, ca acesta să nu fie murdărit înaintea păgânilor, înaintea ochilor cărora îi scosesem.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Totuși mi-am ridicat de asemenea mâna către ei în pustie, că nu îi voi duce în țara pe care [le]-am dat-o, în care curge lapte și miere, care [este] gloria tuturor țărilor;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
Deoarece ei au disprețuit judecățile mele și nu au umblat în statutele mele, ci au murdărit sabatele mele, pentru că inima lor mergea după idolii lor.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Totuși ochiul meu i-a cruțat de la a-i nimici, nici nu i-am nimicit în pustie.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Ci am spus copiilor lor în pustie: Nu umblați în statutele părinților voștri, nici nu țineți judecățile lor, nici nu vă pângăriți cu idolii lor;
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul vostru; umblați în statutele mele și păziți judecățile mele și împliniți-le;
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Și sfințiți sabatele mele; iar ele vor fi un semn între mine și voi, ca să cunoașteți că eu [sunt] DOMNUL Dumnezeul vostru.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Totuși copiii s-au răzvrătit împotriva mea; nu au umblat în statutele mele, nici nu au păzit judecățile mele pentru a le împlini, pe care, [dacă] un om le împlinește, va trăi în ele; ei au murdărit sabatele mele; atunci am spus: Îmi voi turna furia asupra lor, pentru a împlini mânia mea împotriva lor în pustie.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Totuși mi-am retras mâna și am lucrat pentru numele meu, ca acesta să nu fie murdărit înaintea ochilor păgânilor, înaintea ochilor cărora îi scosesem.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Mi-am ridicat de asemenea mâna pentru ei în pustie, că îi voi împrăștia printre păgâni și îi voi risipi prin țări;
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
Pentru că nu au împlinit judecățile mele, ci au disprețuit statutele mele și au murdărit sabatele mele și ochii lor au fost după idolii părinților lor.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Și de asemenea eu, eu le-am dat statute [care] nu [erau] bune și judecăți prin care nu puteau să trăiască;
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Și i-am murdărit în propriile lor daruri, în aceea că ei au făcut să treacă prin [foc] pe toți cei care deschid pântecele, ca să îi pustiesc ca ei să știe că eu [sunt] DOMNUL.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
De aceea, fiu al omului, vorbește casei lui Israel și spune-le: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Totuși în aceasta părinții voștri m-au blasfemiat, în aceea că fărădelege au făcut împotriva mea.
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
După ce i-am adus în țara, [pentru] care îmi ridicasem mâna că le-o voi da, au văzut fiecare deal înalt și toți copacii stufoși, și acolo au adus sacrificiile lor și acolo și-au prezentat provocarea darului lor; acolo de asemenea și-au pregătit aroma dulce și acolo și-au turnat darurile de băutură.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Atunci eu le-am spus: Ce [este] înălțimea la care mergeți? Și până în această zi i s-a pus numele Bama.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Pentru aceea spune casei lui Israel: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Sunteți voi murdăriți după felul părinților voștri? Și curviți după urâciunile lor?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
Fiindcă atunci când aduceți darurile voastre, când treceți pe fiii voștri prin foc, vă murdăriți cu toți idolii voștri, până în această zi; iar eu să mă las întrebat de voi, casă a lui Israel? [Precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU, nu mă voi lăsa întrebat de voi.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
Și nu veți spune ce vă vine în minte: Vom fi ca păgânii, ca familiile țărilor, pentru a servi lemnului și pietrei.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
[Precum] eu trăiesc, spune DOMNUL Dumnezeu, într-adevăr cu o mână puternică și cu un braț întins și cu furie revărsată, voi conduce peste voi;
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Și vă voi scoate dintre popoare și vă voi aduna din țările în care sunteți împrăștiați, cu o mână puternică și cu un braț întins și cu furie revărsată.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Și vă voi aduce în pustia popoarelor și acolo mă voi judeca eu cu voi față în față.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Precum m-am judecat cu părinții voștri în pustia țării Egiptului, astfel mă voi judeca [și] cu voi, spune Domnul DUMNEZEU.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Și vă voi face să treceți pe sub toiag și vă voi aduce în legătura legământului;
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
Și voi curăți dintre voi pe răzvrătiți și pe cei care calcă [legea] împotriva mea; îi voi scoate din țara în care ei locuiesc temporar și nu vor intra în țara lui Israel; și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Cât despre voi, casă a lui Israel, astfel spune Domnul DUMNEZEU: De acum înainte, dacă refuzați să îmi dați ascultare, [atunci] duceți-vă, serviți, fiecare, idolilor săi; dar nu mai murdăriți numele meu sfânt cu darurile voastre și cu idolii voștri.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Pentru că pe muntele meu cel sfânt, pe muntele înălțimii lui Israel, spune Domnul DUMNEZEU, acolo îmi va servi toată casa lui Israel, cu toții în țară; acolo îi voi accepta și acolo voi cere ofrandele voastre și primele roade ale darurilor voastre, cu toate lucrurile voastre sfinte.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Vă voi accepta cu aroma voastră dulce, când vă voi scoate dintre popoare și vă voi aduna din țările în care ați fost împrăștiați; și voi fi sfințit în voi înaintea păgânilor.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, când vă voi aduce în țara lui Israel, în țara [pentru] care mi-am ridicat mâna că o voi da părinților voștri.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Și acolo vă veți aminti de căile voastre și de toate facerile voastre cu care v-ați pângărit; și vă veți detesta înaintea ochilor voștri pentru toate relele voastre pe care le-ați făcut.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Și veți cunoaște că eu [sunt] DOMNUL, după ce voi fi lucrat cu voi din cauza numelui meu, nu conform căilor voastre stricate, nici conform facerilor voastre corupte, casă a lui Israel, spune Domnul DUMNEZEU.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Fiu al omului, îndreaptă-ți fața spre sud și picură [cuvântul tău] spre sud și profețește împotriva pădurii câmpiei de sud;
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
Și spune pădurii de sud: Ascultă cuvântul DOMNULUI: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Iată, voi aprinde un foc în tine și va mistui fiecare copac verde în tine și fiecare copac uscat; flacăra învăpăiată, nu va fi stinsă și toate fețele de la sud până la nord vor fi arse în el.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Și toată făptura va vedea că eu, DOMNUL, am aprins-o; nu se va stinge.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Atunci am spus: Ah, Doamne DUMNEZEULE! Ei spun despre mine: Nu vorbește el în parabole?

< Ezekiel 20 >