< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
I stało się roku siódmego, miesiąca piątego, dziesiątego dnia tegoż miesiąca, przyszli niektórzy z starszych Izraelskich, aby się radzili Pana; i usiedli przedemną.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Tedy się stało słowo Pańskie do mnie, mówąc:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Synu człowieczy! mów do starszych Izraelsich, a powiedz im: Tak mówi panujący Pan: Izali wy przychodzicie, abyście się mnie radzili? Jako żyję Ja, że się wy mnie nie radzicie, mówi panujący Pan;
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Izali się za nich zastawiać będziesz? Izali się za nich zastawiać będziesz, synu człowieczy? Oznajmij im raczej obrzydliwości ojców ich,
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
A rzecz do nich: Tak mówi panujacy Pan: Tego dnia, któregom wybrał Izraela, podniosłem rękę moję nasieniu domu Jakóbowego, i dałem się im poznać w ziemi Egipskiej; podniosłem rękę moję dla nich, mówiąc: Jam Pan, Bóg wasz.
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Onego dnia podniosłem rękę moję dla nich, że ich wywiodę z ziemi Egipskiej do ziemi, którąm im upatrzył, opływającej mlekiem i miodem, która jest ozdobą wszystkich ziem.
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
I rzekłem im: Każdy z was niech porzuci obrzydliwości oczów swoich, a nie kalajcie się plugawemi bałwanami egipskiemi; bom Ja Pan, Bóg wasz.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Ale mi byli odpornymi, i nie chcieli mię słuchać; żaden z nich obrzydliwości oczów swoich nie odrzucił, i plugawych bałwanów egipskich nie opóścił; prztożem rzekł: Wyleję gniew mój na nich, a wypęłnie popędliwość moję nad nimi w pośrodku ziemi egipskiej.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
A wszakżem uczynił dla imienia mego, aby nie było zelżone przed oczyma tych narodów, między którymi oni byli, przed których oczyma dałem się im poznać, że ich chcę wywieść z ziemi egipskiej.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
A tak wywiodłem ich z ziemi egipskiej, i przyprowadziłem ich na puszczę;
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
I dałem im ustawy moje, i sądy moje podałem im do wiadomości; które jeźliby człowiek zachowywał, żyć w nich będzie.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Nadto i sabaty moje dałem im, aby były znakiem między mną i między nimi, aby wiedzieli, żem Ja jest Pan, który ich poświęcam.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Ale mi się odpornym stał dom Izraelski na puszczy; w ustawach moich nie chodzili, i sądy moje odrzucili, które jeźliby człowiek czynił, żyć w nich będzie. Sabaty też moje bardzo zgwałcili; prztożem mówił, iż wleję popędliwość moję na nich na pus zczy, abym ich wygubił.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Leczem uczynił dla imienia mego, aby nie było zelżone przed oczyma tych narodów przed którychem ich oczyma wywiódł.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
A wszakżem podniósł rękę moję dla nich na tej puszczy, że ich nie wprowadzę do ziemi, którąm im był dał, opływającej mlekiem i miodem, i która jest ozdobą wszystkich ziem;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
Ponieważ sądy moje odrzucili, a w ustawach moich nie chodzili, i sabaty moje pogwałcili, a że serce ich za plugawemi bałwanami chodzi.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Ale im przecie przepuściło oko moje, tak, żem ich nie wytracił, i nie wygładził do szczętu na puszczy.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
I mówiłem do synów ich na tej puszczy: W ustawach ojców waszych nie chodźcie, i sądów ich nie przestrzegajcie, ani się plugawemi bałwanami ich kalajcie.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Jam Pan, Bóg wasz; w ustawach moich chodźcie, a sądów moich strzeżcie, i czyńcie ich;
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Sabaty też moje święćcie, i będą znakiem między mną i między wami, abyście wiedzieli żem Ja Pan, Bóg wasz.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Lecz mi byli odpornymi ci synowie; w ustawach moich nie chodzili, i sądów moich nie przestrzegali, aby je czynili, (które jeźliby czynił człowiek pewnieby żył w nich) i sabaty moje pogwałcili. I rzekłem: Wyleję popędliwość moję na nich, abym wyko nał gniew swój na nich na tej puszczy.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Alem odwrócił rękę moję, a uczyniłem to dla imienia mego, aby nie było zelżone przed oczyma tych narodów, przed którychem ich oczyma wywiódł.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Alem ja podniósł rękę moję dla nich na puszczy, żem ich miał rozproszyć między pogan, i rozwiać ich po ziemiach,
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
Przeto, że sądów moich nie czynili, i ustawy moje odrzucili, i sabaty moje pogwałcili, a za plugawemi bałwanami ojców swoich oczy swe obrócili.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Dlategoż i Jam im dał ustawy nie dobre i sądy, w których żyć nie będą;
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
I splugawiłem ich z darami ich, gdy przewodzili przez ogień wszelkie otwarzające żywot, abym ich spustoszył, a żeby się dowiedzieli żem ja Pan.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Prztoż mów do domu Izraelskigo, synu człowieczy! a powiedz im: Tak mówi panujący Pan: Jeszcze i w tem lżyli mię ojcowie wasi, dopuszczając się przeciwko mnie przestępstwa,
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Że gdym ich wwiódł do ziemi, o którąm był podniósł rękę moję, żem ją im dać miał, gdzie ujrzeli jaki pagórek wysoki, albo jakie drzewo gałęziste, zaraz tam ofiarowali ofiary swoje, i dawali tam draźniące dary swoje, tamże kładli i wdzięczną wonno ść swoję, tamże sprawowali mokre ofiary swoje.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
A chociażem mówił do nich: Cóż to za wyżyna, do której wy chadzacie? Przecie ją zowią wyżyną aż do dnia tego.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Przetoż rzecz domowi Izraelskiemu: Tak mówi panujący Pan: Izali się wy drogami ojców waszych kalać macie, a z obrzydliwościami ich nierząd płodzić?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
I macież się kalać przy wszystkich plugawych bałwanach waszych, przynosząc dary wasze i przewodząc synów waszych przez ogień aż do dnia tego, a przecie odemnie rady szukać, o domie Izraelski? Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że się wy mnie więcej radzić nie będziecie.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
A to, co wstępuje na myśl waszę, nigdy się nie stanie. Wy mówicie: Będziemy jako inne narody, jako pokolenia innych ziem, drewnu i kamieniowi służące;
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że ręką możną i ramieniem wyciągnionem, a w popędliwości wylanej będę królował nad wami;
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
I wywiodę was z narodów, a zgromadzę was z ziem, do którycheście rozproszeni, ręką możną, i ramieniem wyciągnionem, i w popędliwości wylanej;
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
A prowadząc was po puszczy tych narodów, tam się z wami twarzą w twarz sądzić będę.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Jakom się sądził z ojcami waszymi na puszczy ziemi Egipskiej, tak się z wami sądzić będę, mówi panujący Pan;
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
I popędzę was pod rózgą, abym was przywiódł do związku przymierza.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
Ale z was wybiorę odpornych i występujących przeciwko mnie; z ziemi pielgrzymstwa ich wywiodę ich, wszakże do ziemi Izraelskiej nie wnijdą; i poznacie, żem Ja Pan.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Wy tedy, o domie Izraelski! tak mówi panujący Pan: Idźcież, służcie każdy plugawym bałwanom swoim i na potem, ponieważ mnie nie słuchacie; a imienia mego świętego nie kalajcie więcej darami waszemi, i plugawemi bałwanami waszemi.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Bo na świętej górze mojej, na wysokiej górze Izraeskiej, mówi panujący Pan, tam mi służyć będzie wszystek dom Izraeski, ile ich będzie w onej ziemi; tam ich łaskawie przyjmę, i tam się pytać będę o ofiarach waszych podnoszonych, i o pierwiastkach darów waszych ze wszystkiemi świętemi rzeczami waszemi.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Z wdzięczną wonnością łaskawie was przyjmę, gdy was wywiodę z narodów, a zgromadzę was z onych ziem, do którycheście rozproszeni byli, a tak poświęcony będę w was przed oczyma onych narodów.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
A poznacie, żem Ja Pan, gdy was wprowadzę do ziemi Izraelskiej, do ziemi onej, o którąm podniósł rękę moję, że ją dam ojcom waszym;
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
A wspomnicie tam na drogi wasze, i na wszystkie sprawy wasze, któremiście się splugawili, a obmierzniecie sami sobie przed obliczem waszem dla wszystkich złości waszych, któreście czynili.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Tam się dowiecie, żem Ja Pan, gdy wam to uczynię dla imienia mego, nie według dróg waszych złych, ani według spraw waszych skażonych, o domie Izraelski! mówi panujący Pan.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Synu człowieczy! obróć twarz twoję ku stronie południowej, a krop jako rosą na południe, i prorokuj przeciwko losowi pola południowego,
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
A rzecz lasowi południowemu: Słuchaj słowa Pańskiego: Tak mówi panujący Pan: Oto Ja rozniecę w tobie ogień, który pożre w tobie wszelkie drzewo zielone, i wszelkie drzewo suche; nie będzie ugaszony płomień pałający, i zgoreją w nim wszystkie twar ze od południa aż do północy.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
I ujrzy wszelkie ciało, żem go Ja Pan zapalił; nie będzie ugaszony.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
I rzekłem: Ach panujący Panie! Oni mówią o mnie: Ten tylko w przypowieściach mówi.

< Ezekiel 20 >