< Ezekiel 20 >
1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
I det syvende år, i den femte måned, på den tiende dag i måneden, kom nogen av Israels eldste for å spørre Herren, og de satte sig foran mig.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Da kom Herrens ord til mig, og det lød så:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Menneskesønn! Tal med Israels eldste og si til dem: Så sier Herren, Israels Gud: Er I kommet for å spørre mig? Så sant jeg lever, lar jeg mig ikke spørre av eder, sier Herren, Israels Gud.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Vil du dømme dem, vil du dømme, menneskesønn? Tal til dem om deres fedres vederstyggeligheter
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
og si til dem: Så sier Herren, Israels Gud: På den dag da jeg utvalgte Israel og løftet min hånd til ed for ætlingene av Jakobs hus og gav mig til kjenne for dem i Egyptens land, da jeg løftet min hånd til ed for dem og sa: Jeg er Herren eders Gud -
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
på den dag løftet jeg min hånd og tilsvor dem at jeg vilde føre dem ut av Egyptens land til et land som jeg hadde utsøkt for dem, et land som flyter med melk og honning, det fagreste av alle land.
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Og jeg sa til dem: Enhver av eder kaste bort de vederstyggeligheter hans øine henger ved, og gjør eder ikke urene med Egyptens motbydelige avguder! Jeg er Herren eders Gud.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Men de var gjenstridige mot mig og vilde ikke høre på mig; de kastet ikke bort de vederstyggeligheter som deres øine hang ved, og forlot ikke Egyptens motbydelige avguder. Da sa jeg at jeg vilde utøse min harme over dem, fullbyrde min vrede på dem midt i Egyptens land.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Men det jeg gjorde, det gjorde jeg for mitt navns skyld, forat det ikke skulde bli vanhelliget for det folks øine som de bodde blandt, og for hvis øine jeg gav mig til kjenne for dem for å føre dem ut av Egyptens land.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Og jeg førte dem ut av Egyptens land og lot dem dra inn i ørkenen.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Og jeg gav dem mine bud og kunngjorde dem mine lover; for det menneske som holder dem, skal leve ved dem.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Også mine sabbater gav jeg dem, så de skulde være til et tegn mellem mig og dem, forat de skulde vite at jeg er Herren, som helliger dem.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Men Israels hus var gjenstridig mot mig i ørkenen; de fulgte ikke mine bud og forkastet mine lover, enda det menneske som holder dem, får leve ved dem, og mine sabbater vanhelliget de grovelig. Da sa jeg at jeg vilde utøse min harme over dem i ørkenen og gjøre ende på dem.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Men det jeg gjorde, det gjorde jeg for mitt navns skyld, forat det ikke skulde bli vanhelliget for de folks øine for hvis øine jeg hadde ført dem ut.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Men jeg løftet også min hånd for dem i ørkenen og svor at jeg ikke vilde la dem komme inn i det land som jeg hadde gitt dem, det land som flyter med melk og honning, det fagreste av alle land,
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
fordi de forkastet mine lover og ikke fulgte mine bud og vanhelliget mine sabbater; for deres hjerte fulgte deres motbydelige avguder.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Men jeg viste dem skånsel og ødela dem ikke; jeg gjorde ikke aldeles ende på dem i ørkenen.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Og jeg sa til deres barn i ørkenen: Følg ikke eders fedres bud og hold ikke deres lover og gjør eder ikke urene med deres motbydelige avguder!
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Jeg er Herren eders Gud; følg mine bud og hold mine lover og gjør efter dem!
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Og hellighold mine sabbater! De skal være til et tegn mellem mig og eder, forat I skal vite at jeg, Herren, er eders Gud.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Men barna var gjenstridige mot mig; de fulgte ikke mine bud og holdt ikke mine lover, så de gjorde efter dem, enda det menneske som holder dem, får leve ved dem; mine sabbater vanhelliget de. Da sa jeg at jeg vilde utøse min harme over dem, fullbyrde min vrede på dem i ørkenen.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Men jeg drog min hånd tilbake og gjorde det jeg gjorde, for mitt navns skyld, forat det ikke skulde bli vanhelliget for de folks øine for hvis øine jeg hadde ført dem ut.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Men jeg løftet også min hånd for dem i ørkenen og svor at jeg vilde sprede dem blandt hedningefolkene og strø dem ut i landene,
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
fordi de ikke holdt mine lover, men forkastet mine bud og vanhelliget mine sabbater, og deres øine fulgte deres fedres motbydelige avguder.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Derfor gav jeg dem også bud som ikke var gode, og lover som de ikke kunde leve ved.
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Jeg lot dem bli urene ved sine offergaver, idet de lot alt som åpner mors liv, gå igjennem ilden, så jeg kunde ødelegge dem, forat de skulde kjenne at jeg er Herren.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Tal derfor til Israels hus, menneskesønn, og si til dem: Så sier Herren, Israels Gud: Også dermed hånte eders fedre mig at de viste troløshet mot mig;
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
jeg førte dem inn i det land som jeg med løftet hånd hadde svoret å ville gi dem; men så snart de så en høi bakke eller et løvrikt tre, ofret de der sine slaktoffer og bar der frem sine harmelige offergaver; dit kom de med sin søte offerduft, og der utøste de sine drikkoffer.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Da sa jeg til dem: Hvad er disse offerhauger, siden I søker til dem? - Og allikevel kalles de offerhauger den dag idag.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Si derfor til Israels hus: Så sier Herren, Israels Gud: Hvad? I gjør eder urene på samme vis som eders fedre og driver hor med deres vederstyggeligheter;
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
når I bærer frem eders gaver og lar eders barn gå gjennem ilden, gjør I eder ennu den dag idag urene ved alle eders motbydelige avguder - og jeg skulde la mig spørre av eder, Israels hus? Så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, jeg lar mig ikke spørre av eder.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
Og aldri skal det skje det som kommer eder i sinne, når I sier: Vi vil være som hedningene, som folkene rundt om i landene; vi vil dyrke tre og sten.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, jeg vil regjere over eder med sterk hånd og med utrakt arm og med utøst harme.
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Og jeg vil føre eder ut fra de folk og samle eder fra de land som I nu er spredt i, med sterk hånd og med utrakt arm og med utøst harme.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Og jeg vil føre eder til folkenes ørken, og der vil jeg gå i rette med eder, åsyn til åsyn;
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
likesom jeg gikk i rette med eders fedre i ørkenen ved Egyptens land, således vil jeg gå i rette med eder, sier Herren, Israels Gud.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Og jeg vil la eder gå forbi under hyrdestaven, og jeg vil føre eder inn i paktens bånd,
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
og jeg vil skille ut fra eder de gjenstridige og dem som er falt fra mig; fra deres utlendighets land vil jeg føre dem ut, men til Israels land skal ingen av dem komme, og I skal kjenne at jeg er Herren.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Og I, Israels hus! Så sier Herren, Israels Gud: Gå avsted, dyrk hver sine motbydelige avguder! Men siden skal I sannelig høre på mig og ikke mere vanhellige mitt hellige navn ved eders gaver og ved eders motbydelige avguder.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
For på mitt hellige berg, på Israels høie berg, sier Herren, Israels Gud, der skal hele Israels hus, alle som er i landet, tjene mig; der vil jeg ha behag i dem, og der vil jeg spørre efter eders offergaver og efter den førstegrøde som I bærer frem av alt det I helliger.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
For den søte dufts skyld vil jeg ha velbehag i eder, når jeg fører eder ut fra de folk og samler eder fra de land som I nu er spredt i, og åpenbarer min hellighet på eder for hedningefolkenes øine.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Og I skal kjenne at jeg er Herren, når jeg fører eder til Israels land, til det land som jeg med løftet hånd har svoret å ville gi eders fedre.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Og der skal I komme i hu eders ferd og alle de gjerninger som I har gjort eder urene med, og I skal vemmes ved eder selv for alle de onde gjerninger som I har gjort.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Og I skal kjenne at jeg er Herren, når jeg gjør således med eder, for mitt navns skyld og ikke efter eders onde ferd og eders skamløse gjerninger, Israels hus, sier Herren, Israels Gud.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Menneskesønn! Vend ditt åsyn mot syd og prek mot Syden og spå mot skoglandet i syd!
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
Og si til Sydens skog: Hør Herrens ord! Så sier Herren, Israels Gud: Se, jeg tender en ild i dig, og den skal fortære hvert friskt tre og hvert tørt tre i dig; den luende ild skal ikke utslukkes, men alle ansikter fra syd til nord skal bli forbrent ved den.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Og alt kjød skal se at jeg, Herren, har tendt den; den skal ikke utslukkes.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Da sa jeg: Akk, Herre, Herre! De sier om mig: Han taler jo bare i lignelser!