< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
Kwasekusithi ngomnyaka wesikhombisa, ngenyanga yesihlanu, ngolwetshumi lwenyanga, abathile babadala bakoIsrayeli beza ukuzabuza iNkosi, bahlala phambi kwami.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Ilizwi leNkosi laselifika kimi lisithi:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Ndodana yomuntu, khuluma kubadala bakoIsrayeli, uthi kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Lize ukuzangibuza yini? Kuphila kwami, isibili kangiyikubuzwa yini, itsho iNkosi uJehova.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Uzabahlulela yini, uzabahlulela yini, ndodana yomuntu? Bazise izinengiso zaboyise;
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
uthi kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Ngosuku engakhetha ngalo uIsrayeli, ngaphakamisa isandla sami kunzalo yendlu kaJakobe, ngazazisa kubo elizweni leGibhithe, lapho ngiphakamisa isandla sami kibo, ngisithi: NgiyiNkosi uNkulunkulu wenu.
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Ngalolusuku ngaphakamisa isandla sami kubo, ukuthi ngibakhuphe elizweni leGibhithe ngibase elizweni engangibahlolele lona, eligeleza uchago loluju, eliludumo lwawo wonke amazwe.
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Ngasengisithi kubo: Lahlani ngulowo lalowo izinengiso zamehlo akhe, lingazingcolisi ngezithombe zeGibhithe: NgiyiNkosi uNkulunkulu wenu.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Kodwa bangivukela, bengavumi ukulalela kimi, kabalahlanga ngulowo lalowo izinengiso zamehlo abo, kabatshiyanga izithombe zeGibhithe. Ngasengisithi ngizathululela ukuthukuthela kwami phezu kwabo, ukuze ngiphelelise ulaka lwami ngimelene labo phakathi kwelizwe leGibhithe.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Kodwa ngakwenza ngenxa yebizo lami, ukuze lingangcoliswa emehlweni ezizwe, ababephakathi kwazo, engazazisa kubo phambi kwamehlo azo, ukubakhupha elizweni leGibhithe.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Ngakho ngabakhupha elizweni leGibhithe, ngabangenisa enkangala.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Ngabanika izimiso zami, ngabazisa izahlulelo zami, okuthi nxa umuntu ezenza, uzaphila ngazo.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Ngabanika futhi amasabatha ami ukuze abe yisibonakaliso phakathi kwami labo, ukuze bazi ukuthi ngiyiNkosi ebangcwelisayo.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Kodwa indlu kaIsrayeli yangivukela enkangala; kabahambanga ngezimiso zami, badelela izahlulelo zami, okuthi nxa umuntu ezenza, uzaphila ngazo; lamasabatha ami bawangcolisa kakhulu. Ngasengisithi ngizathululela ukuthukuthela kwami phezu kwabo enkangala, ukuze ngibaqede.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Kodwa ngakwenza ngenxa yebizo lami, ukuze lingangcoliswa emehlweni ezizwe, engabakhupha emehlweni azo.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Futhi lami ngabaphakamisela isandla sami enkangala, ukuthi kangiyikubaletha elizweni engangilinike bona, eligeleza uchago loluju, eliludumo lwawo wonke amazwe;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
ngoba badelela izahlulelo zami, kabahambanga ngezimiso zami, kodwa bangcolisa amasabatha ami, ngoba inhliziyo yabo yalandela izithombe zabo.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Lanxa kunjalo ilihlo lami labahawukela ukuze ngingababhubhisi, futhi kangibaqedanga enkangala.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Kodwa ngathi kubantwana babo enkangala: Lingahambi ngezimiso zaboyihlo, lingagcini izahlulelo zabo, lingazingcolisi ngezithombe zabo.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
NgiyiNkosi uNkulunkulu wenu; hambani ngezimiso zami, ligcine izahlulelo zami, lizenze.
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Lingcwelise amasabatha ami, abe yisibonakaliso phakathi kwami lani, ukuze lazi ukuthi ngiyiNkosi uNkulunkulu wenu.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Kodwa abantwana bangivukela; kabahambanga ngezimiso zami, kabagcinanga izahlulelo zami ukuthi bazenze; okuthi nxa umuntu ezenza, uzaphila ngazo; bawangcolisa amasabatha ami; ngasengisithi ngizathululela intukuthelo yami phezu kwabo, ukuthi ngiphelelise ulaka lwami ngimelene labo enkangala.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Kodwa ngabuyisa isandla sami, ngenza ngenxa yebizo lami, ukuze lingangcoliswa phambi kwamehlo ezizwe, engangibakhuphe phambi kwamehlo azo.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Mina ngabaphakamisela isandla sami futhi enkangala, ukuthi ngizabahlakaza phakathi kwezizwe, ngibasabalalisele emazweni;
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
ngoba bengazenzanga izahlulelo zami, kodwa badelela izimiso zami, bangcolisa amasabatha ami, lamehlo abo alandela izithombe zaboyise.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Ngakho mina ngabanika futhi izimiso ezazingalunganga, lezahlulelo ababengeke baphile ngazo.
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Ngasengibangcolisa kuzo izipho zabo, ekudabuliseni kwaboemlilweni konke okuvula isizalo, ukuze ngibachithe, ukuze bazi ukuthi ngiyiNkosi.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Ngakho, ndodana yomuntu, khuluma kuyo indlu yakoIsrayeli, uthi kubo: Itsho njalo iNkosi uJehova: Lakulokhu oyihlo bangihlambazile, ngokuthi baphambeke isiphambeko bemelene lami.
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Lapho sengibalethe elizweni, engaphakamisela isandla sami ngalo ukuthi ngibanike lona, babona lonke uqaqa oluphakemeyo, lazo zonke izihlahla eziqatha, bahlaba khona imihlatshelo yabo, banikela khona isicunulo somnikelo wabo, bafaka khona iphunga labo elimnandi, bathulula khona iminikelo yabo yokunathwayo.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Ngasengisithi kubo: Iyini indawo ephakemeyo eliya kuyo? Lebizo layo lithiwa yiNdawo ePhakemeyo kuze kube lamuhla.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Ngakho tshono kuyo indlu kaIsrayeli: Itsho njalo iNkosi uJehova: Lizazingcolisa ngendlela yaboyihlo yini, liphinge lilandela izinengiso zabo?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
Ngoba lapho linikela izipho zenu, lapho lisenza amadodana enu adabule emlilweni, liyazingcolisa ngezithombe zenu zonke kuze kube lamuhla. Mina-ke ngizabuzwa yini na, wena ndlu kaIsrayeli? Kuphila kwami, itsho iNkosi uJehova, isibili kangiyikubuzwa yini.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
Lalokho okuvela engqondweni yenu kakuyikuba khona ngitsho, elikutshoyo ukuthi: Sizakuba njengabezizwe, njengensapho zamazwe, ukuthi sikhonze isigodo lelitshe.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Kuphila kwami, itsho iNkosi uJehova, isibili ngizabusa phezu kwenu ngesandla esilamandla langengalo eyeluliweyo langolaka oluthululiweyo!
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Ngoba ngizalikhupha ebantwini, ngiliqoqe emazweni elihlakazekele kuwo, ngesandla esilamandla langengalo eyeluliweyo langolaka oluthululiweyo.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Njalo ngizaliletha enkangala yabantu, ngizaphikisana lani lapho ubuso ngobuso.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Njengalokhu ngaphikisana laboyihlo enkangala yelizwe leGibhithe, ngokunjalo ngizaphikisana lani, itsho iNkosi uJehova.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Njalo ngizalidlulisa ngaphansi kwentonga, ngilingenise kusibopho sesivumelwano.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
Ngihlanze ngikhuphe phakathi kwenu abavukeli lalabo abaphambeka bemelene lami, ngibakhuphe elizweni lokuhlala kwabo njengabezizwe, kodwa kabayikungena emhlabathini wakoIsrayeli. Khona lizakwazi ukuthi ngiyiNkosi.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Lina-ke, ndlu kaIsrayeli, itsho njalo iNkosi uJehova, hambani likhonze, ngulowo lalowo izithombe zakhe, langemva kwalokho, uba lingangilaleli; kodwa lingangcolisi futhi ibizo lami elingcwele ngezipho zenu langezithombe zenu.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Ngoba entabeni yami engcwele, entabeni yengqonga yakoIsrayeli, itsho iNkosi uJehova, lapho izangikhonza indlu yonke yakoIsrayeli, bonke elizweni; khona ngizabemukela, lakhona ngibize iminikelo yenu, lezithelo zokuqala zeminikelo yenu, lazo zonke izinto zenu ezingcwele.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Ngizalemukela ngephunga elimnandi nxa ngilikhupha ebantwini, ngiliqoqe emazweni ebelihlakazelwe kuwo; njalo ngizangcweliswa phakathi kwenu phambi kwamehlo ezizwe.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Lizakwazi-ke ukuthi ngiyiNkosi, lapho sengilingenise emhlabathini wakoIsrayeli, elizweni engaliphakamisela isandla sami ukulinika oyihlo.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Lapho-ke lizakhumbula izindlela zenu lezenzo zenu zonke, elazingcolisa ngazo; njalo lizazenyanya phambi kobuso benu ngenxa yazo zonke izinto ezimbi elizenzileyo.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Beselisazi ukuthi ngiyiNkosi, nxa ngenze kini ngenxa yebizo lami, hatshi njengokwezindlela zenu ezimbi, kumbe njengokwezenzo zenu zenkohlakalo, lina ndlu kaIsrayeli, itsho iNkosi uJehova.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ilizwi leNkosi lafika kimi futhi lisithi:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Ndodana yomuntu, misa ubuso bakho ngasendleleni yeningizimu, utshumayele ngaseningizimu, uprofethe umelene legusu lensimu yeningizimu;
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
uthi kilo igusu leningizimu: Zwana ilizwi leNkosi: Itsho njalo iNkosi uJehova: Khangela, ngizaphemba umlilo phakathi kwakho, njalo uzaqeda phakathi kwakho sonke isihlahla esiluhlaza laso sonke isihlahla esomileyo; ilangabi elivuthayo kaliyikucitshwa, kodwa kuzatshiswa ngalo bonke ubuso kusukela eningizimu kuze kufike enyakatho.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Futhi yonke inyama izabona ukuthi mina Nkosi ngiwuphembile, kawuyikucitshwa.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Ngasengisithi: Hawu, Nkosi Jehova! Bathi ngami: Kakhulumi imifanekiso yini?

< Ezekiel 20 >