< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
És lőn a hetedik esztendőben, az ötödik hónap tizedikén: jövének férfiak Izráel vénei közül megkérdezni az Urat, és leülének előttem.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
És lőn az Úr beszéde hozzám, mondván:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Embernek fia! beszélj Izráel véneivel, és mondjad nékik: Így szól az Úr Isten: Nemde engem megkérdezni jöttetek-é? Élek én, hogy nem engedem, hogy megkérdezzetek engem, ezt mondja az Úr Isten.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Ítélni akarod őket, ítélni akarsz, embernek fia? add tudtokra atyáik útálatosságait!
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
És mondjad nékik: Így szól az Úr Isten: Azon a napon, melyen elválasztám Izráelt, és fölemelém kezemet a Jákób háza magvának, és megismertetém magamat velök Égyiptom földjén, és kezemet fölemelém nékik, mondván: Én vagyok az Úr, a ti Istentek!
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Azon a napon felemeltem kezemet nékik, hogy kihozzam őket Égyiptom földjéről a földre, a melyet kinéztem vala nékik, a mely téjjel és mézzel folyó, ékessége az minden tartománynak;
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
És mondék nékik: Kiki az ő szemei útálatosságait elvesse, és Égyiptom bálványaival meg ne fertéztessétek magatokat; én vagyok az Úr, a ti Istentek!
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
De pártot ütének ellenem, s nem akarának hallgatni reám. Senki az ő szeme útálatosságait el nem veté és Égyiptom bálványait el nem hagyá. Mondám azért, hogy kiöntöm búsulásomat rájok, teljessé teszem haragomat rajtok Égyiptom földjének közepette.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
De cselekedtem az én nevemért, hogy ez meg ne gyaláztassék a pogányok szemei előtt, a kik közt ők valának, a kiknek szemei előtt megismertettem magamat velök, hogy kihozom őket Égyiptom földjéről.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
És kihozám őket Égyiptom földjéről, s vivém őket a pusztába.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
És adám nékik parancsolatimat, és törvényeimet kijelentém nékik, melyeket az ember ha cselekszik, él azok által.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
És adám nékik szombataimat is, hogy legyenek jegyül köztem és ő közöttök; hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr, az ő megszentelőjök.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
De pártot üte ellenem Izráel háza a pusztában, az én parancsolatimban nem jártak és törvényeimet megveték, a melyeket az ember ha cselekszik, él azok által; és az én szombataimat megfertéztették felette igen. Mondám azért, hogy kiöntöm búsulásomat rájok a pusztában, hogy elveszessem őket.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
De cselekedtem az én nevemért, hogy meg ne gyaláztassék a pogányok szemei előtt, a kiknek szeme láttára kihoztam vala őket.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
És föl is emelém én kezemet nékik a pusztában, hogy be nem viszem őket a földre, melyet adtam nékik, mely téjjel és mézzel folyó, ékessége az minden tartománynak;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
Mivelhogy törvényeimet megvetették és parancsolataimban nem jártak, és szombataimat megfertéztették, mert bálványaik után járt vala szívök:
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Mindazáltal kedvezett szemem nékik, hogy el ne veszessem őket, és nem vetettem nékik véget a pusztában.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
És mondék fiaiknak a pusztában: A ti atyáitok parancsolataiban ne járjatok, és az ő törvényeiket meg ne tartsátok, s bálványaikkal magatokat meg ne fertéztessétek.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Én vagyok a ti Uratok, Istentek: az én parancsolatimban járjatok, az én törvényimet tartsátok meg, és azokat cselekedjétek.
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
És az én szombatimat megszenteljétek, hogy legyenek jegyül én köztem és tiköztetek, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, a ti Istenetek.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
De pártot ütének a fiak ellenem, parancsolataimban nem jártak, s törvényeimet meg nem tartották, hogy azokat cselekedjék, a melyeket az ember ha cselekszik, él azok által; szombataimat megfertéztették; mondám azért, hogy kiöntöm búsulásomat rájok, teljessé teszem haragomat rajtok a pusztában.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
De visszavontam kezemet, s cselekedtem az én nevemért, hogy meg ne gyaláztassék a pogányok előtt, a kiknek szeme láttára kihoztam őket.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Föl is emelém én kezemet nékik a pusztában, hogy elszélesztem őket a pogányok közé, és szétszórom őket a tartományokba;
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
Mivelhogy törvényeimet nem cselekedték, s parancsolataimat megvetették, és szombataimat megfertéztették, s atyáik bálványai után voltak szemeik.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
És én is adtam nékik nem jó parancsolatokat, s törvényeket, a melyek által ne éljenek.
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
S megfertéztetém őket ajándékaikkal, mikor tűzön vittek át minden elsőszülöttet, hogy elpusztítsam őket, hogy megtudják, hogy én vagyok az Úr.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Azért szólj az Izráel házának, embernek fia, és mondjad nékik: Így szól az Úr Isten: Még ebben is gyalázattal illettek engem a ti atyáitok, hogy hűtlenül elszakadának tőlem:
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Mikor bevittem őket a földre, a melyért fölemeltem kezemet, hogy azt nékik adom, megtekintének minden magas halmot és minden sűrű ágú fát, és ott áldozzák vala az ő áldozatjaikat, és ott adják vala haragra ingerlő ajándékaikat; és oda teszik vala kedvelt illatjokat, és oda öntik vala italáldozataikat.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
És mondék nékik: Micsoda e magaslat, a hova ti gyülekeztek? És nevezik nevét magaslatnak mind e mai napig.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Ennekokáért mondjad Izráel házának: Így szól az Úr Isten: Nemde a ti atyáitok módjára fertéztetitek-é meg magatokat, és az ő útálatosságaik szerint paráználkodtok-é?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
És ajándékaitok vitelével, mikor átviszitek fiaitokat a tűzön, fertéztetitek meg magatokat minden bálványaitok előtt mind e mai napig, és én engedjem, hogy megkérdezzetek engem, Izráel háza? Élek én, ezt mondja az Úr Isten, hogy nem engedem, hogy megkérdezzetek engem!
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
És a mi lelketekben támadt, semmiképpen sem lesz meg, hogy azt mondjátok: Leszünk olyanok, mint a pogányok, mint a tartományok nemzetségei, szolgálván fának és kőnek.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Élek én, ezt mondja az Úr Isten, hogy erős kézzel és kinyújtott karral és kiontott búsulással uralkodom rajtatok.
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
És kiviszlek titeket a népek közül, és egybegyűjtelek titeket a tartományokból, melyekbe elszéledtetek, erős kézzel és kinyújtott karral és kiontott búsulással;
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
És vezetlek titeket a népek pusztájára, hol szemtől-szembe törvénykezem veletek.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
A mint törvénykeztem a ti atyáitokkal Égyiptom földének pusztájában; úgy törvénykezem veletek, ezt mondja az Úr Isten.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
És átviszlek titeket a vessző alatt, és hozlak titeket a frigynek kötelébe.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
És kitisztítom közületek a pártosokat, és az ellenem támadókat, és a földről, melyen jövevények voltak, kihozom őket, de Izráel földjére nem fognak bemenni, hogy megtudjátok, hogy én vagyok az Úr!
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Ti pedig, Izráel háza, azt mondja az Úr Isten, mindenitek járjon az ő bálványai után és szolgáljon azoknak; de azután bizony, hallgatni fogtok rám, és az én szent nevemet többé meg nem fertéztetitek ajándékitokkal és bálványaitokkal.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Mert az én szent hegyemen, Izráelnek magas hegyén, ezt mondja az Úr Isten, ott fog szolgálni nékem Izráel egész háza együtt azon a földön; ott kedvelem őket, ott kivánom meg a ti áldozataitokat és ajándékitoknak első zsengéjét mindenben, mit nékem szenteltek.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Kedves illatban kedvellek titeket, mikor kihozlak titeket a népek közül és egybegyűjtelek titeket a tartományokból, melyeken elszéledtetek, és megszenteltetem ti bennetek a pogányok szemei előtt.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
És megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, mikor beviszlek titeket Izráel földjére, arra a földre, melyért fölemeltem kezemet, hogy adom azt a ti atyáitoknak.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
És ott megemlékeztek útaitokról, s minden cselekedeteitekről, melyekkel magatokat megfertéztettétek, s megútáljátok ti magatokat minden gonoszságtokért, melyeket cselekedtetek.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
És megtudjátok, hogy én vagyok az Úr, mikor cselekszem veletek az én nevemért, és nem a ti gonosz útaitok és romlott cselekedeteitek szerint, oh Izráel háza, ezt mondja az Úr Isten!
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
És lőn az Úrnak beszéde hozzám, mondván:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Embernek fia! fordítsd orczádat délre, és szólj dél felé és prófétálj a déli mező erdeje ellen!
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
És mondjad a dél erdejének: Halld meg az Úr beszédét, így szól az Úr Isten: Ímé, én tüzet gyújtok benned, hogy megemészszen te benned minden zöldelő és minden aszú fát. Meg nem aluszik a lángoló láng, és megég a miatt minden orcza déltől északig.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
És meglátja minden test, hogy én, az Úr gyújtottam meg azt, mert meg nem aluszik.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
És mondék: Ah, ah, Uram Isten! ezek azt mondják nékem: Hát nem példabeszédekben beszél ez?

< Ezekiel 20 >