< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
EIA hoi kekahi, i ka hiku o ka makahiki, i ka lima o ka mahina, i ka la umi o ua mahina la, hele mai kekahi poe o na lunakahiko o ka Iseraela e ninau ia Iehova, a noho iho la imua o ko'u alo.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Alaila hiki mai ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
E ke keiki a ke kanaka, e olelo aku oe i na lunakahiko o ka Iseraela, e i aku ia lakou, Ke i mai nei Iehova ka Haku penei; Hele mai nei oukou e ninau ia'u? Ma ko'u ola ana, aole au e ninauia e oukou, wahi a Iehova ka Haku.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
E hoohewa oe ia lakou, e hoohewa ia lakou, e ke keiki a ke kanaka? E hoike ia lakou i na mea I hoopailua o ko lakou poe makua.
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
E olelo aku ia lakou, Ke i mai nei o Iehova ka Haku penei; i ka la i koho aku ai au i ka Iseraela, a i hapai ai i kuu lima i na keiki a ka ohana a Iakoba, a i hoike ai ia'u iho ia lakou ma ka aina Aigupita, i ka wa i hapai ai au i kuu lima ia lakou, me ka i ana'e, Owau no Iehova ko oukou Akua;
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
I ka la i hapai ai au i kuu lima ia lakou, e lawe mai ia lakou mai ka aina mai o Aigupita, i ka aina a'u i nana aku ai no lakou, e kahe ana ka waiu a me ka meli, ka mea nani o na aina a pau:
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Alaila olelo aku la au ia lakou, E haalele oukou kela kanaka keia kanaka i ka mea inainaia o kona mau maka, mai noho a hoohaumia ia oukou iho ma na kii o Aigupita: owau no Iehova ko oukou Akua.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Aka, kipi mai la lakou ia'u, aole o lakou makemake e hoolohe mai ia'u; aole lakou i haalele kela kanaka keia kanaka i ka mea inainaia o ko lakou mau maka, aole hoi i haalele i na kii o Aigupita: alaila olelo aku au, E ninini aku au i ko'u ukiuki maluna o lakou, e hooko i ko'u huhu ia lakou mawaenakonu o ka aina o Aigupita.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Aka, ua hana au no ko'u inoa, i ole ia e hoohaumiaia i na maka o na lahuikanaka, iwaena o ia poe i noho ai lakou: imua hoi o ko lakou mau maka i hoike ai au ia'u iho ia lakou, i ka lawe ana mai ia lakou mai loko mai o ka aina o Aigupita.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
A lawe mai la hoi au ia lakou mai ka aina mai o Aigupita, a alakai ia lakou iloko o ka waonahele.
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Haawi aku la hoi au i ka'u mau kauoha ia lakou, a hoike aku la hoi au i ko'u mau kanawai ia lakou, o na mea ke malamaia e ke kanaka, e ola ia ilaila.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
A o ko'u mau Sabati kekahi ka'u i haawi aku ai ia lakou, i hoailona iwaena o'u a me lakou, i ike lakou owau no Iehova ka mea nana lakou i hoano.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Aka, kipi mai la ka ohana a Iseraela ia'u ma ka waonahele, aole lakou i hele ma ka'u mau kauoha, ua hoowahawaha hoi lakou i ko'u mau kanawai, o na mea ke malamaia e ke kanaka, e ola ia ilaila: a ua hoohaumia nui lakou i ko'u mau Sabati. Alaila elele aku la au, E ninini aku au i ko'u ukiuki maluna o lakou ma ka waonahele, e hoopau ai ia lakou.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Aka, hana iho la au no ko'u inoa, i ole ia e hoohaumiaia i na maka o na lahuikanaka, imua o ko lakou alo i lawe mai ai au ia lakou iwaho.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Ua hapai no nae au i kuu lima ia lakou, ma ka waonahele, e lawe ole au ia lakou i ka aina a'u i haawi aku ai, e kahe ana ka waiu a me ka meli, ka mea naui o na aina a pau;
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
No ka mea, ua hoowahawaha lakou i ko'u mau kanawai, aole hoi i hele ma ka'u mau kauoha, aka, ua hoohaumia lakou i ko'u mau Sabati; no ka mea, ua hele ko lakou naau mamuli o ko lakou mau kii.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Aka hoi, ua aloha aku ko'u maka ia lakou i ole e luku ia lakou; aole hoi au i hoopau ia lakou ma ka waonahele.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Aka, olelo aku la au i ka lakou mau keiki ma ka waonahele, Mai hele oukou ma na oihana a ko oukou mau makuakane, aole hoi e malama i ko lakou mau kanawai, aole hoi e hoohaumia ia oukou iho me ko lakou mau akuakii.
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Owau no Iehova ko oukou Akua; e hele hoi oukou ma ka'u mau kauoha, a e malama i ko'u mau kanawai, a e hana oukou ma ia mau mea:
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
A e hoauo hoi i ko'u mau Sabati; a e lilo ia i hoailona iwaena o'u a me oukou, i ike oukou owau no Iehova ko oukou Akua.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Kipi mai la nae na keiki ia'u; aole lakou i hele ma ka'u mau kauoha, aole hoi lakou i malama i ko'u mau kanawai e hana malaila, o ua mea ke malamaia e ke kanaka, e ola ia ilaila: ua hoohaumia lakou i ko'u mau Sabati; alaila olelo iho la au, e niuini aku au i ko'u ukiuki maluna o lakou, e hooko ai i ko'u huhu ia lakou ma ka waonahele.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Aka, hoihoi mai au i kuu lima, a hana hoi au no ko'u inoa, i ole ia e hoohaumiaia i na maka o na lahuikanaka, imua o ko lakou alo i lawe mai ai au ia lakou.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Hapai ae la hoi au i kuu lima ia lakou ma ka waonahele, e hooauhee liilii ia lakou iwaena o na lahuikanaka, a e hoopuehu ia lakou ma na aina.
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
No ka mea, aole lakou i hana ma ko'u mau kanawai, aka, ua hoowahawaha i ka'u mau kauoha, a ua hoohaumia i ko'u mau Sabati, a o ko lakou mau maka, aia no mamuli o na kii o ko lakou mau makua.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Nolaila hoi, haawi au no lakou i na kauoha pono ole, a me na kanawai i ola ole ai lakou ilaila;
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
A ua hoohaumia au ia lakou iloko o ko lakou mau haawina; i ko lakou hoohele ana iwaena o ke ahi i na mea a pau i wehe ae i ka opu, i hooneoneo au ia lakou, i mea e ike ai lakou owau no Iehova.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Nolaila e olelo aku, e ke keiki a ke kanaka, i ka ohana a Iseraela, a e i aku ia lakou, Ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; Maloko no hoi o keia, i hoino wale mai ai ko oukou mau makua ia'u, i ka lakou hana hewa ana mai ia'u:
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
I ko'u lawe ana mai ia lakou i ka aina, nona i hapai ai au i kuu lima e haawi aku au ia no lakou, a ike lakou i na puu kiekie a pau, a me na laau paapu a pau, alaila kaumaha ae la lakou i ka lakou mau mohai malaila; a haawi lakou ilaila i ka hoonaukiuki ana o ka lakou alana: ilaila hoi i hana aku ai lakou i ko lakou mea ala, a i ninini aku ai i ka lakou mau mohai inu.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Alaila olelo aku la au ia lakou, Heaha ka wahi kiekie e hele aku ai oukou? A ua kapaia kona inoa o Bama a hiki i keia la.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Nolaila e olelo aku i ka ohana a Iseraela, Ke i mai nei Iehova ka Haku penei; Ua haumia anei oukou mamuli o ka aoao o ko oukou mau makua? A ua moe kolohe anei oukou mamuli o ko lakou mau mea inainaia?
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
No ka mea, i ko oukou kaumaha ana i ka oukou mau mohai, i ko oukou hoohele ana i ka oukou mau keiki iwaena o ke ahi, ua hoohaumia oukou ia oukou iho me ko oukou mau akuakii a pau, a hiki i keia la; a e uinauia mai anei au e oukou, e ka ohana a Iseraela? Na ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, aole au e ninauia mai e oukou.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
A o ka mea i kupu iloko o ko oukou naau, aole loa ia, i ka oukou olelo ana, E like kakou me na lahuikanaka, e like me na ohana o na aina i ka hoomana i ka laau a me ka pohaku.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Ma ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, He oiaio, me ka lima ikaika, a me ka lima kikoo aku, a me ka ukiuki i nininiia aku, e alii ai au maluna o oukou:
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
A e lawe mai au ia oukou mai waena mai o kanaka, a e hoakoakoa au ia oukou mai na aina mai i hooauheeia'i oukou, me ka lima ikaika, a me ka lima kikoo, a me ka ukiuki i niniuiia'ku.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
A e lawe au ia oukou iloko o ka waouahele o kanaka, a malaila au e hakaka ai me oukou, he maka no he maka.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Me au hoi i hakaka ai me ko oukou mau makua ma ka waonahele o ka aina Aigupita, pela e hakaka ai au me oukou, wahi a Iehova ka Haku.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
A e hoohele ae au ia oukou malalo ae o ko kookoo, a e lawe au ia oukou iloko o ka mea paa o ka berita:
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
A e holoi aku wau mai waena aku o oukou i na kipi, a me ka poe i hana hewa mai ia'u; e lawe mai au ia lakou mai ka aina mai i noho iki ai lakou, aole nae lakou e komo i ka aina o ka Iseraela; a e ike i oukou owau no Iehova.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
A oukou hoi, e ka ohana a Iseraela, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; E hele oukou, a e malama kela mea keia mea i kona mau kii, a mahope aku hoi, ina aole oukou e hoolohe mai ia'u: aka, mai hoohaumia hou i ko'u inoa, me ka oukou mau haawina a me ko oukou mau akuakii.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
No ka mea, ma ko'u mauna hoano, ma ka mauna kiekie o ka Iseraela, wahi a Iehova ka Haku, malaila e malama mai ai ia'u ka ohana a pau a Iseraela, o ka poe a pau loa ma ka aina; malaila e maliu ai au ia lakou, malaila e kauoha ai au i ka oukou mau mohai, a me na hua mua o ka oukou mau alana, me ko oukou mau mea hoano a pau.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
E maliu au ia oukou me ko oukou mea ala ono, aia lawe mai au ia oukou mai ka poe kanaka mai, a e hoakoakoa ia oukou mai loko mai o na aina i hooauhee liilii ia ai oukou; a e hoanoia mai au ma o oukou la i na maka o na lahuikanaka.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
A e ike oukou owau no Iehova, aia lawe mai au ia oukou iloko o ka aina o ka Iseraela, i ka aina nona i hapai ai au i kuu lima e haawi aku ia i ko oukou poe makua.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
A malaila e hoomanao ai oukou i ko oukou mau aoao, a me ka oukou mau hana a pau, na mea i haumia ai oukou; a e hoowahawaha oukou ia oukou iho i ko oukou mau maka, no na mea ino a pau a oukou i hana aku ai.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
A e ike no oukou owau no Iehova, aia hana au me oukou no ko'u inoa, aole mamuli o ko oukou mau aoao hewa, aole hoi e like me ka oukou hana hewa ana, e ka ohana a Iseraela, wahi a Iehova ka Haku.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Hiki mai la hoi ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
E ke keiki a ke kanaka, e hookupono oe i kou wahi maka i ke kukuluhema, a e hoolei aku i kau olelo ma ka aoao hema e wanana ku e oe i ka ululaau o ka aina hema:
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
A e olelo aku i ka ululaau o ke kukuluhema, E hoolohe i ka olelo a Iehova, no ka mea, ke olelo mai nei Iehova ka Haku, penei; Aia hoi, e kukuni au i ke ahi iloko ou, a e hoopau ae ia i na laau maka a pau iloko ou, a me na laau maloo a pau; a o ka lapalapa e lapalapa ana aole loa ia e kinaiia, a e wela ilaila na wahi maka a pau mai ke kukuluhema a ke kukuluakau.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
A e ike no ka io a pau, na'u na Iehova ia i kukuni, aole no ia e kinaiia.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
I aku la hoi au, Auwe, e Iehova ka Haku ke olelo nei lakou no'u, Aole anei ia e olelo i na olelo nane?

< Ezekiel 20 >