< Ezekiel 20 >

1 Ní ọjọ́ kẹwàá, oṣù karùn-ún ọdún keje, ní díẹ̀ nínú àwọn àgbàgbà Israẹli wá wádìí lọ́wọ́ Olúwa, wọn jókòó níwájú mi.
Ja tapahtui seitsemäntenä vuotena, kymmenentenä päivänä viidennessä kuukaudessa, että muutamia Israelin vanhimmista tuli kysymään Herralta; ja he istuivat minun eteeni.
2 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
Silloin tapahtui Herran sana minulle ja sanoi:
3 “Ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn àgbàgbà Israẹli, kì ó sì wí fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ṣe ki ẹ lè wádìí lọ́dọ̀ mi ni ẹ ṣe wá? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi kì yóò gbà kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.’
Sinä, ihmisen poika, puhu Israelin vanhimpain kanssa, ja sano heille: näin sanoo Herra, Herra: oletteko te tulleet kysymään minulta? Niin totta kuin minä elän, en tahdo minä teitä vastata, sanoo Herra, Herra.
4 “Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí? Ìwọ fẹ́ dájọ́ wọn bí ọmọ ènìyàn? Nítorí náà fi gbogbo ìwà ìríra baba wọn kò wọ́n lójú,
Mutta jos sinä ihmisen poika tahdot tuomita heitä, niin tuomitse heitä näin: ilmoita heille heidän isäinsä kauhistus.
5 kí ó sì sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, ní ọjọ́ tí mo yàn Israẹli, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ìbúra sí àwọn ọmọ ilé Jakọbu, mo sì fi ara mi hàn wọn ní Ejibiti, mo gbé ọwọ́ mi sókè nínú ẹ̀jẹ́ wí pé, “Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Ja sano heille: näin sanoo Herra, Herra: siihen aikaan, kuin minä valitsin Israelin, nostin minä käteni Jakobin huoneen siemenelle, ja annoin heidän tuta minuani Egyptin maalla; ja tosin minä nostin käteni heille, ja sanoin: minä olen Herra teidän Jumalanne.
6 Ní ọjọ́ náà mo lọ búra fún wọn pé, èmi yóò mú wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti lọ sí ilẹ̀ ti mo ti wá sílẹ̀ fún wọn, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Mutta minä nostin heille käteni sillä ajalla, että minun piti johdattaman heitä Egyptin maalta siihen maakuntaan, jonka minä heille edes katsonut olin, joka rieskaa ja hunajaa vuotaa, joka on paras kaikkein maakuntain seassa.
7 Mo sì wí fún wọn pé, “Kí olúkúlùkù nínú yín gbé ìríra ojú rẹ̀ kúrò, kí ẹ sì má bá sọ ara yín di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà Ejibiti, èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.”
Ja sanoin heille: heittäkään jokainen kauhistuksen pois silmäinsä edestä, ja älkäät saastuttako itsiänne Egyptin epäjumalista; sillä minä olen Herra teidän Jumalanne.
8 “‘Ṣùgbọ́n wọn ṣọ̀tẹ̀ sí mi wọn kò sì gbọ́rọ̀, wọn kò gbé àwòrán ìríra tí wọ́n dojúkọ kúrò níwájú wọn bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si kọ̀ àwọn òrìṣà Ejibiti sílẹ̀, torí náà mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí, èmi yóò sì jẹ́ kí ìbínú mi sẹ̀ lórí wọn ní ilẹ̀ Ejibiti.
Mutta he olivat minulle kovakorvaiset ja ei tahtoneet kuulla minua; ja ei yksikään heistä heittänyt kauhistustansa pois silmäinsä edestä, ja ei hyljänneet Egyptin epäjumalia. Niin minä ajattelin vuodattaa vihani heidän päällensä, ja antaa minun hirmuisuuteni käydä heidän ylitsensä Egyptin maassa.
9 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní jẹ́ kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí wọn ń gbé láàrín wọn, lójú àwọn ẹni tí mo ti fi ara hàn fún ara Israẹli nípa mímú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti.
Mutta en minä tehnyt sitä minun nimeni tähden, ettei sen pitänyt saastutetuksi tuleman pakanain edessä, joiden seassa he olivat, ja joille minä olin itseni ilmoittanut, että minä heidät tahdoin johdattaa ulos Egyptin maalta.
10 Nítorí náà, mo mú wọn jáde ní ilẹ̀ Ejibiti mo sì mú wọn wá sínú aginjù.
Ja kuin minä heidät Egyptin maalta olin johdattanut ulos, ja antanut heidän tulla korpeen:
11 Mo sì fún wọn ni òfin mi, mo sì fi àwọn òfin mi hàn wọ́n; nítorí pé ẹni tó bá ṣe wọ́n yóò yè nípa wọn.
Annoin minä heille minun säätyni, ja minun oikeuteni heille tiettäväksi tein: se ihminen joka ne tekee, hän elää niissä.
12 Bẹ́ẹ̀ ni mo fún wọn ní ọjọ́ ìsinmi gẹ́gẹ́ bí àmì láàrín àwọn àti èmi, kí wọn lè mọ̀ pé èmi ni Olúwa tó sọ wọn di mímọ́.
Minä annoin myös heille minun sabbatini merkiksi minun ja heidän vaiheellansa, että heidän piti tietämän, että minä olen Herra, joka heitä pyhitän.
13 “‘Síbẹ̀; ilé Israẹli ṣọ̀tẹ̀ sí mí nínú aginjù. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sì kọ àwọn òfin mi sílẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá pa á mọ́ yóò yè nínú rẹ̀. Wọn sì sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú gbígbóná mi sórí wọn, èmi yóò sì pa wọ́n run nínú aginjù.
Mutta Israelin huone oli minulle kovakorvainen korvessa, ja ei elänyt minun säätyini jälkeen, ja katsoi minun oikeuteni ylön, joissa se ihminen elää, joka ne tekee; ja he saastuttivat minun sabbatini sangen suuresti: niin minä ajattelin vuodattaa minun vihani heidän päällensä korvessa, ja peräti kadottaa heitä.
14 Ṣùgbọ́n nítorí orúkọ mi, mo ṣe ohun tí kò ní mú kí orúkọ mi bàjẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè tí mo kó wọn jáde.
Mutta en minä sitä tehnyt minun nimeni tähden, ettei sen pitänyt turmelluksi tuleman pakanain seassa, joista minä heidät olin johdattanut ulos heidän silmäinsä edessä.
15 Nítorí náà, mo tún gbọ́wọ́ mi sókè ní ìbúra fún wọn nínú aginjù pé, èmi kì yóò mú wọn dé ilẹ̀ tí mo fi fún wọn—ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin, ilẹ̀ tí ó lẹ́wà jùlọ láàrín àwọn ilẹ̀ yòókù.
Ja minä nostin käteni heitä vastaan korvessa, etten minä tahtonut heitä antaa tulla siihen maahan, jonka minä heille antanut olin, joka rieskaa ja hunajaa vuotaa, joka on paras kaikkein maakuntain seassa,
16 Nítorí pé, wọn kọ òfin mi sílẹ̀, wọn kò sì tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn sọ ọjọ́ ìsinmi mi dí aláìmọ́. Nítorí pé tọkàntọkàn ni wọn ń tẹ̀lé òrìṣà wọn.
Että he katsoivat minun oikeuteni ylön, ja ei eläneet minun säätyini jälkeen, ja turmelivat minun sabbatini; sillä heidän sydämensä vaelsi heidän epäjumalainsa jälkeen.
17 Síbẹ̀síbẹ̀ mo wò wọ́n pẹ̀lú àánú, ń kò sì pa wọ́n run tàbí kí òpin dé bá wọn nínú aginjù.
Mutta minun silmäni armahti heitä, etten minä heitä kadottanut, enkä peräti tyhjäksi tehnyt heitä korvessa.
18 Ṣùgbọ́n mo sọ fún àwọn ọmọ wọn nínú aginjù pé, “Ẹ má ṣe rìn ní ìlànà àwọn baba yín, ẹ má ṣe pa òfin wọn mọ́, ẹ má ṣe bá ara yín jẹ́ pẹ̀lú òrìṣà wọn.
Ja minä sanoin heidän lapsillensa korvessa: ei teidän pidä elämän teidän isäinne säätyin jälkeen, eikä pitämän heidän oikeuksiansa, eli saastuttaman itsiänne heidän epäjumaliinsa;
19 Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín, ẹ tẹ̀lé àṣẹ mi, kí ó sì pa òfin mi mọ́.
Sillä minä olen Herra teidän Jumalanne: minun säätyini jälkeen pitää teidän elämän, ja minun oikeuteni pitämän, ja niiden jälkeen tekemän.
20 Ẹ ya ọjọ́ ìsinmi mi sí mímọ́ kí ó lè jẹ́ àmì láàrín wa, ki ẹ lè mọ̀ pé èmi ní Olúwa Ọlọ́run yín.”
Ja minun sabbatini pitää teidän pyhittämän, että ne pitää oleman merkiksi minun ja teidän vaiheellanne, että teidän pitää tietämän, että minä Herra olen teidän Jumalanne.
21 “‘Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ náà ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Wọn kò tẹ̀lé àṣẹ mi, wọn kò sì pa òfin mi mọ́ bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ẹni tó bá tẹ̀lé àwọn òfin yìí, yóò yè nínú rẹ̀, wọ́n sì tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Nítorí náà, mo sọ pé èmi yóò tú ìbínú mi lórí wọn, Èmi yóò sì mú kí ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn ni aginjù.
Mutta lapset olivat minulle myös kovakorvaiset, ja ei eläneet minun säätyini jälkeen, eikä pitäneet minun oikeuksiani, tehdäksensä niiden jälkeen, joissa ihminen elää, joka ne pitää, ja he turmelivat minun sabbatini; niin minä ajattelin vuodattaa minun vihani heidän päällensä, ja antaa minun hirmuisuuteni käydä heidän ylitsensä korvessa.
22 Síbẹ̀síbẹ̀ mo dáwọ́ dúró, nítorí orúkọ mi, mo sì ṣe ohun tí kò ní ba orúkọ mi jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè ti mo kó wọn jáde lójú wọn.
Mutta minä käänsin käteni, ja en tehnyt sitä minun nimeni tähden, ettei sen pitänyt turmelluksi tuleman pakanain edessä, joista minä heitä olen johdattanut ulos heidän silmäinsä edessä.
23 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú ọwọ́ ti mo gbé sókè sí wọn, mo búra fún wọn nínú aginjù pé èmi yóò tú wọn ka sì àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì fọ́n wọn káàkiri ilẹ̀ gbogbo,
Minä nostin myös minun käteni heitä vastaan korvessa, hajoittaakseni heitä pakanain sekaan ja maakuntiin,
24 nítorí pé wọn kò pa òfin mi mọ́, wọn sì tún kọ àṣẹ mi sílẹ̀, wọn tún sọ ọjọ́ ìsinmi mi di aláìmọ́. Ojú wọn sì wà ní ara òrìṣà baba wọn.
Ettei he pitäneet minun oikeuksiani, ja katsoivat minun säätyni ylön, ja turmelivat minun sabbatini, ja katselivat isäinsä epäjumalia.
25 Èmi náà sì fi wọn fún ìlànà tí kò dára àti òfin tí wọn kò le e yè nípa rẹ̀;
Sentähden annoin minä heille säädyt, jotka ei hyvät olleet, ja oikeudet, joissa ei heille ollut elämää,
26 mo jẹ́ kí ó sọ wọn di aláìmọ́ nípa ẹ̀bùn nípa fífi àkọ́bí ọmọ wọn rú ẹbọ sísun, àkọ́bí wọn la iná kọjá, kí èmi sọ wọ́n di ahoro, kí wọn le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
Ja hylkäsin heidän uhrinsa koska he käyttivät tulessa kaikki esikoiset, että minun piti heitä hävittämän, ja että heidän piti tietämän, että minä olen Herra.
27 “Nítorí náà, Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilé Israẹli kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Èyí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí, nínú èyí tí baba yín ti sọ̀rọ̀-òdì sí mi, nípa kíkọ̀ mí sílẹ̀.
Sentähden puhu, sinä ihmisen poika, Israelin huoneelle, ja sano heille: näin sanoo Herra, Herra: teidän isänne ovat vielä enemmin minua pilkanneet, hyvällä ehdolla minua vastaan rikkoissansa.
28 Nítorí nígbà tí mo mú wọn dé ilẹ̀ náà, tí mo gbé ọwọ́ mi sókè láti fi í fún wọn, nígbà náà ni wọ́n rí olúkúlùkù òkè gíga, àti gbogbo igi bíbò, wọ́n sì rú ẹbọ wọn níbẹ̀, wọ́n sì gbé ìmúnibínú ọrẹ wọ́n kalẹ̀ níbẹ̀; níbẹ̀ pẹ̀lú ni wọ́n ṣe òórùn dídùn wọn, wọ́n sì ta ohun ọrẹ mímu sílẹ̀ níbẹ̀.
Sillä kuin minä olin antanut heidän tulla siihen maahan, jonka ylitse minä käteni nostanut olin, että minun piti sen antaman heille; kussa he joskus näkivät korkean vuoren taikka paksuoksaisen puun, siellä he uhrasivat uhrinsa ja kantoivat sinne uhrinsa vihan kehoitukseksi, ja suitsuttivat siellä makian hajunsa ja vuodattivat siellä juomauhrinsa.
29 Nígbà náà ni mo wí fún wọn pé, kí ní ibi gíga tí ẹ̀yin lọ yìí?’” (Orúkọ rẹ̀ ni a sì ń pè ní Bama di òní yìí.)
Mutta minä sanoin heille: mihinkä pitää siis oleman sen kukkulan, johonka te menette? Ja siitä kutsutaan se kukkulaksi aina tähän päivään asti.
30 “Nítorí náà sọ fún ilé Israẹli pé, ‘Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, ṣé o fẹ́ ba ara rẹ jẹ́ bi àwọn baba rẹ ṣe ṣe, tiwọn ń ṣe àgbèrè nípa títẹ̀lé àwọn àwòrán ìríra?
Sentähden sano Israelin huoneelle: näin sanoo Herra, Herra: te saastutatte itsenne teidän isäinne menoissa, ja teette huorin heidän kauhistustensa kanssa;
31 Nígbà tí ẹ̀yin bá san ọrẹ yìí, ìrúbọ ọmọkùnrin ọmọ yín, tí ẹ mú ọmọ yin la iná kọjá, ẹ̀yin ń tẹ̀síwájú láti ba ara yín jẹ́ pẹ̀lú àwọn òrìṣà yín títí di òní yìí, ẹ̀yin yóò ha jẹ wádìí lọ́dọ̀ mi, ìwọ ilé Israẹli? Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi ki yóò jẹ́ kí ẹ wádìí lọ́dọ̀ mi.
Ja saastutatte itsenne teidän epäjumalissanne, joille te uhraatte teidän lahjanne, ja poltatte teidän poikanne tulessa hamaan tähän päivään asti: ja minun pitäis antaman teille vastausta, sinä Israelin huone? Niin totta kuin minä elän, sanoo Herra, Herra: en tahdo minä vastausta antaa teille.
32 “‘Ẹ̀yin wí pé, “Àwa fẹ́ dàbí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù, bí àwọn ènìyàn ayé, tó ń bọ igi àti òkúta.” Ṣùgbọ́n ohun ti ẹ ni lọ́kàn kò ní ṣẹ rárá.
Ja se mikä tulee teidän mieleenne, ei siitä pidä mitään oleman: että te sanotte: me tahdomme tehdä niinkuin pakanat ja muut kansat maakunnissa, ja palvella kantoja ja kiviä.
33 Bí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò jẹ ọba lórí yín pẹ̀lú ọwọ́ agbára tí èmi yóò nà jáde pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná mi.
Niin totta kuin minä elän, sanoo Herra, Herra, minä tahdon hallita teitä väkevällä kädellä ja ojennetulla käsivarrella, ja vuodatetulla hirmuisuudella.
34 Èmi yóò si mú yín jáde kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì ṣà yín jọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín sí pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà tí èmi yóò nà jáde àti pẹ̀lú ìtújáde ìbínú gbígbóná ni.
Ja tahdon johdattaa teitä pois kansoista, ja koota teitä niistä maakunnista, joihinka te hajoitetut olette, väkevällä kädellä ja ojennetulla käsivarrella, ja vuodatetulla hirmuisuudella.
35 Èmi yóò si mú yín wá sí aginjù àwọn orílẹ̀-èdè, níbẹ̀ ni ojúkójú ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ lé e yín lórí.
Ja tahdon teidän antaa tulla kansain korpeen, ja olla siellä oikeudella teidän kanssanne, kasvoista niin kasvoihin.
36 Bí mo ṣe ṣe ìdájọ́ àwọn baba yín nínú aginjù nílẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní Olúwa Olódùmarè wí.
Niinkuin minä teidän isäinne kanssa Egyptin maan korvessa oikeudella olin: juuri sillä tavalla tahdon minä olla oikeudella teidän kanssanne, sanoo Herra, Herra.
37 Èmi yóò kíyèsi i yín bí mo ti mú un yín kọjá lábẹ́ ọ̀pá, èmi yóò sì mú yín wá sí abẹ́ ìdè májẹ̀mú.
Minä tahdon antaa teidän tulla vitsan alle, ja johdattaa teitä liiton siteellä.
38 Èmi yóò si ṣa àwọn ọlọ̀tẹ̀ kúrò láàrín yín, àti àwọn o lù re òfin kọjá, èmi yóò mu wọn jáde kúrò ni ilẹ̀ tiwọn gbé ṣe àtìpó, wọn ki yóò si wọ ilẹ̀ Israẹli. Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, èmi ní Olúwa.
Ja tahdon perata pois vastahakoiset ja minusta luopuvaiset teidän seastanne. Ja tosin minä tahdon johdattaa heitä ulos asumamaastansa, ja en anna heitä tulla Israelin maalle, että teidän tietämän pitää, että minä olen Herra.
39 “‘Ní tí ẹ̀yin, ilé Israẹli, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kí olúkúlùkù yín lọ máa sìn òrìṣà rẹ̀, ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, ẹ̀yin yóò gbọ́ tèmi, ẹ̀yin kò sí ní i bá orúkọ mímọ́ mi jẹ́ pẹ̀lú ọrẹ àti àwọn òrìṣà yín mọ́.
Sentähden te, Israelin huone, näin sanoo Herra, Herra: ettette kuitenkaan tahdo kuulla minua, niin tehkäät niinkuin teille kelpaa, ja jokainen teitä palvelkaan epäjumalaansa tästäkin lähin; mutta minun pyhä nimeni antakaat tästäedes pilkkaamatta olla teidän uhreissanne ja epäjumalissanne.
40 Nítorí lórí òkè mímọ́ mi, lórí òkè gíga Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí, níbẹ̀ ni ilẹ̀ náà ní gbogbo ilé Israẹli yóò sìn mí; èmi yóò sì tẹ́wọ́ gba wọ́n níbẹ̀. Níbẹ̀ èmi yóò béèrè ọrẹ àti ẹ̀bùn nínú àkọ́so yín pẹ̀lú gbogbo ẹbọ mímọ́ yín.
Sillä näin sanoo Herra, Herra: minun pyhällä vuorellani, korkialla Israelin vuorella, siellä pitää koko Israelin huone ja kaikki, jotka maakunnassa ovat, palveleman minua; siellä pitää heidän minulle oleman otolliset, ja siellä minä tahdon anoa teiltä ylennysuhria ja teidän uhrinne esikoista kaiken sen kanssa, jolla te minua pyhitätte.
41 Èmi yóò tẹ́wọ́ gbà yín gẹ́gẹ́ bí tùràrí olóòórùn dídùn nígbà tí mo ba mú yín jáde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí a fọ́n yín ká sí, èmi yóò sì fi ìwà mímọ́ mi hàn láàrín yín lójú àwọn orílẹ̀-èdè.
Te olette minulle otolliset makialla savulla, kuin minä annan teidän tulla pois kansoista, ja kokoon teitä siitä maasta, kuhunka te hajoitetut olette, ja pyhitän itseni teissä, pakanain edessä.
42 Nígbà náà ni ẹ o mọ̀ pé èmi ní Olúwa, nígbà tí mo bá mú yín wa sí ilẹ̀ Israẹli; sí ilẹ̀ tí mo gbọ́wọ́ mí sókè nínú ẹ̀jẹ́ láti fún àwọn baba yín.
Ja teidän pitää ymmärtämän, että minä olen Herra, koska minä olen antanut teidän tulla Israelin maalle, siihen maahan, josta minä nostin käteni, että minun piti teidän isillenne sen antaman.
43 Níbẹ̀ ni ẹ ó wa rántí ìwà àti gbogbo ìṣesí yín, èyí tí ẹ̀yin fi sọ ara yín di aláìmọ́, ẹ̀yin yóò sì kórìíra ara yín fún gbogbo ibi tí ẹ̀yin ti ṣe.
Siellä pitää teidän muistaman teidän menonne ja kaikki teidän tekonne, joilla te itsenne saastuttaneet olette, ja teidän pitää suuttman itseenne kaiken teidän pahuutenne tähden, jonka te tehneet olette.
44 Nígbà náà ní ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá hùwà sí yín nítorí orúkọ mi ni, tí ń kò hùwà sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ibi àti ìwà ìríra yín. Ẹ̀yin ilé Israẹli, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ja teidän pitää ymmärtämän, että minä olen Herra, koska minä teen teidän kanssanne minun nimeni tähden, ja ei teidän pahan menonne ja vahingollisen työnne jälkeen, sinä Israelin huone, sanoo Herra, Herra.
45 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Ja Herran sana tapahtui minulle ja sanoi:
46 “Ọmọ ènìyàn, dojúkọ ìhà gúúsù; wàásù lòdì sí gúúsù kí ìwọ sì sọtẹ́lẹ̀ sí igbó ilẹ̀ gúúsù.
Sinä, ihmisen poika, aseta kasvos oikian käden puoleen, ja pisaroitse lounaan puoleen, ja ennusta metsää vastaan, kedolla lounaan päin,
47 Sọ fún igbó ìhà gúúsù pé: ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Èyí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Kíyèsi í, èmi yóò dá iná kan nínú rẹ̀, yóò sì jó olúkúlùkù igi tútù nínú rẹ̀, àti olúkúlùkù igi gbígbẹ. Jíjò ọwọ́ iná náà ní kí yóò ṣé é pa, àti gbogbo ojú láti gúúsù dé àríwá ni a ó sun nínú rẹ̀.
Ja sano lounaan puoliselle metsälle: kuule Herran sanaa: näin sanoo Herra, Herra: katso, minä tahdon sinussa tulen sytyttää, sen pitää sekä tuoreet että kuivat puut polttaman, ettei hänen ankaraa liekkiänsä taideta sammuttaa, vaan kaikki pitää poltettaman, mitä lounaasta pohjaan käsin on.
48 Gbogbo ènìyàn yóò sì mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó dá a, a kì yóò sì le è pa á.’”
Ja kaikki liha pitää näkemän, että minä Herra sen sytyttänyt olen; ja ei pidä sitä sammutettaman.
49 Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Wọn ń wí fún mi pé, ‘Kì í wa ṣe pé òwe lo ń pa bí?’”
Ja minä sanoin: ah! Herra, Herra, he sanovat minusta: tämä puhuu paljaita tapauksia.

< Ezekiel 20 >