< Ezekiel 2 >

1 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
És monda nékem: Embernek fia! állj lábaidra, és szólok veled.
2 Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
És lélek jöve én belém, a mint szóla, és állata engem lábaimra, és hallám azt, a ki szól vala nékem.
3 Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
És mondá nékem: Embernek fia! küldelek én téged Izráel fiaihoz, a pártos nemzetségekhez, a kik pártot ütöttek ellenem; ők és atyáik vétkeztek ellenem mind e mai napig.
4 Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
A kemény orczájú fiakhoz és makacs szívűekhez küldelek téged, és ezt mondjad nékik: Így szól az Úr Isten!
5 Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
Ők pedig vagy hallják, vagy nem hallják, mivelhogy pártos ház, hadd tudják meg, hogy próféta volt köztük.
6 Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
Te pedig, embernek fia, ne félj tőlök, és az ő beszédöktől se félj; ha bogácsok és tövisek vannak is veled, és ha skorpiókkal lakol is együtt; beszédöktől ne félj, orczájoktól ne rettegj, mert ők pártos ház.
7 Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
És szóljad az én beszédimet nékik, vagy hallják, vagy nem, mert pártos ház.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
Te pedig, embernek fia, halld meg a mit én néked szólok. Ne légy pártos mint ez a pártos ház, nyisd föl szádat, és egyed, a mit én adok néked.
9 Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
És látám, és ímé egy kéz nyúlt felém, és ímé benne egy könyv türete vala.
10 ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.
És kiterjeszté azt előttem, és ímé be vala írva elől és hátul, és írva valának reá gyászénekek és nyögések és jajszók.

< Ezekiel 2 >