< Ezekiel 2 >

1 Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, dìde dúró lórí ẹsẹ̀ rẹ. Èmi yóò bá ọ sọ̀rọ̀.”
И ми рече: Сине човешки, изправи се на нозете си, и ще ти говоря.
2 Bí ó ṣe ń sọ̀rọ̀, ẹ̀mí sì wọ inú mi ó mú mi dúró lórí ẹsẹ̀ mi, mo sì ń gbọ́ tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀.
И като ми говори, Духът влезе в мене и ме постави на нозете ми; и чух онзи, който ми говореше.
3 Ó sọ pé, “Ọmọ ènìyàn, mo ń rán ọ sí àwọn ọmọ Israẹli, sí ọlọ̀tẹ̀ orílẹ̀-èdè tí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi; àwọn àti baba ńlá wọn ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi títí di òní olónìí.
И рече ми: Сине човешки, аз те изпращам при израилтяните, при бунтовни люде, които въстанаха против Мене; те и бащите им са престъпвали Моите думи дори до тоя днешен ден.
4 Àwọn ènìyàn tí mo ń rán ọ sí jẹ́ aláìgbọ́ràn àti ọlọ́kàn líle. Sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí.’
Тия чада, при които те изпращам, са безочливи и коравосърдечни; а ти да им думаш: Така казва Господ Иеова.
5 Bí wọn fetísílẹ̀ tàbí wọn kò fetísílẹ̀ nítorí pé wọ́n ọlọ̀tẹ̀ ilé ni wọ́n—wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan wà láàrín wọn.
послушали или непослушали, (защото е бунтовен дом), пак те ще познаят, че е имало пророк всред тях.
6 Àti ìwọ, ọmọ ènìyàn, má ṣe bẹ̀rù wọn tàbí ọ̀rọ̀ ẹnu wọn. Má ṣe bẹ̀rù, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òṣùṣú àti ẹ̀gún yí ọ ká, tí o sì ń gbé àárín àwọn àkéekèe. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí wọ́n ń sọ tàbí bẹ̀rù wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọlọ̀tẹ̀ ìdílé ni wọ́n.
И ти, сине човешки, да се не плашиш от тях, и от думите им да се не убоиш, ако и да има тръни и бодили около тебе, и да живееш между скорпии; да се не убоиш от думите им, нито да се ужасяваш от погледите им, макар че са бунтовен дом.
7 Ìwọ gbọdọ̀ sọ ọ̀rọ̀ mi fún wọn, bí wọ́n gbọ́ bí wọn kọ̀ láti gbọ́ torí pé ọlọ̀tẹ̀ ni wọ́n.
И да им говориш думите Ми, или послушали или непослушали; защото са твърде бунтовни.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ, ọmọ ènìyàn, gbọ́ ohun tí mo ń sọ fún ọ. Má ṣe ṣọ̀tẹ̀ bí i ti ìdílé ọlọ́tẹ̀; la ẹnu rẹ kí o sì jẹ ohun tí mo fún ọ.”
Ти обаче, сине човешки, слушай това, което ти говоря; не ставай и ти бунтовник като тоя бунтовен дом; отвори устата си и изяж това, което ти давам.
9 Mo sì wò, mo sì rí ọwọ́ kan tí a nà sí mi. Ìwé kíká sì wà níbẹ̀,
И като погледнах, ето ръка простряна към мене, и ето в нея свитък книга.
10 ó sì tú ìwé náà fún mi. Ní ojú àti ẹ̀yìn ìwé náà ni a kọ ìpohùnréré ẹkún, ọ̀fọ̀ àti ègún sí.
И той го разви пред мене. Писаното бе отвътре и отвън, в което бяха написани плачове, ридание и горко.

< Ezekiel 2 >