< Ezekiel 19 >
1 “Kọ orin ọ̀fọ̀ nítorí àwọn ọmọ-aládé Israẹli
Moreover, take thou up a lamentation for the princes of Israel,
2 wí pé: “‘Èwo nínú abo kìnnìún ni ìyá rẹ̀ ní àárín àwọn kìnnìún yòókù? Ó sùn ní àárín àwọn ọ̀dọ́ kìnnìún ó sì ń tọ́jú àwọn ọmọ rẹ̀.
and say: How was thy mother a lioness; among lions she couched, in the midst of the young lions she reared her whelps!
3 Ó sì tọ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọ rẹ̀ dàgbà, ó sì di kìnnìún tó ní agbára, ó kọ́ ọ láti ṣọdẹ, ó sì ń pa àwọn ènìyàn jẹ.
And she brought up one of her whelps, he became a young lion; and he learned to catch the prey, he devoured men.
4 Àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì fi ẹ̀wọ̀n mú un nínú iho wọn. Wọn fi ẹ̀wọ̀n mu nu lọ sí ilẹ̀ Ejibiti.
Then the nations assembled against him, he was taken in their pit; and they brought him with hooks unto the land of Egypt.
5 “‘Nígbà tí abo kìnnìún yìí rí pé ìrètí rẹ̀ sì jásí asán, ó mú ọmọ rẹ̀ mìíràn ó sì tún tọ́ ọ dàgbà di kìnnìún tó ní agbára.
Now when she saw that she was disappointed, and her hope was lost, then she took another of her whelps, and made him a young lion.
6 Ó sì ń rìn káàkiri láàrín àwọn kìnnìún nítorí pé ó ti lágbára, o kọ ọdẹ ṣíṣe, ó sì pa àwọn ènìyàn.
And he went up and down among the lions, he became a young lion; and he learned to catch the prey, he devoured men.
7 Ó sì wó odi wọn palẹ̀ ó sì sọ àwọn ìlú wọn di ahoro. Ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé ibẹ̀ sì wà ní ìpayà nítorí bíbú ramúramù rẹ̀.
And he knew their castles, and laid waste their cities; and the land was desolate, and the fulness thereof, because of the noise of his roaring.
8 Nígbà náà ni àwọn orílẹ̀-èdè dìde sí i, àwọn tó yìí ká láti ìgbèríko wá. Wọn dẹ àwọ̀n wọn fún un, wọn sì mú nínú ihò wọn.
Then the nations cried out against him on every side from the provinces; and they spread their net over him, he was taken in their pit.
9 Wọn fi ìwọ̀ gbé e sínú àgò, wọn mú un lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Babeli, wọn fi sínú ìhámọ́, a kò sì gbọ́ bíbú rẹ̀ mọ́ lórí òkè Israẹli.
And they put him in a cage with hooks, and brought him to the king of Babylon; that they might bring him into strongholds, so that his voice should no more be heard upon the mountains of Israel.
10 “‘Ìyá rẹ dàbí àjàrà nínú ọgbà àjàrà rẹ̀; tí á gbìn sí etí odò ó, kún fún èso, ó sì kún fún ẹ̀ka nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
Thy mother was like a vine, in thy likeness, planted by the waters; she was fruitful and full of branches by reason of many waters.
11 Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ lágbára tó láti fi ṣe ọ̀pá àṣẹ ìjòyè, ó ga sókè láàrín ewé rẹ̀, gíga rẹ̀ hàn jáde láàrín ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ka rẹ̀.
And she had strong rods to be sceptres for them that bore rule; and her stature was exalted among the thick branches, and she was seen in her height with the multitude of her tendrils.
12 Ṣùgbọ́n ó fà á tu ní ìrunú, á sì wọ́ ọ lulẹ̀, afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn sì gbé èso rẹ̀, ọ̀pá líle rẹ̀ ti ṣẹ́, ó sì rọ iná sì jó wọn run.
But she was plucked up in fury, she was cast down to the ground, and the east wind dried up her fruit; her strong rods were broken off and withered, the fire consumed her.
13 Báyìí, a tún ún gbìn sínú aṣálẹ̀ ni ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tó ń pòǹgbẹ omi.
And now she is planted in the wilderness, in a dry and thirsty ground.
14 Iná sì jáde láti ọ̀kan lára ẹ̀ka rẹ̀ ó sì pa ẹ̀ka àti èso rẹ̀ run, dé bi pé kò sí ẹ̀ka tó lágbára lórí rẹ̀ mọ́; èyí to ṣe fi ṣe ọ̀pá fún olórí mọ́.’ Èyí ni orin ọ̀fọ̀ a o sì máa lo bí orin ọ̀fọ̀.”
And fire is gone out of the rod of her branches, it hath devoured her fruit, so that there is in her no strong rod to be a sceptre to rule.' This is a lamentation, and it was for a lamentation.