< Ezekiel 18 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
Vad orsak haven I till att bruka detta ordspråk i Israels land: »Fäderna äta sura druvor, och barnens tänder bliva ömma därav»?
3 “Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
Så sant jag lever, säger Herren, HERREN, I skolen ingen orsak mer hava att bruka detta ordspråk i Israel.
4 Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
Se, alla själar äro mina, faderns själ såväl som sonens är min; den som syndar, han skall dö.
5 “Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
Om nu en man är rättfärdig och övar rätt och rättfärdighet,
6 tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
om han icke håller offermåltid på bergen, ej heller upplyfter sina ögon till Israels hus' eländiga avgudar, om han icke skändar sin nästas hustru, ej heller kommer vid en kvinna under hennes orenhets tid,
7 Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
om han icke förtrycker någon, utan giver tillbaka den pant han har fått för skuld, om han icke tager rov, utan giver sitt bröd åt den hungrige och kläder den nakne,
8 Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
om han icke ockrar eller tager ränta, om han håller sin hand tillbaka från vad orätt är och fäller rätta domar människor emellan --
9 Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
ja, om han så vandrar efter mina stadgar och håller mina rätter, i det att han gör vad redligt är, då är han rättfärdig och skall förvisso få leva, säger Herren, HERREN.
10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
Men om han så föder en son som bliver en våldsverkare, vilken utgjuter blod eller gör allenast något av allt detta
11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
som han själv icke gjorde, en som håller offermåltid på bergen, skändar sin nästas hustru,
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
förtrycker den arme och fattige, tager rov, icke giver pant tillbaka, upplyfter sina ögon till de eländiga avgudarna, bedriver vad styggeligt är,
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
ockrar och tager ränta -- skulle då denne få leva? Nej, han skall icke få leva, utan eftersom han bedriver sådana styggelser, skall han straffas med döden; hans blod skall komma över honom.
14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
Och om sedan denne föder en son, vilken ser alla de synder som hans fader begår, och vid åsynen av dem själv tager sig till vara för att göra sådant,
15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
en som icke håller offermåltid på bergen, icke upplyfter sina ögon till Israels hus' eländiga avgudar, icke skändar sin nästas hustru,
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
en som icke förtrycker någon, icke fordrar pant eller tager rov, utan giver sitt bröd åt den hungrige och kläder den nakne,
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
en som icke förgriper sig på den arme, ej heller ockrar eller tager ränta, utan gör efter mina rätter och vandrar efter mina stadgar, då skall denne icke dö genom sin faders missgärning, utan skall förvisso få leva.
18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
Hans fader däremot, som begick våldsgärningar och rövade från sin broder och gjorde bland sina fränder det som icke var gott, se, han måste dö genom sin missgärning.
19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
Huru kunnen I nu fråga: »Varför skulle icke sonen bära på sin faders missgärning?» Jo, sonen övade ju rätt och rättfärdighet och höll alla mina stadgar och gjorde efter dem; därför skall han förvisso få leva.
20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
Den som syndar, han skall dö; en son skall icke bära på sin faders missgärning, och en fader skall icke bära på sin sons missgärning. Över den rättfärdige skall hans rättfärdighet komma, och över den ogudaktige skall hans ogudaktighet komma.
21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
Men om den ogudaktige omvänder sig från alla de synder som han har begått, och håller alla mina stadgar och övar rätt och rättfärdighet, då skall han förvisso leva och icke dö.
22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
Ingen av de överträdelser han har begått skall du tillräknas honom; genom den rättfärdighet han har övat skall han få leva.
23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
Menar du att jag har lust till den ogudaktiges död, säger Herren, HERREN, och icke fastmer därtill att han vänder om från sin väg och får leva?
24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
Men om den rättfärdige vänder om från sin rättfärdighet och gör vad orätt är, alla sådana styggelser som den ogudaktige gör -- skulle han då få leva, om han gör så? Nej, intet av all den rättfärdighet han har övat skall då ihågkommas, utan genom den otrohet han har begått och den synd han har övat skall han dö.
25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
Men nu sägen I: »Herrens väg är icke alltid densamma.» Hören då, I av Israels hus: Skulle verkligen min väg icke alltid vara densamma? Är det icke fastmer eder väg som icke alltid är densamma?
26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
Om den rättfärdige vänder om från sin rättfärdighet och gör vad orätt är, så måste han dö till straff därför; genom det orätta som han gör måste han dö.
27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
Men om den ogudaktige vänder om från den ogudaktighet som han har övat, och i stället övar rätt och rättfärdighet, då får han behålla sin själ vid liv.
28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
Ja, eftersom han kom till insikt och vände om från alla de överträdelser han hade begått, skall han förvisso leva och icke dö.
29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
Och ändå säga de av Israels hus: »Herrens väg är icke alltid densamma»! Skulle verkligen mina vägar icke alltid vara desamma, I av Israels hus? Är det icke fastmer eder väg som icke alltid är densamma?
30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
Alltså: jag skall döma var och en av eder efter hans vägar, I av Israels hus, säger Herren, HERREN. Vänden om, ja, vänden eder bort ifrån alla edra överträdelser, för att eder missgärning icke må bliva eder till en stötesten.
31 Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
Kasten bort ifrån eder alla de överträdelser som I haven begått, och skaffen eder ett nytt hjärta och en ny ande; ty icke viljen I väl dö, I av Israels hus?
32 Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!
Jag har ju ingen lust till någons död, säger Herren HERREN. Omvänden eder därför, så fån I leva.

< Ezekiel 18 >