< Ezekiel 18 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Cuvântul DOMNULUI a venit la mine din nou, spunând:
2 “Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
Ce înseamnă [aceasta], că voi folosiți acest proverb referitor la țara lui Israel, spunând: Părinții au mâncat aguridă și dinții copiilor s-au strepezit?
3 “Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
[Precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU, că nu veți mai folosi acest proverb în Israel.
4 Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
Iată, toate sufletele sunt ale mele; ca sufletul tatălui, tot astfel sufletul fiului este al meu; sufletul care păcătuiește, acela va muri.
5 “Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
Dar dacă un om este drept și face ceea ce este legiuit și drept,
6 tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
[Și] nu a mâncat pe munți, nici nu și-a ridicat ochii spre idolii casei lui Israel, nici nu a pângărit-o pe soția aproapelui său, nici nu s-a apropiat de o femeie în timpul menstruației [ei],
7 Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
Și nu a oprimat pe nimeni, [ci] a dat înapoi datornicului garanția lui, nu a jefuit pe nimeni prin violență, a dat pâinea lui celui flămând și a acoperit pe cel gol cu o haină;
8 Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
Cel [care] nu a dat cu camătă, nici nu a luat vreo dobândă, [care] și-a retras mâna de la nelegiuire, a făcut judecată dreaptă între om și om,
9 Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
A umblat în statutele mele și a păzit judecățile mele, pentru a lucra după adevăr; el [este] drept; el va trăi negreșit, spune Domnul DUMNEZEU.
10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
Dacă el naște un fiu [care este] tâlhar, un vărsător de sânge și [care] face [cuiva] unul din aceste [lucruri],
11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
Și care nu împlinește niciuna din acele [datorii], ci a mâncat pe munți și a pângărit-o pe soția aproapelui său,
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
A oprimat pe sărac și pe nevoiaș, a jefuit prin violență, nu a dat înapoi garanția și și-a ridicat ochii spre idoli, a făcut urâciune,
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
A dat cu camătă și a luat dobândă, să trăiască [unul ca] acesta? Nu va trăi; a făcut toate aceste urâciuni; va muri negreșit, sângele lui va fi asupra lui.
14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
Acum, iată, [dacă] el naște un fiu care vede toate păcatele pe care le-a făcut tatăl lui și ia seama și nu face unele ca acestea,
15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
Nu a mâncat pe munți, nici nu și-a ridicat ochii spre idolii casei lui Israel, nu a pângărit soția aproapelui său,
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
Nici nu a oprimat pe cineva, nu a păstrat garanția, nici nu a jefuit prin violență, [ci] a dat pâinea lui celui flămând și a acoperit pe cel gol cu o haină,
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
[Ș]i-a tras mâna de la cel sărac, nu a primit camătă nici dobândă, a împlinit judecățile mele, a umblat în statutele mele; el nu va muri pentru nelegiuirea tatălui său, va trăi negreșit.
18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
[Cât despre] tatăl său, pentru că a oprimat cu cruzime, a jefuit pe fratele său prin violență și a făcut [ceea] ce nu [este] bine în mijlocul poporului său, iată, el va muri în nelegiuirea lui.
19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
Totuși voi spuneți: De ce? Nu poartă fiul nelegiuirea tatălui? Când fiul a făcut ceea ce este legiuit și drept [și] a păzit toate statutele mele și le-a împlinit, el va trăi negreșit.
20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
Sufletul care păcătuiește, acela va muri. Fiul nu va purta nelegiuirea tatălui, nici tatăl nu va purta nelegiuirea fiului: dreptatea celui drept va fi asupra lui însuși și stricăciunea celui stricat va fi asupra lui însuși.
21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
Dar dacă cel stricat se va întoarce de la toate păcatele lui, pe care le-a făcut, și va păzi toate statutele mele și va face ceea ce este legiuit și drept, el va trăi negreșit, nu va muri.
22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
Toate fărădelegile lui, pe care le-a făcut, nu îi vor fi menționate; el va trăi în dreptatea lui, pe care a făcut-o.
23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
Găsesc eu vreo plăcere în moartea celui stricat? spune Domnul DUMNEZEU; [și] nu în întoarcerea lui de la căile lui, pentru a trăi?
24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
Dar când cel drept se întoarce de la dreptatea lui și face nelegiuire [și] face conform cu toate urâciunile pe care [omul] stricat le face, va trăi el? Toată dreptatea lui, pe care a făcut-o, nu va fi menționată; în fărădelegea lui pe care a încălcat legea și în păcatul lui pe care l-a păcătuit, în ele va muri.
25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
Totuși voi spuneți: Calea Domnului nu este nepărtinitoare. Ascultă acum, casă a lui Israel: Nu este calea mea nepărtinitoare? Nu sunt căile voastre părtinitoare?
26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
Când unul drept se întoarce de la dreptatea lui și face nelegiuire și moare în ele; pentru nelegiuirea pe care a făcut-o va muri el.
27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
Din nou, când cel stricat se întoarce de la stricăciunea lui pe care a făcut-o și face ceea ce este legiuit și drept, el își va păstra sufletul în viață.
28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
Pentru că el ia aminte și se întoarce de la toate fărădelegile lui pe care le-a făcut, va trăi negreșit, nu va muri.
29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
Totuși casa lui Israel spune: Calea Domnului nu este nepărtinitoare. Casă a lui Israel, nu sunt căile mele nepărtinitoare? Nu sunt căile voastre părtinitoare?
30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
De aceea, casă a lui Israel, eu vă voi judeca, pe fiecare conform căilor lui, spune Domnul DUMNEZEU. Pocăiți-vă și întoarceți-vă de la toate fărădelegile voastre; astfel nelegiuirea nu va fi ruina voastră.
31 Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
Lepădați de la voi toate fărădelegile voastre, prin care ați încălcat [legea; ] și faceți-vă o inimă nouă și un duh nou, căci de ce să muriți, casă a lui Israel?
32 Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!
Fiindcă eu nu găsesc vreo plăcere în moartea celui care moare, spune Domnul DUMNEZEU; pentru aceea, întoarceți-vă și trăiți.

< Ezekiel 18 >