< Ezekiel 18 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩũrio atĩrĩ:
2 “Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
“Inyuĩ andũ aya, mũkoragwo mũkiuga atĩa rĩrĩa mũkwaria thimo ĩno igũrũ rĩa bũrũri wa Isiraeli: “‘Maithe ma ciana marĩĩaga thabibũ ngagatu, namo magego ma ciana makaigua thithi’?
3 “Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
“Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Ti-itherũ o ta ũrĩa niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, mũtigacooka kũgweta thimo ĩno thĩinĩ wa Isiraeli.
4 Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
Nĩgũkorwo roho o wothe ũrĩ muoyo nĩ wakwa; roho wa ithe nĩ wakwa o na wa mũriũ no wakwa. Roho ũrĩa wĩhagia nĩguo ũgaakua.
5 “Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
“Mũndũ aahota gũkorwo nĩ mũthingu, na ekaga maũndũ ma kĩhooto na marũngĩrĩru.
6 tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
We ndarĩĩaga irio iria irutagĩrwo mahooero-inĩ marĩa marĩ irĩma igũrũ, kana agatiirĩra maitho mĩhianano ya andũ a nyũmba ya Isiraeli. We ndathaahagia mũtumia wa mũndũ ũrĩa ũngĩ, kana agakoma na mũndũ-wa-nja rĩrĩa arĩ na ihinda rĩa mweri.
7 Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
Ndahinyagĩrĩria mũndũ o na ũrĩkũ, no nĩacookagĩria mũndũ ũrĩa marĩ thiirĩ nake kĩrĩa ooete kĩrĩ gĩa kũrũgamĩrĩra thiirĩ. We ndatunyanaga indo, no arĩa ahũtu nĩamaheaga irio ciake, na arĩa marĩ njaga akamahe nguo.
8 Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
Ningĩ ndakombanagĩra nĩguo etie uumithio ũtarĩ wa kĩhooto, kana agetia uumithio mũkĩru. We nĩagiragia guoko gwake gũtigeeke ũũru, na nĩatuithanagia ciira na kĩhooto gatagatĩ ka mũndũ na ũrĩa ũngĩ.
9 Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
Mũndũ ũcio nĩarũmagĩrĩra watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo, na akahingia watho wakwa na wĩhokeku. Mũndũ ũcio nĩ mũthingu; ti-itherũ nĩagatũũra muoyo, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
“Mũndũ ũcio angĩkorwo arĩ na mwanake mũtunyani, mũitithia wa thakame kana wĩkaga ũndũ o na ũmwe wa maũndũ macio mangĩ mooru
11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
(o na harĩa ithe ateekire ũndũ o na ũmwe wa mo): “We nĩarĩĩaga irio iria irutĩirwo mahooero-inĩ marĩa marĩ irĩma-igũrũ. Nĩathũkagia mũtumia wa mũndũ ũrĩa ũngĩ.
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
Nĩahinyagĩrĩria mũthĩĩni na mũbatari. Nĩatunyanaga indo. Ndacookagia kĩrĩa oete gĩa kũrũgamĩrĩra thiirĩ. Nĩatiiragĩra mĩhianano maitho. Nĩekaga maũndũ marĩa marĩ magigi.
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
We nĩakombanagĩra nĩguo etie uumithio ũtarĩ wa kĩhooto, na agetia uumithio mũkĩru. Mũndũ ta ũcio-rĩ, nĩagatũũra muoyo? Ndangĩtũũra muoyo! Nĩ ũndũ nĩekĩte maũndũ macio mothe marĩ magigi-rĩ, ti-itherũ no nginya akooragwo na thakame yake ĩmũcookerere we mwene.
14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
“No rĩrĩ, mũriũ ũcio angĩkorwo arĩ na mwana ũrĩa wonaga mehia macio mothe ithe ekaga, na o na gũtuĩka nĩamoonaga, we ndekaga maũndũ macio mooru:
15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
“We ndarĩĩaga irio iria irutĩirwo mahooero-inĩ marĩa marĩ irĩma igũrũ, kana agatiirĩra maitho mĩhianano ya andũ a nyũmba ya Isiraeli. Ndathaahagia mũtumia wa mũndũ ũrĩa ũngĩ.
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
Ndahinyagĩrĩria mũndũ o na ũrĩkũ, na ndeetagia kĩndũ gĩa kũrũgamĩrĩra thiirĩ. Ndatunyanaga indo, no irio ciake aciheaga arĩa ahũtu, na akahe arĩa marĩ njaga nguo.
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
Nĩarigagĩrĩria guoko gwake gũtikehie, na ndakombanagĩra nĩguo etie uumithio ũtarĩ wa kĩhooto, kana etie uumithio mũkĩru. Nĩahingagia watho wakwa, na akarũmĩrĩra watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo. Ũcio-rĩ, ndagakua nĩ ũndũ wa mehia ma ithe; ti-itherũ nĩagatũũra muoyo.
18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
No rĩrĩ, ithe nĩagaakua nĩ ũndũ wa mehia make mwene, tondũ we nĩekire maũndũ ma ũrĩa-ngʼũũrũ, na agĩtunya mũrũ wa ithe indo, na agĩĩka maũndũ marĩa mooru gatagatĩ-inĩ ka andũ ao.
19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
“No inyuĩ mũũragia atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ gĩkũgiria mũriũ agae mahĩtia ma ithe?’ Kuona atĩ mũriũ ũcio nĩekĩte maũndũ marĩa marĩ kĩhooto na magĩrĩru, na akamenyerera watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo, na akaũhingia-rĩ, ti-itherũ nĩegũtũũra muoyo.
20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
Roho ũrĩa wĩhagia nĩguo ũgaakua. Mwana ndakagaya waganu wa ithe, kana ithe agae waganu wa mwana. Ũthingu wa mũndũ ũrĩa mũthingu nowe mwene ũgaacookererwo nĩguo, naguo waganu wa mũndũ ũrĩa mwaganu nowe ũgaacookererwo nĩguo.
21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
“No rĩrĩ, mũndũ mwaganu angĩgarũrũka atigane na mehia mothe marĩa ekĩte, na arũmie watho wakwa wa kũrũmĩrĩrwo, na ekage maũndũ ma kĩhooto na marĩa magĩrĩire, ti-itherũ nĩegũtũũra muoyo; we ndagakua.
22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
Gũtirĩ ihĩtia o na rĩmwe rĩa marĩa aaneka rĩgaacooka kũririkanwo. Tondũ wa maũndũ ma ũthingu marĩa ekĩte-rĩ, nĩegũtũũra muoyo.
23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
Mwathani Jehova ekũũria atĩrĩ: Anga niĩ nĩngenagio nĩ gĩkuũ kĩa andũ arĩa aaganu? Githĩ ti kwenda ingĩenda magarũrũke matigane na mĩthiĩre ĩyo yao nĩguo matũũre muoyo?
24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
“No angĩkorwo mũndũ mũthingu no agarũrũke atigane na ũthingu wake, na ehie na eke maũndũ marĩ magigi ta marĩa mekagwo nĩ mũndũ mwaganu-rĩ, anga nĩagagĩtũũra muoyo? Hatirĩ ũndũ o na ũmwe wa maũndũ ma ũthingu marĩa aaneka ũkaaririkanwo. Tondũ wa mahĩtia ma kwaga kwĩhokeka na tondũ wa mehia marĩa ekĩte-rĩ, no agaakua.
25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
“No inyuĩ muugaga atĩrĩ, ‘Njĩra ya Mwathani ti ya kĩhooto.’ Ta thikĩrĩriai inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli: Njĩra yakwa-rĩ, ti ya kĩhooto? Atĩrĩrĩ, githĩ njĩra cianyu ticio itarĩ cia kĩhooto?
26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
Mũndũ mũthingu angĩgarũrũka atigane na ũthingu wake ehie, agaakua nĩ ũndũ wa mehia make; agaakua nĩ ũndũ wa mehia macio ekĩte.
27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
No mũndũ mwaganu angĩgarũrũka atigane na waganu ũrĩa ekĩte, na eke maũndũ ma kĩhooto na marĩa magĩrĩire-rĩ, we nĩakahonokia muoyo wake.
28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
Nĩ ũndũ nĩeciiragia ũhoro wa mahĩtia make mothe marĩa aneeka, na akagarũrũka agatigana namo-rĩ, ti-itherũ nĩagatũũra muoyo; we ndagakua.
29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
No andũ a nyũmba ĩno ya Isiraeli mekuuga atĩrĩ, ‘Njĩra ya Mwathani ti ya kĩhooto.’ Anga njĩra ciakwa ti cia kĩhooto, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli? Githĩ njĩra cianyu ticio itarĩ cia kĩhooto?
30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
“Nĩ ũndũ ũcio, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli, nĩngũmũtuĩra ciira, o mũndũ o mũndũ kũringana na mĩthiĩre yake, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga. Mwĩrirei! Tiganai na mahĩtia manyu mothe; namo mehia manyu matigatũma mwanangwo.
31 Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
Tiganai na waganu wothe ũrĩa mwĩkĩte, mũgĩe na ngoro njerũ na roho mwerũ. Nĩ kĩĩ gĩgũtũma mũkue, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli?
32 Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!
Nĩgũkorwo ndikenagio nĩ gĩkuũ kĩa mũndũ o na ũrĩkũ, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga. Mwĩrirei mũtũũre muoyo!

< Ezekiel 18 >