< Ezekiel 18 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
Yahweh gave me another message. [He said, ]
2 “Kín ni ẹ̀yin rò tí ẹ̀yin fi ń pa òwe nípa Israẹli wí pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà kíkan, eyín àwọn ọmọ sì kan.’
“You people quote [RHQ] this proverb [and say that it is] about Israel: ‘Parents/People eat sour grapes, but it is their children who have a very sour taste in their mouths', [which means that you think that it is not fair for you to be punished for your ancestors’ sins].
3 “Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, ẹ̀yin kí yóò pa òwe yìí mọ́ ni Israẹli.
But [I], Yahweh the Lord, declare that [as surely] as I am alive, you Israeli people will no longer quote that proverb.
4 Nítorí pé èmi ló ní gbogbo ọkàn, ọkàn baba tèmi bẹ́ẹ̀ ni ọkàn ọmọ pàápàá jẹ tèmi, ọkàn tó bá ṣẹ̀ ní yóò kú.
Everyone [who is alive] belongs to me. That includes children and their parents; they all belong to me. And it is those who sin who will [because of their sins].
5 “Bí ọkùnrin olódodo kan bá wà, tó ń ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ
[So, ] suppose there is a righteous person [always] does what is fair and right [DOU].
6 tí kò bá wọn jẹun lórí òkè gíga, tí kò gbójú rẹ̀ sókè sí àwọn òrìṣà ilẹ̀ Israẹli, ti kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́ tàbí kí ó sùn ti obìnrin ni àsìkò èérí rẹ̀.
He does not [meat sacrificed to idols] on the hilltops, he does not request help from idols. He does not have sex with someone else’s wife or have sex with a woman during her monthly menstrual period.
7 Kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, ó sì sanwó fún onígbèsè rẹ̀ gẹ́gẹ́ bó ṣe ṣe ìlérí fún un, kò fi ipá jalè ṣùgbọ́n ó fún ẹni tí ebi ń pa ní oúnjẹ, tí ó sì fi ẹ̀wù wọ àwọn tí ó wà ní ìhòhò.
He does not mistreat/oppress people; if [borrows money from him and gives him his cloak to guarantee that he will pay the money back], he always gives the cloak back to that [before the sun goes down]. He does not rob people. He gives food to hungry people. He gives clothing to people who need clothes.
8 Ẹni tí kò fi fún ni láti gba ẹ̀dá, tàbí kò gba èlé tó pọ̀jù. Ó yọ ọwọ́ rẹ̀ kúrò nínú ìwà ẹ̀ṣẹ̀, ó sì ń ṣe ìdájọ́ òtítọ́ láàrín ọkùnrin kan àti èkejì rẹ̀.
When he lends money to people, he does not [do it just to] charge big interest. He does not do [SYN] things that are evil. He [always] decides things fairly.
9 Tí ó ń tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ó sì ń pa òfin mi mọ́ lóòtítọ́ àti lódodo. Ó jẹ́ olódodo, yóò yè nítòótọ́, ní Olúwa Olódùmarè wí.
He faithfully obeys all [DOU] my laws. That man is truly righteous; he will remain alive. [That is what I, ] Yahweh the Lord, promise.
10 “Bí ó bá bi ọmọkùnrin, oníwà ipá, tó ń jalè, tó tún ń pànìyàn, tó sì ń ṣe gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí sí arákùnrin rẹ̀
But suppose that man has a son who acts violently, who murders people and does any of these other things, even though his father has not done any of them:
11 (tí kò sì ṣe ọ̀kan nínú gbogbo iṣẹ́ wọ̀n-ọn-nì): “Ó ń jẹun lójúbọ lórí òkè gíga, tí ó sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́.
He [meat sacrificed to idols] on the hilltops. He has sex with other people’s wives.
12 Ó ni àwọn tálákà àti aláìní lára, ó ń fipá jalè, kì í dá padà gẹ́gẹ́ bí ìlérí, o gbójú sókè sí òrìṣà, ó sì ń ṣe ohun ìríra.
He mistreats/oppresses poor and needy people. He robs people. If someone gives him his cloak to [that he will pay the money back], he never gives the cloak back to [before the sun goes down]. He seeks help from idols. He does [other] detestable things.
13 Ó ń fi owó ya ni pẹ̀lú èlé, ó sì tún ń gba èlé tó pọ̀jù. Ǹjẹ́ irú ọkùnrin yìí wa le è yè bí? Òun kì yóò wá láààyè! Nítorí pé òun ti ṣe àwọn ohun ìríra yìí, kíkú ni yóò kú, ẹ̀jẹ̀ rẹ yóò sì wá lórí rẹ̀.
When he lends money, he [very big] interest. If you think that such a person [be allowed to] remain alive [RHQ], you are certainly wrong. Because he has done those detestable things, he will surely be executed, and it will be his own fault [IDM].
14 “Bí ọkùnrin yìí bá bímọ ọkùnrin, tó sì rí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti baba rẹ ń ṣẹ̀ yìí, tó sì bẹ̀rù, ti kò ṣe irú rẹ̀:
But suppose that man has a son who sees all the sins that his father commits, but he does not do those things:
15 “Tí kò jẹun lójúbọ lórí òkè gíga tàbí kò gbójú sókè sí àwọn òrìṣà ilé Israẹli, tí kò sì ba obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́
He does not [meat sacrificed to idols] on the hilltops. He does not request help from idols. He does not have sex with other people’s wives.
16 tí kò sì ni ẹnikẹ́ni lára, tí kò dá ohun ògo dúró tí kò gba èlé tàbí kò fipá jalè ṣùgbọ́n tí ó ń fún ẹni tébi ń pa lóúnjẹ, tó sì fi aṣọ bo àwọn oníhòhò.
He does not mistreat/oppress people. If he lends money to someone, he does not require that person to give him his cloak to guarantee that he will pay the money back. He does not rob anyone. He gives food to those who need it. He gives clothes to those who need clothes.
17 Ó ń yọ ọwọ́ rẹ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀, kò sì gba èlé tàbí èlé tó pọ̀jù, tí ó ń pa òfin mi mọ́, tí ó sì ń tẹ̀lé àwọn àṣẹ mi. Kò ní kú fún ẹ̀ṣẹ̀ baba rẹ̀, nítòótọ́ ní yóò yè!
He does not commit sins, [like his father did], and does not charge big interest [DOU] when he lends money. He faithfully obeys [all] [DOU] my laws. That person will not be executed for his father’s sins; he will surely remain alive.
18 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ara rẹ̀, nítorí pé ó jẹ́ arẹ́nijẹ, ó jalè arákùnrin rẹ, ó ṣe ohun tí kò dára láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
But his father will be executed for the sins that he committed, because he cheated people and robbed people and did [other] things that are evil.
19 “Síbẹ̀, ẹ tún ń béèrè pé, ‘Kí ló dé ti ọmọ kò fi ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀?’ Níwọ́n ìgbà tí ọmọ ti ṣe ohun tó tọ́, tó sì yẹ, tó sì ti kíyèsi ara láti pa gbogbo àṣẹ mi mọ́, nítòótọ́ ni pé yóò yè.
[If] you ask, ‘Why should the [man’s] son not (suffer/be punished) for the evil things that his father did?’, [I will answer that] the son has done what is fair and right [DOU] and has obeyed all my laws, so he will surely remain alive.
20 Ọkàn tí ó bá ṣẹ̀ ní yóò kú. Ọmọ kò ní í ru ẹ̀bi baba rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni baba náà kò ní ru ẹ̀bi ọmọ rẹ̀. Ìwà rere ènìyàn rere yóò wà lórí rẹ̀, ìwà búburú ti ènìyàn búburú náà la ó kà sí i lọ́rùn.
It is those who sin who will [because of their sins]. People will not be punished for the sins of their parents, or for the sins of their children. Good/Righteous people will be rewarded for their being good/righteous, and evil people will be punished for [doing] evil.
21 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tó ti dá, tó sì bẹ̀rẹ̀ sí í pa àṣẹ mi mọ́, tó sì ń ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, nítòótọ́ ni yóò yè, kò sì ní kú.
But if a wicked person (turns away from/quits) doing all the evil things that he did previously, and if he starts to obey faithfully all my laws, and does what is fair and right [DOU], he will surely remain alive; he will not be executed.
22 A kò sì ní rántí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tó ti dá tẹ́lẹ̀ láti kà á sí lọ́rùn nítorí tí ìwà òdodo rẹ tó fihàn, yóò yè.
He will not be punished for the sins he committed [previously]. Because of the good/righteous things that he has done [since that time], he [be allowed to] remain alive.
23 Ǹjẹ́ èmi ha ni inú dídùn si ikú ènìyàn búburú bí í? Ní Olúwa Olódùmarè wí pé, dípò èyí inú mi kò ha ni i dùn nígbà tó ba yípadà kúrò ni àwọn ọ̀nà búburú rẹ̀ kí ó sì yè?
[I], Yahweh the Lord, declare that I certainly am not [RHQ] happy about wicked people dying. Instead, I am happy when they turn away from their wicked behavior, [because of that, they] remain alive.
24 “Ṣùgbọ́n bí ènìyàn rere bá yípadà kúrò ni ọ̀nà òdodo rẹ̀ tó sì ń dẹ́ṣẹ̀, tí ó sì tún ń ṣe àwọn ohun ìríra tí ènìyàn búburú ń ṣe, yóò wa yè bí? A kì yóò rántí ọ̀kankan nínú ìwà rere rẹ̀ mọ́, nítorí ó ti jẹ̀bi ìwà àrékérekè àti ẹ̀ṣẹ̀ tó dá, yóò sì kú.
But if a righteous person stops doing righteous things and [starts to] commit sins and does the same detestable things that wicked people do, he will certainly not [RHQ] [be allowed to] remain alive. I will not think about the righteous things that he did previously. Because he did not [do what pleases me], and because of [all] the sins that he has committed, he will be executed.
25 “Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin tún wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ ilé Israẹli. Ọ̀nà mi ni kò ha gún? Kì í wa ṣé pé ọ̀nà tiyín gan an ni kò gún?
But you say, ‘Yahweh does not act fairly!’ You Israeli people, listen to what I say: It is certainly not [RHQ] what I do that is unfair, it is what you continually do that is not fair/right!
26 Bí olódodo ba yípadà kúrò nínú olódodo rẹ̀, tó sì dẹ́ṣẹ̀, yóò ku fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá.
If a righteous person (turns away from/quits) doing what is righteous and commits sins, he will [for committing those sins].
27 Ṣùgbọ́n bi ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú tó ti ṣe, tó sì ṣe ohun tó tọ́ àti ohun tó yẹ, yóò gba ẹ̀mí rẹ̀ là.
But if a wicked person turns away from doing wicked things and does what is just and right [DOU], he will save [from being executed/punished].
28 Nítorí pé ó ronú lórí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tó ti dá, ó sì yípadà kúrò nínú wọn, nítòótọ́ ni yóò yè; kì yóò sí kú.
Because he has thought about all the evil things that he did and has turned away from doing them, he will [be allowed to] live. He will not be executed [for having done evil things].
29 Síbẹ̀, ilé Israẹli wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò gún.’ Ọ̀nà mi kò ha tọ́ bí ilé Israẹli? Kì í wa ṣe pè ọ̀nà tiyín gan an ni ko gún?
But [you] Israeli people [MTY] say, ‘Yahweh does not act fairly.’ You people of Israel, my behavior is certainly not [RHQ] unfair! It is your behavior that is not right.
30 “Nítorí náà, ilé Israẹli, èmi yóò da yín lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà ẹnìkọ̀ọ̀kan yín bá ṣe rí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ẹ yípadà! Kí ẹ si yí kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ yín, bẹ́ẹ̀ ni ìrékọjá kì yóò jẹ́ ọ̀nà ìṣubú yín.
Therefore, you Israeli people [MTY], I, Yahweh the Lord, will judge each of you according to what you have done. Repent! Turn [away] from all your wicked behavior! Then you will not be destroyed [PRS] because of your sins.
31 Ẹ kọ̀ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ti ẹ ti dá sílẹ̀, kí ẹ sì gba ọkàn àti ẹ̀mí tuntun. Nítorí kí ló fi máa kú, ilé Israẹli?
Get rid of all your wicked behavior, and get a new way of thinking [IDM, DOU]. You Israeli people [MTY], (do you really want to be executed for your sins?/you act as though you want to be executed [for your sins]) [RHQ].
32 Nítorí pé inú mi kò dùn sí ikú ẹnikẹ́ni ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí náà, ẹ yípadà kí ẹ sì yè!
[I], Yahweh the Lord, declare that I am not pleased about your dying. So repent, and remain alive!”