< Ezekiel 17 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
Și cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
Fiu al omului, pune înainte o ghicitoare și vorbește o parabolă casei lui Israel;
3 Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
Și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: O acvilă mare cu aripi mari, aripi lungi, plină de pene, care avea culori diferite, a venit în Liban și a luat ramura cea mai înaltă a cedrului;
4 ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
A rupt vârful lăstarilor lui și l-a dus într-o țară de comerț; l-a pus într-o cetate de comercianți.
5 “‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
El a luat de asemenea din sămânța țării și a sădit-o într-un câmp roditor; a pus-[o] lângă ape mari [și] a sădit-o [ca] pe o salcie.
6 Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
Și ea a crescut și a devenit o viță care se întinde, [dar] de statură mică, a cărei ramuri s-au întors spre ea și rădăcinile ei erau sub el; astfel a devenit o viță și a adus ramuri și a dat mulți lăstari.
7 “‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
Era de asemenea o altă acvilă mare cu aripi mari și pene multe; și, iată, această viță și-a plecat rădăcinile spre ea, și și-a întins multe ramuri spre ea, ca ea să o adape [din] brazdele sădirii ei.
8 Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
Era sădită într-un pământ bun lângă ape mari, ca să facă ramuri și să dea rod, ca să ajungă o viță frumoasă.
9 “Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
Spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Va prospera? Nu va smulge el rădăcinile acesteia și nu îi va tăia rodul, ca să se ofilească? Se va ofili în toate frunzele ei înverzite, fără ca o mare putere și mult popor să o smulgă din rădăcinile ei.
10 Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
Da, iată, [fiind] sădită, va prospera? Nu se va ofili de tot când vântul de est o atinge? Se va ofili în brazdele unde a crescut.
11 Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
Mai mult, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
12 “Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
Spune acum casei cea răzvrătită: Nu știți voi ce [înseamnă acestea]? Spune-[le]: Iată, împăratul Babilonului a venit la Ierusalim și a luat pe împăratul lui și pe prinții lui și i-a dus cu el la Babilon;
13 Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
Și a luat din sămânța împăratului și a făcut legământ cu el și a luat un jurământ de la el; a luat de asemenea pe cei puternici ai țării;
14 Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
Ca împărăția să fie înjosită, ca să nu se ridice, [ci] prin ținerea legământului său să stea în picioare.
15 Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
Dar el s-a răzvrătit împotriva lui trimițând pe ambasadorii lui în Egipt, ca ei să îi dea cai și mult popor. Va prospera el? Va scăpa cel care face acestea? Va rupe el legământul și va scăpa?
16 “‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
[Precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU, cu siguranță, în locul [în care locuiește] împăratul care l-a făcut împărat, al cărui jurământ el l-a disprețuit și al cărui legământ l-a rupt, va muri cu el în mijlocul Babilonului.
17 Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Nici Faraon cu armata [lui] puternică și marea ceată nu va face nimic pentru el în război, ridicând valuri de pământ și construind fortificații, pentru a stârpi multe persoane;
18 Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
Văzând că el a disprețuit jurământul prin ruperea legământului, când, iată, el și-a dat mâna și a făcut toate acestea, nu va scăpa.
19 “‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
De aceea astfel spune Domnul DUMNEZEU: [Precum] eu trăiesc, într-adevăr, jurământul meu pe care l-a disprețuit și legământul meu pe care l-a rupt, chiar pe acesta îl voi întoarce asupra capului său.
20 Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
Și îmi voi întinde plasa peste el și va fi prins în cursa mea și îl voi aduce la Babilon și mă voi judeca acolo cu el pentru fărădelegea lui cu care a încălcat [legea], împotriva mea.
21 Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
Și toți fugarii lui cu toate cetele lui vor cădea prin sabie, iar cei ce rămân vor fi împrăștiați în toate vânturile; și veți cunoaște că eu, DOMNUL, am vorbit.
22 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Eu de asemenea voi lua din ramura cea mai înaltă a cedrului cel înalt și [o] voi pune; voi tăia din vârful lăstarilor lui unul fraged și [îl] voi sădi pe un munte înalt și înălțat;
23 Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
Pe muntele înălțimii lui Israel îl voi sădi; și va aduce mlădițe și va da rod și va fi un cedru frumos; și sub el vor locui toate păsările de tot felul; în umbra ramurilor lui vor locui ele.
24 Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”
Și toți copacii câmpului vor cunoaște că eu, DOMNUL, am înjosit copacul înalt, am înălțat copacul de jos, am uscat copacul verde și am făcut copacul uscat să înflorească; eu, DOMNUL, am vorbit și am făcut [aceasta].

< Ezekiel 17 >