< Ezekiel 17 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
I doszło do mnie słowo PANA mówiące:
2 “Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
Synu człowieczy, zadaj zagadkę i opowiedz domowi Izraela przypowieść;
3 Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
I powiedz: Tak mówi Pan BÓG: Wielki orzeł o wielkich i długich skrzydłach, pełen pstrego pierza, przyleciał nad Liban i wziął wierzchołek cedru.
4 ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
Ułamał koniec jego pędów, zaniósł go do ziemi kupieckiej i złożył go w mieście kupieckim.
5 “‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
Wziął też nasienie tej ziemi i zasadził na urodzajnym polu; umieścił je nad wielkimi wodami jak wierzbę.
6 Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
I urosło, i stało się bujną winoroślą, [choć] niskiego wzrostu; jej latorośle zwracały się ku niemu, a korzenie były mu poddane. I stało się winoroślą, która wydała latorośle i wypuściła pędy.
7 “‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
Ale był inny wielki orzeł o wielkich skrzydłach i gęstym pierzu, a oto ta winorośl zwróciła swoje korzenie ku niemu i rozciągnęła swe latorośle do niego, aby on ją nawadniał z bruzd swego sadu.
8 Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
A [była] przecież zasadzona na dobrym polu, nad wielkimi wodami, aby wypuściła latorośle, wydała owoc i stała się wspaniałą winoroślą.
9 “Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
Wtedy powiedz: Tak mówi Pan BÓG: Czy się jej poszczęści? Czy [orzeł] nie wyrwie jej korzeni i nie oberwie jej owocu [tak], by uschła? Uschną wszystkie listki, które wypuści, i nie będzie trzeba wielkiej mocy ani licznego ludu, aby ją wyrwać z korzeniami.
10 Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
Oto jakkolwiek będzie zasadzona, czy się [jej] poszczęści? Czy doszczętnie nie uschnie, gdy dotknie ją wiatr wschodni? Uschnie w bruzdach, w których wyrosła.
11 Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
Potem doszło do mnie słowo PANA:
12 “Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
Mów teraz do domu buntowniczego: Czyż nie wiecie, co znaczą te [rzeczy]? Powiedz: Oto król Babilonu przybył do Jerozolimy, zabrał jej króla i książąt i uprowadził ich ze sobą do Babilonu.
13 Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
Wziął też jednego z potomków króla, zawarł z nim przymierze i związał go przysięgą. Zabrał też możnych tej ziemi;
14 Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
Aby królestwo było poniżone, tak by się nie podnosiło, [ale] by tak trwało, zachowując jego przymierze.
15 Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
Lecz on zbuntował się przeciwko niemu, wysyłając swych posłów do Egiptu, aby dano mu koni i liczny lud. Czy mu się poszczęści? Czy ujdzie zemsty ten, który tak czynił? Czy ocali się ten, który złamał przymierze?
16 “‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
Jak żyję, mówi Pan BÓG, w miejscu tego króla, który go uczynił królem, a którego przysięgą wzgardził i którego przymierze złamał, u niego w Babilonie umrze.
17 Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
I ani faraon z wielkim wojskiem i z licznym zastępem nie pomoże mu na wojnie, gdy usypie wały i pobuduje wieże, aby zniszczyć mnóstwo ludzi;
18 Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
Ponieważ wzgardził przysięgą, łamiąc przymierze. Oto bowiem dał na to swą rękę, a to wszystko uczynił. Nie ujdzie zemsty.
19 “‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
Dlatego tak mówi Pan BÓG: Jak żyję, moją przysięgę, którą wzgardził, i moje przymierze, które złamał, złożę mu na głowę.
20 Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
Rozciągnę na nim swoją sieć i zostanie schwytany w moje sidła, i zaprowadzę go do Babilonu, a tam się z nim rozprawię za jego występek, którym zgrzeszył przeciwko mnie.
21 Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
A wszyscy, którzy uciekli od niego wraz ze wszystkimi jego hufcami, od miecza polegną, a pozostali zostaną rozproszeni na wszystkie wiatry. I poznacie, że ja, PAN, [to] powiedziałem.
22 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
Tak mówi Pan BÓG: Wezmę wierzchołek tego wysokiego cedru i zasadzę; z najwyższych jego gałązek odłamię młodą gałązkę i zasadzę [ją] na wysokiej i wyniosłej górze;
23 Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
Na wysokiej górze Izraela ją zasadzę. Wypuści gałązki, wyda owoc i stanie się cedrem wspaniałym. I będzie mieszkać pod nim wszelkie ptactwo skrzydlate; pod cieniem jego gałęzi będą mieszkać.
24 Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”
A tak wszystkie drzewa polne poznają, że ja, PAN, poniżyłem drzewo wysokie, a wywyższyłem drzewo niskie, ususzyłem drzewo zielone, a sprawiłem, że zakwitło drzewo suche. Ja, PAN, to powiedziałem i uczynię.

< Ezekiel 17 >