< Ezekiel 17 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
2 “Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
Menneskesønn! Fremsett en gåte for Israels hus og tal til dem i en lignelse
3 Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
og si: Så sier Herren, Israels Gud: Den store ørn med de store vinger og de lange svingfjær, med full fjærham og brokete farver, kom til Libanon og tok bort toppen av sederen.
4 ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
Den brøt av den øverste kvist og førte den til kjøbmannslandet og satte den i kremmerstaden.
5 “‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
Så tok den et skudd av landets vekster og satte det i en dyrket mark; den plantet det på et sted hvor det var meget vann; den satte det likesom et piletre.
6 Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
Og det vokste op og blev til et vintre som bredte sig vidt ut, men var lavt av vekst, forat dets ranker skulde vende sig til den, og dets røtter være under den. Og det blev til et vintre som satte grener og skjøt løvrike kvister.
7 “‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
Men det var en annen stor ørn med store vinger og mange fjær, og se, vintreet bøide sine røtter bort imot den, og fra den seng hvori det var plantet, strakte det sine ranker bort til den, forat den skulde vanne det.
8 Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
På en god mark, på et sted hvor det var meget vann, var det plantet, så det kunde skyte grener og bære frukt og bli et herlig vintre.
9 “Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
Si: Så sier Herren, Israels Gud: Skal det trives? Skal ikke dets røtter rykkes op og dets frukt rives av, så det tørker bort? Alle dets spirende blad skal tørke bort, og ikke med stor styrke og meget folk vil nogen kunne få det til å skyte op av sine røtter.
10 Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
Se, det er plantet; skal det trives? Skal det ikke tørke bort, tørke aldeles bort, så snart østenvinden rører ved det? I den seng hvor det vokser, skal det tørke bort.
11 Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
Og Herrens ord kom til mig, og det lød så:
12 “Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
Si til den gjenstridige ætt: Vet I ikke hvad dette er? Si: Se, Babels konge kom til Jerusalem og tok dets konge og dets høvdinger og førte dem til sig i Babel.
13 Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
Og han tok en av kongeætten og gjorde en pakt med ham og tok ham i ed, og de mektige i landet tok han med sig,
14 Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
forat det skulde være et ringe kongerike og ikke ophøie sig, men holde pakten med ham og bli stående.
15 Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
Men han falt fra ham og sendte sine bud til Egypten, forat de skulde gi ham hester og meget folk. Skal han ha fremgang? Skal den som gjør slikt, slippe unda? Skal han kunne bryte en pakt og slippe unda?
16 “‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
Så sant jeg lever, sier Herren, Israels Gud, på det sted hvor han bor den konge som gjorde ham til konge, men hvis ed han foraktet, og hvis pakt han brøt, hos ham, midt i Babel skal han visselig dø.
17 Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Og ikke skal Farao med en stor hær og meget folk komme ham til hjelp i krigen, når det kastes op en voll og bygges skanser for å utrydde mange liv.
18 Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
Han foraktet eden og brøt pakten, enda han hadde gitt hånden på det. Alt dette har han gjort; han skal ikke slippe unda.
19 “‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
Derfor sier Herren, Israels Gud, så: Så sant jeg lever, eden som han svor ved mig, men allikevel foraktet, og pakten som han gjorde med mig, men allikevel brøt, den vil jeg visselig la komme over hans hode.
20 Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
Jeg vil utspenne mitt garn over ham, og han skal fanges i mitt nett, og jeg vil føre ham til Babel og gå i rette med ham der, for den troløshet som han har vist mot mig.
21 Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
Og alle flyktninger fra alle hans krigsskarer skal falle for sverdet, og de som blir igjen, skal spredes for alle vinder, og I skal kjenne at jeg, Herren, har talt.
22 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
Så sier Herren, Israels Gud: Da vil jeg ta en kvist av den høie seders topp og sette; av dens øverste kvister vil jeg bryte av et spett skudd, og jeg vil sette det på et høit, høit fjell.
23 Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
På Israels høie fjell vil jeg plante det, og det skal skyte grener og bære frukt og bli til en herlig seder, og alle slags fugler, alt som har vinger, skal bo under det; i skyggen av dets grener skal de bo.
24 Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”
Og alle markens trær skal kjenne at jeg, Herren, har gjort et høit tre lavt og et lavt tre høit, et friskt tre tørt og et tørt tre grønt; jeg, Herren, har sagt det, og jeg skal gjøre det.

< Ezekiel 17 >