< Ezekiel 17 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ ní wá wí pé:
És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
2 “Ọmọ ènìyàn pa àlọ́ kan, sì pa òwe kan fún ilé Israẹli.
Ember fia, adj fel egy rejtvényt és mondj egy példázatot Izrael házáról.
3 Sọ fún wọn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, idì ńlá kan tó ní apá títóbi àti ìyẹ́ gígùn tó kún fún àwọ̀ oríṣìíríṣìí wa si Lebanoni, ó sì mu ẹ̀ka igi kedari tó ga jùlọ,
És mondjad: így szól az Úr, az Örökkévaló. A nagy sas, a nagy szárnyú, hosszú tollú, teli tollazatú, melynek tarka a színe, eljött a Libazonba és elvette a cédrusnak sudarát;
4 ó gé ọ̀mùnú orí ẹ̀ka yìí kúrò, ó mú un lọ sí ilẹ̀ oníṣòwò, ó sì gbìn ín sí ìlú àwọn oníṣòwò.
gallyainak legfelsőbbjét letépte és elvitte kalmárok országába, kereskedők városában helyezte el.
5 “‘Ó mú lára irúgbìn ilẹ̀ náà, ó gbìn ín sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi, ó gbìn ín bí igi wílóò.
És vett az ország vetéséből és vetésre való mezőbe tette, elvitte nagy víz mellé, fűzfaképen helyezte el.
6 Ó dàgbà, ó sì di àjàrà tó kúrú ṣùgbọ́n to bolẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ kọjú sí i, gbòǹgbò rẹ̀ sì dúró lábẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ó di àjàrà, ó sì mu ẹ̀ka àti ewé jáde.
Kisarjadt és terjeszkedő szőlőtővé lett, alacsony termetűvé úgy hogy ágai hozzáhajoltak és gyökerei alatta voltak; és szőlőtővé lett, vesszőket hajtott és ágacskákat eresztett.
7 “‘Ṣùgbọ́n ẹyẹ idì ńlá mìíràn tún wá, tó ní apá títóbi pẹ̀lú ìyẹ́ púpọ̀. Gbòǹgbò àjàrà náà sì ta lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ láti orí ilẹ̀ tí wọn gbìn ín sí, ó wá pẹ̀ka lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ kí ó le fún un ni omi.
De volt egy nagy sas, nagy szárnyú és sok tollozatú és íme, ez a szőlőtő feléje görbítette gyökereit és ágait hozzá eresztette, hogy őt itassa, ültetvénye ágyaiból.
8 Orí ilẹ̀ tó dára lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi ni a gbìn ín sí, kí ó bá à le pẹ̀ka, kò sì so èso, ó sì wá di igi àjàrà tó lọ́lá púpọ̀.’
Jó mezőre, nagy víz mellé van ültetve, hogy lombot hajtson és gyümölcsöt teremjen, hogy pompás szőlőtővé váljék.
9 “Sọ fún wọn pé, ‘Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyí, yóò wá gbilẹ̀ bí? A kò wá ní i wú gbòǹgbò rẹ̀, ki a si gé èso rẹ̀ kúrò kí ó bá à le rọ? Gbogbo ewé rẹ̀ tó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ ni yóò rẹ̀. Kò sì nígbà agbára tàbí ènìyàn púpọ̀ láti fà gbòǹgbò rẹ̀ tu.
Mondjad, így szól az Úr, az Örökkévaló: fog-e boldogulni? nemde ki fogja szakítani gyökereit és gyümölcsét lemetszi, hogy elszáradjon, minden kisarjadt levele el fog száradni; és nem nagy karral és sok néppel kell őt kirántani gyökereiből.
10 Bí a tilẹ̀ tún un gbìn, yóò wa gbilẹ̀ bí? Kò wá ní i rọ pátápátá nígbà ti afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn bá kọlù ú. Gbogbo ewé rẹ̀ yóò rẹ̀ lórí ilẹ̀ tó ti dàgbà?’”
Íme el van ültetve, vajon fog-e boldogulni? Nemde, amint a keleti szél éri, száradva elszárad, sarjadása ágyain fog elszáradni.
11 Nígbà náà, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mi wá pé:
És lett hozzám az Örökkévaló igéje, mondván:
12 “Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé yìí, ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ ìtumọ̀ àwọn nǹkan wọ̀nyí?’ Sọ fún wọn: ‘Ọba Babeli wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó ọba àti àwọn ìjòyè ọmọ-aládé ibẹ̀ lọ sí Babeli lọ́dọ̀ rẹ̀.
Mondjad csak az engedetlenség házának: nemde tudjátok, mik ezek? Mondjad: Íme eljött Bábel királya Jeruzsálembe és elvitte királyát és nagyjait és vitte őket magához Bábelbe.
13 Lẹ́yìn èyí, ó bá ọ̀kan nínú ọmọ ọba dá májẹ̀mú, ó mú un ìbúra, ó tún kó àwọn alágbára ilẹ̀ náà lọ.
És vett; a királyi magzatból és kötött vele szövetséget és eskübe fogadta és az ország vezéreit elvitte,
14 Kí ìjọba ilẹ̀ náà le rẹ ilẹ̀, kí ó má lè gbé ara rẹ̀ sókè, kí ó lè dúró nípa pípa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
hogy alacsony királyság legyen, hogy föl ne emelkedjék, megőrizve az ő szövetségét, hogy az fennálljon.
15 Ṣùgbọ́n ọba ṣọ̀tẹ̀ sí i nípa ríran àwọn ikọ̀ rẹ̀ lọ sí Ejibiti, kí wọn bá à lè fún un ni ẹṣin àti àwọn ọmọ-ogun púpọ̀. Yóò ha ṣe àṣeyọrí? Ṣe ẹni tó ṣe irú nǹkan yìí yóò sì bọ́ níbẹ̀? Yóò ha dalẹ̀ tán kí ó sì bọ́ níbẹ̀ bí?
De fellázadt ellene, követet küldve Egyiptomba, hogy adjanak neki lovakat és sok népet; vajon fog-e boldogulni, megmenekül-e aki ezeket teszi? Szövetséget bontott föl, és megmeneküljön:
16 “‘Bí mo ti wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, òun yóò kú ní Babeli, ní ilẹ̀ ọba tó fi sórí oyè, ìbúra ẹni tí ó kẹ́gàn àti májẹ̀mú ẹni tí ó dà.
hogy én élek, úgymond az Úr, az Örökkévaló, bizony azon király székhelyén, aki őt királlyá tette, akinek esküjét megvetette és akinek szövetségét fölbontotta, ő nála, Bábel közepén fog meghalni.
17 Farao pẹ̀lú àwọn ọmọ-ogun àti àjọ ńlá rẹ̀ kò ní lè ṣe ìrànwọ́ fún un lójú ogun. Nígbà tí wọ́n bá pa bùdó ogun tì í, tí wọ́n sì mọ odi láti pa ọ̀pọ̀ ènìyàn.
És nem nagy hadsereggel és sok gyülekezettel fog vele együttműködni Fáraó a háborúban, mikor sáncot hánynak föl és ostromtornyokat építenek, sok lélek kiirtására.
18 Nítorí pé ó kẹ́gàn ìbúra nípa dída májẹ̀mú, àti pé ó juwọ́ sílẹ̀ nínú ṣíṣe ìlérí, kì yóò bọ níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn nǹkan tí ó ṣe yìí.
Hisz megvetette az esküt, fölbontva a szövetséget, és íme kezét adta és mindezeket tette: nem fog megmenekülni.
19 “‘Nítorí náà Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ti wà láààyè, Èmi yóò mú ẹ̀san ẹ̀jẹ́ mi tó kẹ́gàn àti májẹ̀mú mi tó dà wa sórí rẹ̀.
Azért, úgymond az Úr, az Örökkévaló, ahogy élek, bizony az én eskümet, melyet megvetett és szövetségemet, melyet fölbontott, fejére hárítom.
20 Èmi yóò ta àwọ̀n mi sórí rẹ̀, yóò sì bọ sínú okùn mi, Èmi yóò mú ọ lọ Babeli láti ṣe ìdájọ́ ìwà ọ̀dàlẹ̀ tó hù sí mi.
És kiterítem rá hálómat és megfogatik varsámban és elviszem őt Bábelbe és ítéletre szállok ott vele hűtlenségéért, mellyel hűtlenkedett irántam.
21 Gbogbo ìgbèkùn àti ọ̀wọ́ ọmọ-ogun rẹ̀ ni yóò kú pẹ̀lú idà, èmi yóò sì fọn àwọn ìyókù ká sínú afẹ́fẹ́ káàkiri. Nígbà náà ni yóò mọ̀ pé, “Èmi Olúwa ni ó ti sọ̀rọ̀.”
És mind a szökevényei, minden csapatjában, kard által fognak elesni, és a megmaradottak minden szélnek fognak elszóratni; és megtudjátok, hogy én az Örökkévaló beszéltem.
22 “‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi fúnra mi yóò mú ọ̀kan lára ẹ̀ka tí ó ga jùlọ lórí igi kedari gíga, tí èmi yóò sì gbìn ín, èmi yóò sì gé ọ̀mùnú tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ yọ láti òkè, èmi yóò sì gbìn ín sórí òkè tó ga tó sì lókìkí.
Így szól az Úr, az Örökkévaló: Majd veszek én a cédrusnak magas sudarából és elültetem; legfelsőbb gallyaiból egy gyengét tépek le, és majd elplántálom én magas, ormos hegyre.
23 Ní ibi gíga òkè Israẹli ni èmi yóò gbìn ín sí; yóò pẹ̀ka, yóò sì so èso, yóò wa di igi kedari tí ó lọ́lá. Oríṣìíríṣìí ẹyẹ yóò sì fi òjìji abẹ ẹ̀ka rẹ ṣe ibùgbé; wọn yóò ṣe ibùgbé si abẹ́ òjìji ẹ̀ka rẹ̀.
Izraelnek magasságos hegyén fogom elplántálni, hogy lombot hajtson és gyümölcsöt teremjen és pompás cédrussá váljék; és majd lakik alatta minden madár, minden szárnyas, ágai árnyékában laknak.
24 Gbogbo igi inú oko yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ni ó mú igi gíga walẹ̀, tí mo sì mú kúkúrú ga sókè, tí mo mu igi tútù gbẹ, tí mo sì mú igi gbígbẹ rúwé. “‘Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀, Èmi yóò sì ṣe e.’”
És megtudják a mezőnek fái mind, hogy én az Örökkévaló alacsonyítottam le a magas fát, emeltem föl az alacsony fát, szárasztottam el a viruló fát és virágoztattam föl a száradt fát; én az Örökkévaló beszéltem és megteszem.

< Ezekiel 17 >