< Ezekiel 16 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
Du människobarn, förehåll Jerusalem dess styggelser
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
och säg: Så säger Herren, HERREN till Jerusalem: Från Kanaans land stammar du, och där är du född; din fader var en amoré och din moder en hetitisk kvinna.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
Och vid din födelse gick det så till. När du föddes, skar ingen av din navelsträng, och du blev icke rentvagen med vatten, ej heller ingniden med salt och lindad.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Ingen såg på dig med så mycken ömkan, att han villa göra något sådant med dig eller visa dig någon misskund, utan man kastade ut dig på öppna fältet den dag du föddes; så ringa aktade man ditt liv.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
Då gick jag förbi där du låg och fick se dig sprattla i ditt blod, och jag sade till dig: »Du skall få bliva vid liv, du som ligger där i ditt blod.» Ja, jag sade till dig: »Du skall få bliva vid liv, du som ligger där i ditt blod;
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
ja, jag skall föröka dig till många tusen, såsom växterna äro på marken.» Och du sköt upp och blev stor och mycket fager; dina bröst hade höjt sig, och ditt hår hade växt, men du var ännu naken och blottad.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Då gick jag åter förbi där du var och fick se att din tid var inne, din älskogstid; och jag bredde min mantel över dig och betäckte din blygd. Och så gav jag dig min ed och ingick förbund med dig, säger Herren, HERREN, och du blev min.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
Och jag tvådde dig med vatten och sköljde blodet av dig, och smorde dig med olja,
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
och klädde på dig brokigt vävda kläder och satte på dig skor av tahasskinn och en huvudbindel av fint linne och en slöja av silke.
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
Och jag prydde dig med smycken: jag satte armband på dina armar och en kedja om din hals,
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
jag satte en ring i din näsa och örhängen i dina öron och en härlig krona på ditt huvud.
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
Så blev du prydd med guld och silver, och dina kläder voro av fint linne, av siden och av tyg i brokig vävnad. Fint mjöl, honung och olja fick du äta. Du blev övermåttan skön, och så vart du omsider en drottning.
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Och ryktet om dig gick ut bland folken för din skönhets skull, ty den var fullkomlig genom de härliga prydnader som jag hade satt på dig, säger Herren, HERREN.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
Men du förlitade dig på din skönhet och bedrev otukt, sedan du nu hade fått sådant rykte; du slösade din otukt på var och en som gick där fram: det vore ju något för honom.
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
Och du tog dina kläder och gjorde dig med dem brokiga offerhöjder och bedrev på dessa otukt, sådana gärningar som eljest aldrig någonsin hava förekommit, ej heller mer skola göras.
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
Och du tog dina härliga smycken, det guld och silver som jag hade givit dig, och gjorde dig så mansbilder, med vilka du bedrev otukt.
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
Och du tog dina brokigt vävda kläder och höljde dem i dessa; och min olja och min rökelse satte du fram för dem.
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Och det bröd som jag hade givit dig -- ty fint mjöl, olja och honung hade jag ju låtit dig få att äta -- detta satte du fram för dem till en välbehaglig lukt; ja, därhän kom det, säger Herren, HERREN.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
Och du tog dina söner och döttrar, dem som du hade fött åt mig, och offrade dessa åt dem till spis. Var det då icke nog att du bedrev otukt?
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
Skulle du också slakta mina söner och giva dem till pris såsom offer åt dessa?
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
Och vid alla dina styggelser och din otukt tänkte du icke på din ungdoms dagar, då du var naken och blottad och låg där sprattlande i ditt blod.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
Och sedan du hade bedrivit all denna ondska -- ve, ve dig! säger Herren, HERREN --
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
byggde du dig kummel och gjorde dig höjdaltaren på alla öppna platser.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
I alla gathörn byggde du dig höjd altaren och lät din skönhet skända och spärrade ut benen åt alla som gingo där fram; ja, du bedrev mycken otukt.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
Du bedrev otukt med egyptierna, dina grannar med det stora köttet, ja, mycken otukt till att förtörna mig.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Men se, då uträckte jag min hand mot dig och minskade ditt underhåll och gav dig till pris åt dina fiender, filistéernas döttrar, som blygdes över ditt skändliga väsende.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
Men sedan bedrev du otukt med assyrierna, ty du hade ännu icke blivit mätt; ja, du bedrev otukt med dem och blev ändå icke mätt.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
Du gick med din otukt ända bort till krämarlandet, kaldéernas land; men icke ens så blev du mätt.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
Huru älskogskrankt var icke ditt hjärta, säger Herren, HERREN, eftersom du gjorde allt detta, sådana gärningar som allenast den fräckaste sköka kan göra.
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
Med dina döttrar uppförde du åt dig kummel i alla gathörn och höjdaltaren på alla öppna platser. Men däri var du olik andra skökor, att du försmådde skökolön,
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
du äktenskapsbryterska, som i stället för den man du hade tog andra män till dig.
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Åt alla andra skökor måste man giva skänker, men här var det du som gav skänker åt alla dina älskare och mutade dem, för att de skulle komma till dig från alla håll och bedriva otukt med dig.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
Så gjorde du vid din otukt tvärt emot vad andra kvinnor göra; efter dig lopp ingen för att bedriva otukt, men du gav skökolön, utan att själv få någon skökolön; du gjorde tvärt emot andra.
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Hör därför HERRENS ord, du sköka.
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Så säger Herren, HERREN: Eftersom du har varit så frikostig med din skam och blottat din blygd i otukt med din älskare, därför, och för alla dina vederstyggliga eländiga avgudars skull och för dina söners blods skull, dina söners, som du gav åt dessa,
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
se, därför skall jag församla alla dina älskare, dem som du har varit till behag, ja, alla dem som du har älskat mer eller mindre; dem skall jag församla mot dig från alla håll och blotta din blygd inför dem, så att de få se all din blygd.
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
Och jag skall döma dig efter den lag som gäller för äktenskapsbryterskor och blodsutgjuterskor, och skall låta dig bliva ett blodigt offer för min vrede och nitälskan.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
Och jag skall giva dig i deras hand, och de skola slå ned dina kummel och bryta ned dina höjdaltaren, och slita av dig kläderna och taga ifrån dig dina härliga smycken och låta dig ligga naken och blottad.
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
Och de skola sammankalla en församling mot dig, och man skall stena dig och hugga sönder dig med svärd;
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
och dina hus skall man bränna upp i eld. Så skall man hålla dom över dig inför många kvinnors ögon. Och så skall jag göra slut på din otukt, och du skall icke mer kunna giva någon skökolön.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
Och jag skall släcka min vrede på dig, så att min nitälskan kan vika ifrån dig, och så att jag får ro och slipper att mer förtörnas.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
Eftersom du icke tänkte på din ungdoms dagar, utan var avog mot mig i allt detta, se, därför skall också jag låta dina gärningar komma över ditt huvud, säger Herren, HERREN, på det att du icke mer må lägga sådan skändlighet till alla dina andra styggelser.
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
Se, alla som bruka ordspråk skola på dig tillämpa det ordspråket: »Sådan moder, sådan dotter.»
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
Ja, du är din moders dotter, hennes som övergav sin man och sina barn; du är dina systrars syster deras som övergåvo sina män och sina barn; eder moder var en hetitisk kvinna och eder fader en amoré.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
Din större syster var Samaria med sina döttrar, hon som bodde norrut från dig; och din mindre syster, som bodde söderut från dig, var Sodom med sina döttrar.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Men du nöjde dig icke med att vandra på deras vägar och att göra efter deras styggelser; inom kort bedrev du värre ting än de, på alla dina vägar.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
Så sant jag lever, säger Herren, HERREN: din syster Sodom och hennes döttrar hava icke gjort vad du och dina döttrar haven gjort.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
Se, detta var din syster Sodoms missgärning: fastän höghet, överflöd och tryggad ro hade blivit henne och hennes döttrar beskärd, understödde hon likväl icke den arme och fattige.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Tvärtom blevo de högfärdiga och bedrevo vad styggeligt var inför mig; därför försköt jag dem, när jag såg detta.
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Ej heller Samaria har syndat hälften så mycket som du. Du har gjort så många flera styggelser än dessa, att du genom alla de styggelser du har bedrivit har kommit dina systrar att synas rättfärdiga.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
Så må också du nu bara din skam, du som nu kan lända dina systrar till ursäkt; ty därigenom att du har bedrivit ännu vederstyggligare synder än de, stå nu såsom rättfärdiga i jämförelse med dig. Ja, blygs och bär din skam över att du så har kommit dina systrar att synas rättfärdiga.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
Därför skall jag ock åter upp rätta dem, Sodom med hennes döttrar och Samaria med hennes döttrar. Dig skall jag ock åter upprätta mitt ibland dem,
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
för att du må bära din skam och skämmas för allt vad du har gjort, och därmed bliva dem till tröst.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Och med dina systrar skall så ske: Sodom och hennes döttrar skola åter bliva vad de fordom voro, och Samaria och hennes döttrar skola åter bliva vad de fordom voro Också du själv och dina döttrar skolen åter bliva vad I fordom voren.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
Men om du förr icke ens hördes nämna din syster Sodom, under din höghetstid,
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
innan ännu din egen ondska hade blivit uppenbarad -- såsom den blev på den tid då du vart till smälek för Arams döttrar och för alla de kringboende filistéernas döttrar, som hånade dig på alla sidor --
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
Så måste du nu själv bära på din skändlighet och dina styggelser, säger HERREN.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
Ty så säger Herren, HERREN: Jag har handlat med dig efter dina gärningar, ty du hade ju föraktat eden och brutit förbundet.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
Men jag vill nu tänka på det förbund som jag slöt med dig i din ungdoms dagar, och upprätta med dig ett evigt förbund.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
Då skall du tänka tillbaka på dina vägar och skämmas, när du får taga till dig dina systrar, de större jämte de mindre; ty jag skall giva dem åt dig till döttrar, dock icke för din trohet i förbundet.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
Men jag skall upprätta mitt förbund med dig, och du skall förnimma att jag är HERREN;
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
och så skall du tänka därpå och blygas, så att du av skam icke mer kan upplåta din mun, då när jag förlåter dig allt vad du har gjort, säger Herren, HERREN.