< Ezekiel 16 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Din nou cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
Fiu al omului, fă cunoscute Ierusalimului urâciunile lui;
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
Și spune: Astfel spune Domnul DUMNEZEUL Ierusalimului: Originea ta și nașterea ta [sunt] din țara lui Canaan; tatăl tău [a fost] amorit și mama ta hitită.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
Și [cât despre] nașterea ta, în ziua în care ai fost născută, buricul tău nu s-a tăiat, nici nu ai fost spălată în apă pentru înmuiere; nu ai fost [tratată] deloc cu sare, nici înfășată deloc.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Niciun ochi nu s-a milostivit de tine, pentru a-ți face ceva din acestea, să aibă milă de tine; ci ai fost aruncată în câmp deschis, pentru a fi detestată ființa ta, în ziua în care te-ai născut.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
Și când eu am trecut pe lângă tine și te-am văzut murdărită în propriul tău sânge și ți-am spus [pe când erai] în sângele tău: Trăiește! Da, ți-am spus [pe când erai] în sângele tău: Trăiește!
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
Eu te-am făcut să te înmulțești ca mugurele câmpului și ai crescut și te-ai făcut mare și ai ajuns podoaba podoabelor; sânii [tăi] s-au rotunjit și părul tău a crescut, deși [erai] goală și fără haine.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Acum, după ce am trecut pe lângă tine și te-am privit, iată, timpul tău [era] timpul dragostei; și mi-am întins învelitoarea peste tine și ți-am acoperit goliciunea; da, ți-am jurat și am intrat în legământ cu tine, spune Domnul DUMNEZEU și tu ai devenit a mea.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
Atunci te-am spălat cu apă; da, ți-am spălat în întregime sângele de pe tine și te-am uns cu untdelemn.
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
Te-am îmbrăcat de asemenea cu lucrare brodată și te-am încălțat cu piele de bursuc și te-am încins cu in subțire și te-am acoperit cu mătase.
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
Te-am împodobit de asemenea cu ornamente și ți-am pus brățări la mâini și un lănțișor la gât.
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
Și ți-am pus o bijuterie pe frunte și cercei în urechi și o coroană frumoasă pe cap.
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
Astfel ai fost împodobită cu aur și cu argint și veșmântul tău [era din] in subțire și mătase și lucrare brodată; ai mâncat floarea făinii și miere și untdelemn; și ai fost foarte frumoasă și ai prosperat și ai ajuns o împărăție.
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Și faima ta a mers printre păgâni pentru frumusețea ta, pentru că aceasta [era] desăvârșită prin frumusețea mea, pe care am pus-o peste tine, spune Domnul DUMNEZEU.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
Dar tu te-ai încrezut în frumusețea ta și ai făcut pe curva din cauza faimei tale, și ți-ai turnat curviile la fiecare ce trecea; a lui era [frumusețea ta].
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
Și ai luat din hainele tale și ți-ai împodobit înălțimile tale cu felurite culori și ai făcut pe curva pe ele, [astfel de lucruri] nu se vor [mai] întâmpla, nici nu va mai fi [astfel].
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
Ai luat de asemenea bijuteriile tale frumoase din aurul meu și din argintul meu, pe care ți le dădusem și ți-ai făcut chipuri de bărbați și ai curvit cu ele,
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
Și ai luat hainele tale brodate și le-ai acoperit; și ai pus untdelemnul meu și tămâia mea înaintea lor.
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Mâncarea mea de asemenea, pe care ți-am dat-o, floarea făinii și untdelemn și miere, [cu care] te-am hrănit, și pe ele le-ai pus înaintea lor ca aromă dulce; și [astfel] a fost, spune Domnul DUMNEZEU.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
Mai mult, ai luat pe fiii tăi și pe fiicele tale, pe care mi i-ai născut și pe aceștia i-ai sacrificat lor pentru a fi mâncați. [Este acesta] între curviile tale un lucru mic,
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
De ai ucis și pe copiii mei și i-ai dat ca să îi treci [prin foc] pentru ele?
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
Și în toate urâciunile tale și curviile tale nu ți-ai amintit de zilele tinereții tale, când erai goală și fără haine [și] erai murdărită în sângele tău.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
Și s-a întâmplat după toată stricăciunea ta (vai, vai ție! spune Domnul DUMNEZEU);
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
[Că] ți-ai zidit de asemenea un loc de cinste și ți-ai făcut o înălțime în fiecare stradă.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
Ți-ai zidit înălțimea ta la capul fiecărei căi și ți-ai făcut frumusețea să fie detestată și ți-ai desfăcut picioarele la fiecare ce trecea și ți-ai înmulțit curviile.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
De asemenea ai curvit cu egiptenii vecinii tăi, mari la carne; și ți-ai înmulțit curviile pentru a mă provoca la mânie.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Iată, de aceea mi-am întins mâna asupra ta și ți-am micșorat [hrana] rânduită și te-am dat în voia celor care te urăsc, fiicelor filistenilor, care sunt rușinate de calea ta desfrânată.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
Ai făcut de asemenea pe curva cu asirienii, pentru că erai nesățioasă; da, ai făcut pe curva cu ei și totuși nu ai putut fi satisfăcută.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
Mai mult, ți-ai înmulțit curvia în țara lui Canaan până în Caldeea; și totuși nu ai fost satisfăcută cu aceasta.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
Cât de slabă este inima ta, spune Domnul DUMNEZEU, văzând că faci toate acestea, lucrarea unei femei curve trufașă;
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
În aceea că îți zidești un loc de cinste la capul fiecărei căi și îți faci înălțime în fiecare stradă; și nu ai fost ca o curvă, în aceea că tu batjocorești plata;
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
[Ci ca] o soție care comite adulter, [care] ia pe străini în locul soțului ei!
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Ei dau daruri tuturor curvelor; dar tu dai darurile tale tuturor iubiților tăi și îi plătești, ca ei să vină la tine din toate părțile pentru curvia ta.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
Și tu ești altfel în curviile tale față de [alte] femei, prin aceea că nimeni nu te urmează ca să curvească; ci în aceea că tu dai o răsplată și nicio răsplată nu îți este dată ție, de aceea tu ești altfel.
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
De aceea, curvă, ascultă cuvântul DOMNULUI;
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Pentru că murdăria ta a fost turnată afară și goliciunea ta descoperită prin curviile tale cu iubiții tăi și cu toți idolii urâciunilor tale și prin sângele copiilor tăi, pe care i-ai dat lor;
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
Iată, de aceea voi aduna pe toți iubiții tăi cu care ai avut plăcere și pe toți [cei] care i-ai iubit, cu toți [cei] pe care i-ai urât; îi voi aduna de jur împrejur împotriva ta și îți voi descoperi goliciunea înaintea lor, încât ei să vadă toată goliciunea ta.
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
Și te voi judeca, cum sunt judecate femeile care comit adulter și care varsă sânge; și îți voi da sânge în furie și gelozie.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
Și te voi da de asemenea în mâna lor și ei îți vor dărâma locul tău de cinste și îți vor sfărâma înălțimile; te vor dezbrăca de asemenea de hainele tale și îți vor lua bijuteriile tale frumoase și te vor lăsa goală și fără haine.
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
Ei vor aduce de asemenea o ceată împotriva ta și te vor ucide cu pietre și te vor străpunge cu săbiile lor.
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
Și îți vor arde casele cu foc și vor face judecăți asupra ta înaintea ochilor multor femei; și te voi face să încetezi a mai face pe curva și de asemenea nu vei mai da vreo plată.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
Astfel voi face ca furia mea împotriva ta să se odihnească și gelozia mea se va depărta de la tine și voi fi liniștit și nu mă voi mai mânia.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
Pentru că nu ți-ai amintit de zilele tinereții tale, ci m-ai provocat în toate acestea; iată, de aceea și eu îți voi întoarce calea ta asupra capului [tău], spune Domnul DUMNEZEU; și nu vei [mai] face această desfrânare deasupra tuturor urâciunilor tale.
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
Iată, oricine folosește proverbe va folosi [acest] proverb împotriva ta, spunând: [Precum este] mama, [astfel este] fiica ei.
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
Tu [ești] fiica mamei tale, care detestă pe soțul ei și pe copiii ei; și [ești] sora surorilor tale, care au detestat pe soții lor și pe copiii lor; mama voastră [a fost] hitită și tatăl vostru amorit.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
Și sora ta mai mare [este] Samaria, ea și fiicele ei care locuiesc la stânga ta; și sora ta mai tânără care locuiește la dreapta ta, [este] Sodoma și fiicele ei.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Totuși tu nu ai umblat după căile lor, nici nu ai lucrat după urâciunile lor; ci, ca și [cum acesta ar fi fost] un [lucru] foarte mic, tu ai fost mai coruptă decât ele în toate căile tale.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
[Precum] eu trăiesc, spune Domnul DUMNEZEU, sora ta Sodoma nu a făcut, nici ea nici fiicele ei, precum ai făcut tu și fiicele tale.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
Iată, aceasta a fost nelegiuirea surorii tale Sodoma: mândrie, plinătate de pâine și abundență de lenevie erau în ea și în fiicele ei; și nu a întărit mâna celui sărac și nevoiaș.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Și ele au fost trufașe și au lucrat urâciune înaintea mea; de aceea le-am îndepărtat precum mi s-a părut [bine].
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Nici Samaria nu a făcut [nici] jumătate din păcatele tale, dar tu ți-ai înmulțit urâciunile tale mai mult decât ele și ai declarat drepte pe surorile tale în toate urâciunile tale pe care le-ai făcut.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
Tu de asemenea, care ai judecat pe surorile tale, poartă-ți propria ta rușine pentru păcatele tale pe care le-ai făcut mai urâcios decât ele, ele sunt mai drepte decât tine; da, fii de asemenea încurcată și poartă-ți rușinea, în aceea că tu le-ai declarat drepte pe surorile tale.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
Când voi întoarce din nou pe captivii lor, captivii Sodomei și a fiicelor ei și captivii Samariei și a fiicelor ei, atunci [voi întoarce din nou] pe captivii captivității tale în mijlocul lor;
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
Ca să îți porți propria ta rușine și să fii încurcată în tot ce ai făcut, în aceea că ești o mângâiere pentru ele.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Când surorile tale, Sodoma și fiicele ei, se vor întoarce la starea lor dinainte și Samaria și fiicele ei se vor întoarce la starea lor dinainte, atunci [și] tu și fiicele tale vă veți întoarce la starea voastră dinainte.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
Pentru că sora ta Sodoma nu a fost menționată de gura ta în ziua mândriei tale,
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
Înainte ca stricăciunea ta să se descopere, ca pe timpul ocărârii [tale] a fiicelor Siriei și a tuturor [celor ce sunt] de jur împrejurul ei, fiicele filistenilor, care te disprețuiesc de jur împrejur.
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
Tu ți-ai purtat desfrânarea și urâciunile tale, spune DOMNUL.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
Pentru că astfel spune Domnul DUMNEZEU: Mă voi purta cu tine precum te-ai purtat [cu alții], tu care ai disprețuit jurământul călcând legământul.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
Totuși eu îmi voi aminti de legământul meu cu tine în zilele tinereții tale și voi întemeia pentru tine un legământ veșnic.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
Atunci îți vei aminti de căile tale și vei fi rușinată, când le vei primi pe surorile tale, pe cele mai mari și pe cele mai tinere; și ți le voi da ca fiice, dar nu prin legământul tău.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
Și eu voi întemeia legământul meu cu tine și vei ști că eu [sunt] DOMNUL;
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ca să îți amintești și să fii încurcată și niciodată să nu îți mai deschizi gura din cauza rușinii tale, după ce eu mă voi fi potolit față de tine pentru tot ce ai făcut, spune Domnul DUMNEZEU.

< Ezekiel 16 >