< Ezekiel 16 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
I stało się słowo Pańskie do mnie, mówiąc:
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
Synu człowieczy! oznajmij Jeruzalemowi obrzydliwości jego, i rzecz:
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
Tak mówi panujący Pan do córki Jeruzalemskiej: Obcowanie twoje i ród twój jest z ziemi Chananejskiej; ojciec twój jest Amorejczyk, a matka twoja Hetejka.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
A narodzenie twoje takie: W dzień, któregoś się urodziła, nie urzniono pępka twego, i wodą cię nie obmyto dla ochędożenia, ani cię solą posolono, ani w pieluchy uwiniono.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Nie zlitowało się nad tobą oko, abyć uczyniło jedno z tych, ulitowawszy się ciebie; ale cię porzucono na polu, przeto, żeś była obmierzła w dzień, któregoś się urodziła.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
A idąc mimo cię, i widząc cię ku podeptaniu podaną we krwi twojej, rzekłem ci: Żyj we krwi twojej; rzekłem ci, mówię: Żyj we krwi twojej.
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
Rozmnożyłem cię na tysiące, jako urodzaj polny, i rozmnożonaś, i stałaś się wielką, a przyszłaś do bardzo wielkiej ozdoby; piersi twoje odęły się, a włosy twoje urosły, chociażeś była naga i odkryta.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Prztoż idąc mimo cię, a widząc cię, że oto czas twój, czas miłości, rozciągnąłem podołek mój na cię, i nakryłem nagość twoję, i obowiązałem ci się przysięgą, a wszedłem w przymierze z tobą, mówi panujący Pan, i stałaś się moją.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
I omyłem cię wodą, a spłukawszy krew twoję z ciebie, pomazałem cię olejkiem;
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
Nadto przyodziałem cię szatą haftowaną, i obułem cię w kosztowne trzewiki, i opasałem cię bisiorem, a przyodziałem cię szatą jedwabną;
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
I przybrałem cię w ochędostwo, a dałem manele na ręce twoje, i łańcuch złoty na szyję twoję;
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
Dałem też naczelnik na czoło twoje, a nausznice na uszy twoje, i koronę ozdobną na głowę twoję;
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
A tak byłaś ozdobiona złotem i srebrem, a odzienie twoje było bisior, i szata jedwabna, i haftowana; jadałaś bułkę i miód, i oliwę, a byłaś nader piękną, i szczęśliwieć się powodziło w królestwie,
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Tak, że się rozeszła powieść o tobie między narodami dla piękności twojej; boś doskonałą była dla sławy mojej, którąm był włożył na cię, mówi panujący Pan.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
Aleś ufała w piękności twojej, i płodziłaś nierząd, będąc tak sławną; boś płodziła nierząd z każdym mimo cię idącym, każdy snadnie użył piękności twojej.
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
A nabrwaszy szat swoich naczyniłaś sobie wyżyn rozmaitych farb, a płodziłaś nierząd przy nich, któremu podobny nigdy nie przyjdzie, ani będzie.
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
Nadto nabrawszy klejnotów ozdoby swojej ze złota mego i z srebra mego, którem ci był dał, naczyniłaś sobie obrazów pogłowia męskiego, i płodziłaś z nimi nierząd.
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
Wzięłaś też szaty swe haftowane, a przyodziałaś je, olejek mój i kadzidło moje kładłaś przed nie;
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Nawet i chleb mój, którem ci dał, bułkę i oliwę, i miód, którymem cię karmił, kładłaś przed nie na wonność przyjemną, i było tak, mówi panujący Pan.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
Brałaś też synów swoich, i córki swoje, którycheś mi narodziła, a oneś im ofiarowała ku pożarciu; izali to jeszcze małe wszeteczeństwa twoje?
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
Do tego i synóweś moich zabijała, a dawałaś ich, aby ich przenoszono przez ogień im kwoli.
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
Nadto przy wszystkich obrzydliwościach swoich, i wszeteczeństwach swoich nie pamiętałaś na dni młodości twojej, gdyś była nagą i odkrytą, podaną na podeptanie we krwi twojej.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
Nadto mimo wszystkich onych złości twoich (Biada, biada tobie! mówi panujący Pan.)
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
Zbudowałaś sobie dom nierządny, i wystawiłaś sobie wyżynę w każdej ulicy.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
Po wszystkich rozstaniach dróg pobudowałaś wyżyny swoje, a uczyniłaś obmierzłą piękność swoję, rozkładając nogi swoje każdemu mimo idącemu, i rozmnożyłaś wszeteczeństwa swoje.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
Boś nierząd płodziła z synami Egipskimi, sąsiadami twymi wielkich ciał, a rozmnożyłaś wszeteczeństwa twe, abyś mię do gniewu pobudzała.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Przetoż otom wyciągnął rękę moję na cię, a uminiejszyłem obroku twego, i podałem cię na wolę nienawidzących cię córek Filistyńskich, które się wstydzą za złe drogi twoje.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
Nadto płodziłaś nierząd z synami Assyryjskimi, przeto, żeś się nie mogła nasycić, a nierząd płodząc z nimi, i takeś się nie nasyciła.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
A tak rozmnożyłaś wszeteczeństwo swe w ziemi Chananejskiej i Chaldejskiej, a i tak nie nasyciłaś się.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
O jako jest zmamione serce twoje! mówi panujący Pan, ponieważ się dopuszczasz tych postępków niewiasty nierządnej i wszetecznej.
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
Budując sobie nierządne domy na rozstaniu każdego gościńca, a wyżynę sobie stawiając w każdej ulicy, owszem pogardzając zapłatą nie jesteś ani jako wszetecznica,
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
Ani jako niewiasta cudzołożąca, która mimo męża swego obcych przypuszcza.
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Wszystkim wszetecznicom dawają zapłatę; aleś ty dawała zapłatę swoję wszystkim zalotnikom twoim, i dawałaś im upominki, aby chodzili do ciebie zewsząd na wszeteczeństwa z tobą.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
A tak znajduje się przy tobie przeciwna rzecz od innych niewiast we wszeteczeństwach twoich, ponieważ cię dla wszeteczeństwa nie szukają; ale ty dajesz zapłatę, a nie tobie zapłatę dawają, co się opak dzieje.
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Przetoż, o wszetecznico! słuchaj słowa Pańskiego.
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Tak mówi panujący Pan: Dlatego, iż się wylała sprośność twoja, i odkryła się nagość twoja we wszeteczeństwach twoich z zalotnikami twoimi i ze wszystkimi plugawemi bałwanami obrzydliwości twoich, i dla rozlania krwi synów twoich, którycheś im dał a.
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
Przetoż oto Ja zgromadzę wszystkich zalotników twoich, z którymiś obcowała, i wszystkich, którycheś miłowała, ze wszystkimi, coś ich nienawidziała, i zgromadzę ich przeciwko tobie zewsząd, i odkryję nagość twoję przed nimi, aby widzieli wszystkę na gość twoję;
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
I osądzę cię sądem cudzołożnic i krew rozlewających, i podam cię na śmierć gniewu i zapalczywości.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
Bo cię podam w ręce ich, i zburzą dom twój nierządny, a rozrzucą wyżyny twoje, i zewloką cię z szaty twojej, i pobiorą klejnoty ozdoby twojej, i zostawią cię nagą i odkrytą;
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
I przywiodą na cię gromadę, i ukamionują cię kamieniem, i przebiją cię mieczami swemi;
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
I popalą domy twoje ogniem, a uczynią nad tobą sąd przed oczyma wielu niewiast. A tak uczynię wstręt wszeteczeństwu twemu, i nie będziesz więcej dawała zapłaty.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
A tak odpocznie sobie gniew mój na tobie, i odstąpi zapalczywość moja od ciebie, i uspokoję się, a nie będę się więcej gniewał.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
Dlatego, żeś nie pamiętała na dni młodości twojej, aleś mię tem wszystkiem draźniła, przetoż oto i Ja obróciłem drogę twoję na głowę twoję, mówi panujący Pan, tak, że nie będziesz nierządu płodziła, ani jakich obrzydliwości swoich.
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
Oto ktokolwiek przez przypowieści mówi, na cię przypowieści obróci, mówiąc: Jaka matka, taka córka jej.
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
Córką matki twojej jesteś, która sobie zbrzydziła męża swego i dziatki swoje; a siostrą obu sióstr swoich jesteś, które sobie zbrzydziły mężów swoich i dziatki swoje. Matka wasza jest Hetejka, a ojciec wasz Amorejczyk.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
Ale siostra twoja starsza, która siedzi po lewicy twojej, jest Samaryja i córki jej; a siostra twoja młodsza niż ty, która siedzi po prawicy twojej, jest Sodoma i córki jej.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Aczkolwiekeś po drogach ich nie chodziła, aniś według obrzydliwości ich czyniła, obrzydziwszy to sobie jako rzecz małą, przecięś się bardziej niż one popsowała na wszystkich drogach twoich.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
Jako żyję Ja, mówi panujący Pan, że Sodoma siostra twoja i córki jej nie czyniły, jakoś ty czyniła i córki twoje.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
Oto ta była nieprawość Sodomy, siostry twojej, pycha, sytość chleba, i obfitość pokoju; co ona mając i córki jej, ręki jednak ubogiego i nędznego nie posilała.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Owszem, wyniósłszy się, czyniły obrzydliwość przed obliczem mojem; przetożem je zniósł, jako mi się zdało.
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Samaryja także ani połowy grzechów twoich nie grzeszyła; boś rozmnożyła obrzydliwości twoje nad nią; a tak usprawiedliwiłaś siostry twoje obrzydliwościami twojemi, któreś czyniła.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
Ponośże i ty hańbę swoję, którąś przysądziła siostrom swoim, dla grzechów swych, któremiś obrzydliwości czyniła bardziej niż one, sprawiedliwszemić były niżeli ty; i ty, mówię, zawstydź się, a noś na sobie hańbę swoję, gdyżeś usprawiedliwiła sios try twoje.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
Przywrócęli zaż więźniów ich, to jest, więźniów Sodomy i córek jej, i więźniów Samaryji i córek jej; tedyć też przywiodę pojmanych więźniów twoich w pośrodku ich;
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
Abyś tak nosiła hańbę twoję, a wstydziła się za wszystko, coś czyniła, a tak abyś je ucieszyła.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Jeźliżeć siostry twoje, Sodoma i córki jej, wrócą się do pierwszego stanu swego, także Samaryja i córki jej wrócą się do pierwszego stanu swego; tedy się też i ty z córkami swemi nawrócisz do pierwszego stanu swego.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
Ponieważ Sodoma siostra twoja nie była powieścią w ustach twoich w dzień pychy twojej.
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
Pierwej niż była objawiona złość twoja, jako za czasu oblężenia od córek Syryjskich, i wszystkich, którzy są około nich, córek Filistyńskich, które cię niszczyły ze wszystkich stron.
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
Niecnotę twoję i obrzydliwość twoje ponosisz, mówi Pan.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
Bo tak mówi panujący Pan: Tak uczynię z tobą, jakoś uczyniła, gdyś wzgardziła przysięgą, i złamała przymierze.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
Wszakże wspomnę na przymierze moje z tobą, uczynione za dni młodości twojej, i stwierdzę z tobą przymierze wieczne.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
I wspomnisz na drogi twoje, i zawstydzisz się, gdy przyjmiesz siostry twoje starsze nad cię, i młodsze niż ty, i dam ci je za córki, ale nie według przymierza twego.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
A tak utwierdzę przymierze moje z tobą, a dowiesz się, żem Ja Pan.
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Abyś wspomniała, i zawstydziła się, i nie mogła więcej otworzyć ust dla wstydu swego, gdy cię oczyszczę od wszystkiego, coś czyniła, mówi panujący Pan.

< Ezekiel 16 >