< Ezekiel 16 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
HIKI mai la hoi ka olelo a Iehova ia'u, i mai la,
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
E ke keiki a ke kanaka, e hoike oe ia Ierusalema i kona mau hewa i inainaia;
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
E olelo aku, Ke i mai nei no Iehova ka Haku ia Ierusalema, O kou wahi hanau ai a me kou hanau ana, ma ka aina o Kanaana ia. He Amora kou makuakane, a he Heta kou makuwahine.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
A i kou hanau ana, i ka la i hanau ai oe, aole i okiia kou piko, aole hoi i holoiia me ka wai i maemae; aole hoi oe i hoopaakai iki ia, aole hoi i wahi iki ia.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Aohe maka i aloha ia oe, e hana aku i kahi o keia mau mea nou, e lokomaikai aku ia oe; aka, ua kiolaia'ku oe ma ke kula mawaho, i ka hoowahawahaia o kou kino, i kou la i hanauia'i.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
A maalo ae la au ma ou la, a ike ia oe e paumaele ana i kou koko iho, i aku la au ia oe iloko o kou koko, E ola; oiaio, ua olelo aku au ia oe iloko o kou koko, E ola.
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
Ua hoonui aku au ia oe e like me ka opuu o ke kula, a nui ae nei oe a mahuahua, a hiki oe i ka wa i maikai loa ai ke kino; ua nui na puuwaiu, a ua ulu kou lauoho, aka, ua olohelohe aku la oe, aole i uhiia.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
A i ko'u maalo ana'e ma ou la, a nana aku ia oe, o ko'u manawa, he manawa aloha no ia, a hohola aku au i ke kihi o ko'u kapa maluna, a uhi ae la i kou olohelohe; hoohiki no hoi au nou, a komo hoi iloko o ka berita me oe, wahi a Iehova ka Haku, a lilo mai oe no'u.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
Alaila holoi aku la au ia oe i ka wai; oia, ua holoi lea aku au i kou koko mai ou aku la, a kahinu aku la au ia oe me ka aila.
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
Hoaahu aku la au ia oe me na kapa hoonionioia, a hookamaa aku ia oe me ka ili tahasa, kaei aku la au ia oe me ka olona makalii, a hoouhi ae la ia oe me ke silika.
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
Kahiko aku la au ia oe me na mea e nani ai, a kau aku i na kupee ma kou mau lima, a me ke kaula lei ma kou a-i.
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
A kau aku la au i ke apo ma kou ihu, a me na apopepeiao ma kou mau pepeiao, a me ka leialii nani maluna o kou poo.
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
Kahikoia aku la oe me ke gula a me ke kala, a o kou kapa, he olona, he silika, me ka mea ulana onionioia; a o ka palaoa wali, a me ka meli. a me ka aila kau i ai ai. Nani loa aku la oe, a mahuahua kou pomaikai a aupuni okoa oe.
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Laha aku la kou kaulana iwaena o na lahuikauaka no kou nani; no ka mea, ua hemolele aku la ia no kou nani a'u i kau aku ai maluna ou, wahi a Iehova ka Haku.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
Aka, hilinai iho la oe i kou nani iho, a ua moe kolohe oe no kou kaulana, a ninini aku oe i kou moe kolohe ana maluna o kela mea keia mea e maalo ae ana; nona no ia.
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
A lawe oe i kauwahi o kou mau kapa komo, a kahiko aku la i kou mau wahi kiekie me ka onionio, a malaila i moe kolohe ai oe; aole e hiki hou, aole hoi pela.
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
A ua lawe oe i kauwahi o kou mau mea nani o ko'u gula a me kuu kala, a'u i haawi aku ai ia oe, a hana aku oe i mau kii o na kanaka nou, a moe kolohe aku me lakou.
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
A lawe ae la hoi oe i kou mau kapa onionio a hoouhi aku ia lakou. A ua hoonoho oe i ko'u aila a me ka'u mea ala imua o lakou.
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
O ka'u ai hoi a'u i haawi aku ai ia oe, ka palaoa wali, ka aila a me ka meli a'u i hauai ai ia oe, oia kau i hoonoho ai imua o lakou i mea ala ono: pela io no hoi, wahi a Iehova ka Haku.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
A ua lawe hoi oe i kau mau keikikane, a me kau mau kaikamahine au i hanau ai na'u, a o lakou kau i kaumaha ai no lakou e pau i ka aiia. He mea uuku anei keia o kou moe kolohe ana?
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
Ua pepehi aku no oe i ka'u mau keiki, a ua hookuu ia lakou e hoohele mawaena o ke ahi no lakou.
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
A iloko o kou mau mea inainaia a me kou moe kolohe ana, aole oe i hoomanao i na la o kou opiopio ana, i kou olohelohe ana, a me ka uhi ole ia, a me kou paumaele ana iloko o kou koko.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
Eia hoi keia mahope iho o kau hana hewa ana a pau, (Auwe, auwe oe! wahi a Iehova ka Haku; )
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
Ua hana aku hoi oe i hale hookamakama nou, a hana hoi oe i wahi kiekie ma kela alanui a me keia alanui.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
Ma kela poo, keia poo o ke ala, ua hana oe i wahi kiekie nou, ua hoolilo oe i kou nani i mea e hoowahawahaia. Ua wehe ae oe i kou mau wawae i kela mea keia mea i maalo ae. A hoonui hoi i kou moe kolohe ana.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
Ua moe kolohe oe me ko Aigupita kou mau hoalauna, kapoe io nui; a ua hoomahuahua i kou moe kolohe ana e hoonaukiuki mai ia'u.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Nolaila hoi, ea, ua kikoo aku au i ko'u lima maluna ou, a ua hoemi au i kau ai, a ua haawi aku au ia oe i ka makemake o ka poe inaina ia oe, i na kaikamahine o ko Pilisetia, na mea i hilahila i kou aoao moe kolohe.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
A ua moe kolohe no hoi oe me ko Asuria, no kou ana ole ana; a ua moe kolohe oe me lakou, aole hoi oe i ana.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
Ua hoonui hoi oe i kou moe kolohe ana ma ka aina o Kanaana a hiki i Kaledea, aole nae oe i ana ilaila.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
Pehea ka nawaliwali o kou naau? wahi a Iehova ka Haku, i kau hana ana ia mau mea, i ka hana a ka wahine moe kolohe hilahila ole;
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
I kau hana i kou hale hookamakama ma ke poo o na kuamoo a pau, a hana hoi i wahi kiekie nou ma na alanui a pau; aole me he wahine hookamakama la, no kou hoowahawaha ana i ka uku;
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
Aka, me he wahine mare la e moe kolohe ana, e lalau ana i na kanaka e, aole i kana kane ponoi!
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Ua haawi lakou i na makana i na wahine hookamakama a pau; aka, ua haawi oe i kau mau makana i kau mau ipo a pau, ua hoolimalima oe ia lakou, e hele mai iou la ma kela aoao keia aoao, no kou moe kolohe ana.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
He mea e iloko ou, i kou moe kolohe ana, okoa na wahine e no ka hahai ole o kekahi ia oe e moe kolohe; a no kou haawi ana i ka uku, aole hoi uku i haawiia nou; nolaila he mea e oe.
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
Nolaila, e ka wahine moe kolohe, e hoolohe i ka olelo a Iehova;
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Ke i mai nei Iehova ka Haku penei; No ka nininiia o kou kala keleawe, a me ka hoikeia o kou olohelohe ana, ma kou moe kolohe ana me kau mau ipo, a me ua akua kii a pau o kou mau mea inainaia, ma ke koko o kau mau keiki au i haawi ai ia lakou.
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
Nolaila, ea, e hoakoakoa au i kau mau ipo i lealea pu ai oe, a me ka poe a pau au i makemake ai, a me ka poe a pau au i hoowahawaha ai; e hoakoakoa au ia lakou e ku e ia oe a puni, a e hoike i kou olohelohe ia lakou, a e ike lakou i kou olohelohe a pau.
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
A e hoopai aku au ia oe e like me ka hoopaiia o na wahine i uhaki i ka berita mare me ka hookahe koko; a e haawi au ia oe i ke koko o ka ukiuki a me ka lili.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
A e haawi aku au ia oe iloko o ko lakou lima, a e hoohiolo lakou i kou hale hookamakama, e wawahi hoi i kou mau wahi kiekie: a e kaili aku lakou i kou mau kapa ko mo mai ou aku la, a e lawe aku hoi i kau mau mea nani, a e waiho ia oe e olohelohe ana me ka uhi ole ia.
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
E lawe mai lakou i ka aha kanaka ku e ia oe, a e hailuku lakou ia oe me na pohaku, a e hou ia oe me ka lakou mau pahikaua.
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
A e puhi lakou i kou mau hale i ke ahi, a e hooili i ka hoopai ana maluna ou imua o na wahine he nui no: a e hooki au i kou moe kolohe ana, aole hoi e haawi hou oe i ka uku.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
Pela e hoomaha ai au i ko'u ukiuki ia oe, a e haalele ko'u lili ia oe, a e noho malie au aole e huhu hou.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
No ka mea, aole oe i hoomanao i na la o kou opiopio ana, a ua hoonaukiuki mai oe ia'u ma keia mau mea a pau: e uku aku au ea, i kou aoao, maluna o kou poo, wahi a Iehova ka Haku; aole hoi oe e hookui i keia hana haumia maluna o kau mau mea inainaia a pau.
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
Eia hoi, o na mea a pau e olelo ana ma na olelo nane, e lawe lakou i keia olelo nane nau, e i ana, E like me ka makuwahine, pela no kana kaikamahine.
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
O ke kaikamahine no oe a kou makuwahine i hoowahawaha i kana kane a me kana mau keiki; o ka hoahanauwahine oe o kou mau hoahanauwahine i hoowahawaha i ka lakou mau kane mo ka lakou mau keiki; o kou makuwahine, o ka Heta no ia: o kou makuakaue, o ka Amora no ia.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
A o kou kaikuaana, o Samaria ia, oia me kana mau kaikamahine e noho ana ma kou lima hema. A o kou kaikaina e noho ana ma kou lima akau, oia o Sodoma a me kana mau kaikamahine.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Aole nae oe i hele ma ko lakou mau aoao, aole hoi i hana mamuli o ko lakou mau mea inainaia; aka, me he mea uuku la, ua oi aku kou haumia ana mamua o ko lakou i kou mau aoao a pau.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
Ma ko'u ola ana, wahi a Iehova ka Haku, aole o Sodoma i hana, oia, aole hoi kana mau kaikamahine, e like me oe i hana ai, o oe a me kau mau kaikamahine.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
Eia hoi ka hewa o kou kaikaina, o Sodoma, o ka haaheo, o ka piha loa i ka berena, a o ka palaualelo nui wale ka iloko ona a me kana mau kaikamahine; aole nae ia i hooikaika i ka lima o ka mea ilihune a me ka nele.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Ua hookiekie lakou, a ua hana i na mea inainaia imua o'u; nolaila lawe ae la au ia lakou mamuli o ko'u ike ana he pono.
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Aole hoi i hana o Samaria i ka hapalua o kou mau hewa; ua hoonui aku oe i kou mau mea inainaia i ko lakou, a ua hoapono oe i kou mau hoahanau wahine, ma kou mau mea inainaia a pau au i hana'i.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
A o oe hoi ka mea i hooponopono i kou mau hoahanau wahine, e hali oe i kou hoinoia, no kou mau hewa au i hana aku ai i pakela aku i ko lakou; ua oi aku ko lakou pono i kou; oia, e hilahila hoi oe, a e hali oe i kou hoinoia, no kou hoapono ana i kou mau hoahanau wahine.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
Aia hoihoi mai au i ko lakou pio ana, i ke pio ana o Sodoma a me kana mau kaikamahine, a me ke pio ana o Samaria a me kana mau kaikamahine, alaila, i ke pio ana o kou poe pio iwaena o lakou;
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
I hali oe i kou hoinoia, a e hilahila hoi oe i na mea a pau au i hanaai, i kou hooluolu ana ia lakou.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Aia i hoi kou mau hoahanau wahine o Sodoma a me kana mau kaikamahine, i ko lakou noho kahiko ana, a hoi mai hoi o Samaria a me kana mau kaikamahine i ko lakou noho kahiko ana, alaila e hoi oe me kau mau kaikamahine i ko oukou noho kahiko ana.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
No ka mea, aole oleloia o Sodoma kou kaikaina e ko'u waha, i ka la o kou haaheo ana,
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
Mamua o ka hoikeikeia'na o kou hewa, i ka wa i hoinoia'i na kaikamahine a Suria, a me na mea a pau e kokoke mai ana a puni ia, na kaikamahine a Pilisetia na mea i hoowahawaha ia oe ma kela aoao keia aoao.
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
O kou hewa a me kou mau mea inainaia, oia kau i hali ai, wahi a Iehova.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
No ka mea, ke i mai nei Iehova ka Haku, penei; E hana aku au ia oe e like me ka hana ana au a ka mea hoowahawaha i ka hoohiki ana, a i uhai hoi i ka berita.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
Aka hoi, e hoomanao aku no au i kuu berita a'u i hana pu ai me oe i na la o kou opiopio ana, a e hoomau aku no au nou i berita mau loa.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
Alaila e hoomanao oe i kou mau aoao, a e hilahila no hoi i ka wa e loaa ai ia oe kou mau hoahanau wahine, kou kaikuaana a me kou kaikaina; a e haawi aku au ia laua ia oe i mau kaikamahine, aole hoi ma kou berita.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
A e hoomau au i kuu berita me oe; a e ike no oe, owau no Iehova;
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
I hoomanao hoi oe, a e hilahila hoi, aole loa e ekemu hou kou waha no kou hilahila, i ka wa e laulea hou ai au ia oe i na mea a pau au i hana mai ai, wahi a Iehova ka Haku.