< Ezekiel 16 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Kiugo kĩa Jehova nĩkĩanginyĩrĩire, ngĩĩrwo atĩrĩ,
2 “Ọmọ ènìyàn, mú kí Jerusalẹmu mọ gbogbo ìwà ìríra rẹ̀.
“Mũrũ wa mũndũ, ngʼethanĩra na itũũra rĩa Jerusalemu, ũrĩonie mĩtugo yarĩo ĩyo ĩrĩ magigi,
3 Sọ pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí Jerusalẹmu, ìran rẹ àti ilẹ̀ ìbí rẹ wà ní ilẹ̀ Kenaani; ará Amori ni baba rẹ̀, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ ará Hiti.
uuge atĩrĩ, ‘Ũũ nĩguo Mwathani Jehova areera Jerusalemu: Kĩhumo gĩaku na gũciarwo gwaku cioimanire na bũrũri wa andũ a Kaanani; thoguo aarĩ Mũamori, nake maitũguo aarĩ Mũhiti.
4 Ní ọjọ́ tí a bí ọ, a kò gé okùn ìwọ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fi omi wẹ̀ ọ́ láti mú kí o mọ́, a kò fi iyọ̀ pa ọ́ lára rárá, bẹ́ẹ̀ ni a kò fi aṣọ wé ọ.
Mũthenya ũrĩa waciarirwo-rĩ, ndwatinirio rũrĩra, o na kana ũgĩthambio na maaĩ nĩguo ũthere, o na kana ũkĩhakwo cumbĩ, kana ũgĩthaywo na nguo cia mwana.
5 Kò sí ẹni tó ṣàánú tàbí kẹ́dùn rẹ dé bi à ti ṣe nǹkan kan nínú ìwọ̀nyí fún ọ, ṣùgbọ́n lọ́jọ́ ìbí rẹ, ìta la jù ọ́ sí torí wọ́n kórìíra rẹ.
Gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wakũrorire, agĩkũiguĩra tha, kana agĩgũcaaĩra o kũigana nĩguo agwĩke ũndũ o na ũmwe wa macio. No rĩrĩ, wateirwo na kũu werũ-inĩ, nĩ ũndũ wamenirwo o mũthenya o ro ũcio waciarirwo.
6 “‘Nígbà tí mo sì kọjá tí mo rí ọ tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ, mo sọ fún ọ pé, “Yè!” Nítòótọ́, nígbà tí ìwọ wà nínú ẹ̀jẹ̀ rẹ pé, “Yè.”
“‘Hĩndĩ ĩyo nĩndahĩtũkĩire hau warĩ ngĩkuona ũkĩĩgaragaria thakame-inĩ yaku, na rĩrĩa wakomete hau thakame-inĩ yaku-rĩ, ngĩkwĩra atĩrĩ, “Tũũra muoyo!”
7 Mo mú ọ dàgbà bí ohun ọ̀gbìn inú oko. O ga sókè, o sì dàgbà, o wá di arẹwà jùlọ, ọmú rẹ yọ, irun rẹ gùn, ìwọ tí o wà ní ìhòhò láìfi nǹkan kan bora.
Nĩndatũmire ũkũre o ta mũtĩ wa mũgũnda. Nawe ũgĩkũra, ũkĩneneha, o na ũgĩtuĩka ithaga ithaka mũno gũkĩra marĩa mangĩ. Nyondo ciaku nacio ikĩĩhaanda, na njuĩrĩ yaku ĩgĩkũra, o wee ũrĩa warĩ njaga na ũkaaga nguo.
8 “‘Nígbà tí mo tún kọjá, tí mo rí ọ, mo rí i pé àsìkò àti nífẹ̀ẹ́ rẹ ti tó, mo fi ìṣẹ́tí aṣọ mi bo ìhòhò rẹ. Mo búra fún ọ, èmi sì bá ọ dá májẹ̀mú ìwọ sì di tèmi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
“‘Thuutha ũcio nĩndahĩtũkĩire hau, na rĩrĩa ndaakũrorire ngĩona atĩ warĩ mũgima wa kwendeka, ngĩgũtambũrũkĩria gĩcũrĩ kĩa nguo yakwa, ngĩhumbĩra njaga yaku. Na niĩ ngĩkwĩhĩtĩra mwĩhĩtwa mũrũmu, na tũkĩgĩa kĩrĩkanĩro nawe, ũgĩtuĩka wakwa, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
9 “‘Nígbà náà ni mo fi omi wẹ ẹ̀jẹ̀ kúrò ní ara rẹ, mo fi ìpara pa ọ́ lára.
“‘Nĩndagũthambirie na maaĩ, ngĩkũgiria thakame, na ngĩkũhaka maguta.
10 Mo fi aṣọ oníṣẹ́-ọnà sí ọ lára láti wọ̀ ọ́, mo wọ bàtà aláwọ fún ọ. Mo fi aṣọ funfun gbòò àti aṣọ olówó iyebíye ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́.
Nĩndakũhumbire nguo ngʼemie na ngĩgwĩkĩra nyamũga cia rũũa. Nĩndakũhumbire nguo njega ya gatani na ngĩkũhumba nguo cia goro.
11 Mo fi ohun ọ̀ṣọ́ ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́, mo fi ẹ̀gbà ọwọ́ sí ọ ní ọwọ́, mo fi ìlẹ̀kẹ̀ ọrùn sí ọ ní ọrùn,
Nĩndakũgemirie na mathaga: ngĩgwĩkĩra bangiri moko, na mũgathĩ ngingo,
12 mo sì tún fi òrùka sí ọ ní imú, mo fi yẹtí sí ọ ní etí, mo sì fi adé tó rẹwà dé ọ ní orí.
ngĩcooka ngĩgwĩkĩra gĩcũhĩ iniũrũ, na icũhĩ matũ, na tanji thaka mũtwe.
13 Báyìí ni mo ṣe ọ́ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú wúrà àti fàdákà; tí aṣọ rẹ jẹ́ funfun gbòò, aṣọ olówó iyebíye àti aṣọ tí a ṣiṣẹ́ ọnà sí. Ìyẹ̀fun kíkúnná, oyin àti òróró ni oúnjẹ rẹ. Ó di arẹwà títí ó fi dé ipò ayaba.
Nĩ ũndũ ũcio ũkĩgemio na thahabu na betha: nacio nguo ciaku ciarĩ cia gatani ĩrĩa njega, na itambaya cia goro, na nguo ngʼemie. Irio ciaku ciarĩ mũtu mũhinyu, na ũũkĩ, na maguta ma mũtamaiyũ. Wee nawe ũgĩthakara mũno na ũkĩambatĩrio ũgĩtuĩka mũthamaki-mũndũ-wa-nja.
14 Òkìkí rẹ sì kàn káàkiri orílẹ̀-èdè nítorí ẹwà rẹ, nítorí dídán tí mo fi ṣe ẹwà rẹ ní àṣepé, ni Olúwa Olódùmarè wí.
Nayo ngumo yaku ĩgĩtheerema ndũrĩrĩ-inĩ nĩ ũndũ wa ũthaka waku, nĩ ũndũ riiri ũrĩa ndaagwĩkĩrĩte nĩwatũmire ũthaka waku wagĩrĩre kũna, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.
15 “‘Ṣùgbọ́n, ìwọ gbẹ́kẹ̀lé ẹwà rẹ, ìwọ sì di alágbèrè nítorí òkìkí rẹ. Ìwọ sì fọ́n ojúrere rẹ káàkiri sí orí ẹni yówù tó ń kọjá lọ, ẹwà rẹ sì di tìrẹ.
“‘No rĩrĩ, wee nĩwehokire ũthaka waku, na ũkĩhũthĩra ngumo yaku ĩgĩtũma ũtuĩke mũmaraya. Nĩwahũũrire ũmaraya na mwĩhĩtũkĩri o wothe, naguo ũthaka waku ũgĩtuĩka wake.
16 Ìwọ mú lára àwọn aṣọ rẹ, láti rán aṣọ aláràbarà fún ibi gíga òrìṣà tí ìwọ ti ń ṣe àgbèrè. Èyí kò yẹ kí ó rí bẹ́ẹ̀, tàbí kó tilẹ̀ ṣẹlẹ̀ rárá.
Woire nguo imwe ciaku, ũkĩgemia mahooero ma kũndũ gũtũũgĩru kũrĩa wahũũragĩra ũmaraya. Maũndũ ta macio matiagĩrĩirwo nĩ gwĩkĩka, kana magĩe kuo o na rĩ.
17 Ìwọ tún mú àwọn ohun ọ̀ṣọ́ dáradára tí mo fi wúrà àti fàdákà ṣe fún ọ láti fi yá ère ọkùnrin tí ó ń bá ọ ṣe àgbèrè papọ̀.
Ningĩ ũgĩcooka ũkĩoya mathaga macio mega ndaakũheire, o mathaga macio mathondeketwo na thahabu yakwa na betha yakwa, ũgĩĩthondekera mĩhianano ya arũme, ũgĩcooka ũkĩhũũra ũmaraya nayo.
18 Ìwọ sì wọ aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ rẹ fún wọn, o sì tún gbé òróró àti tùràrí mi sílẹ̀ níwájú wọn.
Ningĩ ũkĩoya nguo icio ciaku ciarĩ ngʼemie, ũgĩcihumba mĩhianano ĩyo, ũgĩcooka ũkĩmĩrutĩra maguta makwa na ũbumba.
19 Ìwọ tún gbé oúnjẹ tí mo fún ọ—ìyẹ̀fun dáradára, òróró àti oyin—fún wọn gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun olóòórùn dídùn; ohun tó ṣẹlẹ̀ nìyìí, ni Olúwa Olódùmarè wí.
O nacio irio iria ndaakũheete ũrĩe, nacio nĩ mũtu mũhinyu, na maguta ma mũtamaiyũ, na ũũkĩ, wacirutĩire mĩhianano ĩyo ĩtuĩke ũbumba ũrĩ na mũtararĩko mwega. Ũguo nĩguo gwekĩkire, Mwathani Jehova nĩwe ugĩte ũguo.
20 “‘Àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin tí o bí fún mi lo ti fi rú ẹbọ bí oúnjẹ fún àwọn òrìṣà. Ṣé ìwà àgbèrè rẹ kò ha tó bí?
“‘Na rĩrĩ, woire ariũ na aarĩ aku arĩa wanjiarĩire, ũkĩmaruta igongona matuĩke ta irio cia mĩhianano ĩyo. Ũhũũri waku wa ũmaraya-rĩ, kaĩ ũtaarĩ mũiganu?
21 Tí ìwọ ti pa àwọn ọmọ mí, ìwọ sì fà wọ́n fún ère gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun.
Nĩwathĩnjire ciana ciakwa ũgĩciruta igongona harĩ mĩhianano ĩyo.
22 Nínú gbogbo iṣẹ́ ìríra àti ìwà àgbèrè rẹ, ìwọ kò rántí ìgbà èwe rẹ, nígbà tí ìwọ wà ní ìhòhò, tó ń jàgùdù nínú ẹ̀jẹ̀.’
Mĩtugo-inĩ yaku yothe ĩrĩ magigi ĩrĩa wekire, na ũhũũri-inĩ waku wa ũmaraya, ndwaririkanire matukũ ma ũnini waku, rĩrĩa warĩ njaga na ũtaarĩ na nguo, o rĩrĩa wegaragaragia thakame-inĩ yaku.
23 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Ègbé! Ègbé ni fún ọ. Lẹ́yìn gbogbo ìwà búburú rẹ,
“‘Hĩ, kaĩ ũrĩ na haaro-ĩ! ũguo nĩguo Jehova ekuuga. O na wĩkĩte mawaganu macio mangĩ mothe,
24 ìwọ kọ́lé amọ̀ fún ara rẹ, ìwọ sì kọ́ ojúbọ gíga sí gbogbo òpin ojú pópó.
nĩweyakĩire kĩhumbu, na ũgĩaka ihooero itũũgĩru handũ harĩa hothe haarĩ na kĩhaaro gĩa kũgomanagwo.
25 Ní gbogbo ìkóríta ni ìwọ lọ kọ ojúbọ gíga sí, tí ìwọ sọ ẹwà rẹ di ìkórìíra, ìwọ sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ nípa fífi ara rẹ sílẹ̀ fún gbogbo ẹni tó ń kọjá lọ.
Gĩturi-inĩ kĩa o njĩra nĩweyakĩire mahooero matũũgĩru, na ũkĩagithia ũthaka waku gĩtĩĩo, ũgakĩrĩrĩria kũneana mwĩrĩ waku kũrĩ mwĩhĩtũkĩri o wothe atharie nawe.
26 Ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ará Ejibiti tí í ṣe aládùúgbò rẹ láti mú mi bínú ìwọ sì ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀.
Nĩwahũũrire ũmaraya na andũ a Misiri arĩa mwariganĩtie nao, o acio maiyũrĩtwo nĩ merirĩria ma mwĩrĩ, ũgĩtũma ndakare nĩ ũndũ waku gũkĩrĩrĩria gũtharia.
27 Nítorí náà ni mo fi na ọwọ́ mi lé ọ lórí, mo sì ti bu oúnjẹ rẹ̀ kù; èmi yóò sì mú ìfẹ́ àwọn to kórìíra rẹ ṣẹ́ lé ọ lórí, àwọn ọmọbìnrin Filistini ti ìwàkiwà rẹ tì lójú.
Nĩ ũndũ ũcio ngĩgũtambũrũkĩria guoko ngĩgũũkĩrĩra, ngĩnyiihia bũrũri waku; nĩndakũneanire moko-inĩ ma thũ ciaku, o acio airĩtu a Afilisti, arĩa maamakirio nĩ mĩtugo yaku ya ũũra-thoni.
28 Nítorí àìnítẹ́lọ́rùn rẹ, ìwọ ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú ara Asiria; ìwọ ti bá wọn ṣe àgbèrè, síbẹ̀síbẹ̀, kò sì lè tẹ́ ọ lọ́rùn.
Nĩwahũũrire ũmaraya na andũ a Ashuri o nao, nĩ ũndũ ndũngĩaiganirie; o na thuutha ũcio-rĩ, ndwaiganirie.
29 Ìwọ si ti sọ àgbèrè rẹ di púpọ̀ láti ilẹ̀ Kenaani dé ilẹ̀ Kaldea; síbẹ̀ èyí kò sì tẹ́ ọ lọ́rùn níhìn-ín yìí.’
Ningĩ ũgĩkĩrĩrĩria gũtharia o nginya ũgĩkinya Babuloni, bũrũri wa onjoria, no-o na weka ũguo ndwaiganirie.
30 “Olúwa Olódùmarè wí pé, ‘Báwo ni ọkàn rẹ ṣe jẹ aláìlera tó tí o ń ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí, bí iṣẹ́ àwọn agídí alágbèrè!
“‘Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ, Hĩ! Kaĩ wee ũrĩ wa ngoro hũthũ-ĩ! Wĩkaga maũndũ macio mothe, o ta mũmaraya ũtarĩ thoni!
31 Ni ti pé ìwọ kọ́ ilé gíga rẹ ni gbogbo ìkóríta, tí ìwọ sì ṣe gbogbo ibi gíga rẹ ni gbogbo ìta, ìwọ kò sì wa dàbí panṣágà obìnrin, ní ti pé ìwọ gan ọ̀yà.
Rĩrĩa weyakĩire ihumbu gĩturi-inĩ kĩa o njĩra, na ũkĩĩakĩra mahooero matũũgĩru harĩa hothe haarĩ kĩhaaro gĩa kũgomanwo-rĩ, we wetuire ta ũtarĩ mũmaraya, nĩ ũndũ nĩwaregire irĩhi.
32 “‘Ìwọ alágbèrè aya! Ìwọ fẹ́ràn ọkùnrin àjèjì ju ọkọ rẹ lọ!
“‘Wee mũtumia ũyũ mũtharia! Wee wendaga ageni handũ ha mũthuuriguo!
33 Àwọn ọkùnrin máa ń sanwó fún àwọn panṣágà ni ṣùgbọ́n ìwọ lo tún ń sanwó fun wọn, tí ó tún ń fún àwọn olólùfẹ́ rẹ lẹ́bùn àti owó ẹ̀yìn kí wọn bá à le máa wá ọ wá láti gbogbo agbègbè fún àgbèrè ṣíṣe.
Mũmaraya o wothe nĩamũkagĩra irĩhi, no wee-rĩ, nĩwe ũheaga endwa aku othe iheo, ũkamahaka nĩguo mokage kũrĩ we kuuma kũndũ guothe nĩguo megwatĩre ikeno ciaku itaagĩrĩire.
34 Nínú àgbèrè rẹ ìwọ yàtọ̀ sí àwọn alágbèrè obìnrin yòókù; nínú àgbèrè rẹ tí ẹnìkan kò tẹ̀lé ọ láti ṣe àgbèrè; àti ní ti pé ìwọ ń tọrẹ tí a kò sì tọrẹ fún ọ, nítorí náà ìwọ yàtọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio wee ndũtariĩ ta arĩa angĩ ũmaraya-inĩ waku; gũtirĩ mũndũ ũkwĩringagĩrĩria ũmwĩtĩkĩre. Wee-rĩ, ũrĩ na ũtiganu mũno na arĩa angĩ, nĩgũkorwo wee nĩwe ũrĩhanaga, no gũtirĩ kĩndũ ũrĩhagwo.
35 “‘Nítorí náà, ìwọ alágbèrè, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
“‘Nĩ ũndũ ũcio, wee mũmaraya ũyũ, igua kiugo kĩa Jehova!
36 Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, “Nítorí pé ìwọ tú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ jáde, ìwọ sì fi ìhòhò rẹ hàn, nípa ṣíṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn olólùfẹ́ rẹ, àti nítorí gbogbo òrìṣà ìríra tí o fi ẹ̀jẹ̀ àwọn ọmọ rẹ ṣe ìrúbọ fún,
Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Tondũ nĩwaitangire ũtonga waku, na ũkĩguũria njaga yaku ũgĩtharia na endwa aku, o na tondũ wa mĩhianano ĩyo yothe yaku ĩrĩ magigi, na tondũ nĩwamaheire thakame ya ciana ciaku,
37 nítorí náà, Èmi yóò ṣa gbogbo àwọn olólùfẹ́ rẹ jọ, àwọn ẹni ti ìwọ ti bá jayé àti gbogbo àwọn tí ìwọ ti fẹ́ àti àwọn tí ìwọ kórìíra. Èmi yóò sa gbogbo wọn káàkiri jọ, láti mú wọn lòdì sí ọ, èmi yóò sí aṣọ rẹ, níwájú wọn, wọn yóò sì rí ìhòhò rẹ.
nĩ ũndũ ũcio nĩngũcookanĩrĩria endwa aku othe arĩa wanekenia nao, arĩa wendete o na arĩa ũthũire. Nĩngũmacookanĩrĩria magũũkĩrĩre kuuma mĩena yothe, na niĩ ngũguũrie nguo mbere yao, nao mone njaga yaku yothe.
38 Èmi yóò sì dá ọ lẹ́jọ́, gẹ́gẹ́ bí a ti dá obìnrin tó ba ìgbéyàwó jẹ́, tí wọn sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀; Èmi yóò sì mú ẹ̀jẹ̀ ìbínú àti owú mi wá sórí rẹ.
Nĩngagũtuĩra ciira o ta ũrĩa andũ-a-nja arĩa matharagia na arĩa maitithagia thakame matuuagĩrwo; na ndũme ũkorwo nĩ mangʼũrĩ makwa na ũiguĩrwo ũiru nĩguo ũcookererwo nĩ thakame ĩyo.
39 Nígbà náà ni èmi yóò fà ọ lé àwọn olólùfẹ́ rẹ lọ́wọ́, wọn yóò sì wó gbogbo òkìtì rẹ pẹ̀lú àwọn ojúbọ rẹ palẹ̀. Wọn yóò tú aṣọ kúrò lára rẹ̀, gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ ni wọn yóò gbà, wọn yóò sì fi ọ sílẹ̀ ní ìhòhò àti ní àìwọṣọ.
Ningĩ nĩngakũneana moko-inĩ ma endwa aku, nao nĩmakaharagania ihumbu icio ciaku, na manange mahooero macio maku matũũgĩru. Nao nĩmagakũruta nguo, na moe mathaga maku ma goro, magũtige njaga na ũrĩ ũtheri.
40 Wọn yóò pe àjọ ènìyàn jọ lé ọ lórí, àwọn tí yóò sọ ọ́ ní òkúta, tiwọn yóò sì fi idà wọn gé ọ sí wẹ́wẹ́.
Nĩmakarehe kĩrĩndĩ gĩgũũkĩrĩre, nao nĩmagakũhũũra na mahiga nyuguto, na magũtinangie na hiũ ciao cia njora.
41 Wọn yóò jo gbogbo ilé rẹ palẹ̀ wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ́ ní ojú àwọn obìnrin. Èmi yóò fi òpin sí àgbèrè ṣíṣe rẹ. Ìwọ kò sì ní san owó fún àwọn olólùfẹ́ rẹ mọ́.
Nĩmagacina nyũmba ciaku na makũherithie wĩroreirwo nĩ andũ-a-nja aingĩ. Nĩngakinyia ũmaraya waku mũthia, nawe ndũgacooka kũrĩha endwa acio aku.
42 Nígbà náà ni ìbínú mi sí o yóò rọ̀, owú ìbínú mi yóò sì kúrò lọ́dọ̀ rẹ; inú mi yóò rọ̀, èmi kò sì ní bínú mọ́.”
Hĩndĩ ĩyo mathũgũta makwa ma gũgũũkĩrĩra nĩmakahũahũa, namo marakara makwa maiyũrĩtwo nĩ ũiru makweherere. Nĩngahoorera na ndigacooka kũrakara.
43 “‘Nítorí pé ìwọ kò rántí ọjọ́ èwe rẹ ṣùgbọ́n ìwọ ń rí mi fín pẹ̀lú gbogbo nǹkan wọ̀nyí, ó dájú pé, Èmi yóò mú gbogbo ohun tí ìwọ ti ṣe wa sí orí rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí, ìwọ kì yóò sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ yìí ni orí gbogbo ohun ìríra rẹ mọ́?
“‘Na tondũ ndwaririkanire matukũ ma ũnini waku, no kũndakaria wandakaririe na maũndũ macio mothe-rĩ, ti-itherũ nĩngatũma ũcookererwo nĩ ũrĩa wĩkĩte, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga. Githĩ nduongereire ũũra-thoni harĩ maũndũ marĩa mangĩ wĩkaga marĩ magigi?
44 “‘Gbogbo àwọn to ń pòwe, ni yóò máa pòwe yìí mọ́ ọ pé: “Bí ìyá ṣe rí, bẹ́ẹ̀ ni ọmọ rẹ̀ obìnrin.”
“‘Mũndũ o wothe waragia na thimo-rĩ, nĩagakuuna thimo ĩno, oige atĩrĩ: “O ta ũrĩa nyina ahaana, no taguo mwarĩ ahaana.”
45 Ìwọ ni ọmọ ìyá rẹ ti ó kọ ọkọ rẹ̀, àti àwọn ọmọ rẹ̀; ìwọ ni arábìnrin àwọn arábìnrin rẹ tí ó kọ àwọn ọkọ wọn àti àwọn ọmọ wọn: ara Hiti ni ìyá rẹ, ara Amori sì ni baba rẹ.
Wee ũrĩ mwarĩ wa nyũkwa kũna, ũrĩa wanyararire mũthuuriwe na ciana ciake; na ũrĩ wa nyina kũna na aarĩ a maitũguo, arĩa maanyararire athuuri ao na ciana ciao. Maitũguo aarĩ Mũhiti, nake thoguo aarĩ Mũamori.
46 Ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin ni Samaria, òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ n gbé ni apá àríwá rẹ, àti àbúrò rẹ obìnrin ní ń gbé ọwọ́ òsì rẹ̀, àti àbúrò rẹ obìnrin ti ń gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ ni Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ obìnrin.
Mwarĩ wa nyũkwa ũrĩa mũkũrũ aarĩ Samaria ũrĩa watũũraga mwena waku wa gathigathini marĩ na airĩtu ake; nake mwarĩ wa nyũkwa ũrĩa mũnini aarĩ Sodomu, ũrĩa watũũraga mwena waku wa gũthini hamwe na airĩtu ake.
47 Kì í sẹ pé ìwọ rìn ni ọ̀nà wọn nìkan, tàbí ṣe àfiwé ìwà ìríra wọn ṣùgbọ́n ní àárín àkókò kúkúrú díẹ̀, ìwọ bàjẹ́ jù wọ́n lọ
Wee-rĩ, to gũthiĩ wathiire na mĩthiĩre yao na ũkĩrũmĩrĩra mĩtugo yao ĩrĩ magigi, no mĩthiĩre-inĩ yaku yothe nĩwahiũhire gũthũka kũmakĩra.
48 Olúwa Olódùmarè wí pé, “Bí mo ṣe wà láààyè, Sodomu tí í ṣe ẹ̀gbọ́n rẹ obìnrin àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ kò ṣe to ohun tí ìwọ àti ọmọbìnrin rẹ ṣe.”
Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: Ti-itherũ o ta ũrĩa Niĩ ndũũraga muoyo-rĩ, mwarĩ wa nyũkwa Sodomu na airĩtu ake matiekire ta ũrĩa wee na airĩtu aku mwĩkĩte.
49 “‘Wò ó, ẹ̀ṣẹ̀ tí Sodomu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ obìnrin ṣẹ̀ nìyìí. Òun àti àwọn ọmọbìnrin rẹ gbéraga, wọ́n jẹ́ alájẹjù àti aláìbìkítà; wọn kò ran tálákà àti aláìní lọ́wọ́.
“‘Maya nĩmo maarĩ mehia ma mwarĩ wa nyũkwa Sodomu: We marĩ na airĩtu ake maarĩ andũ etĩĩi, a kwĩhũũnĩrĩria, na matiarũmbũyagia ũhoro wa andũ arĩa angĩ; matiateithirie andũ arĩa athĩĩni o na arĩa abatari.
50 Nítorí náà, mo mu wọn kúrò níwájú mi lójú mi gẹ́gẹ́ bi ìwọ ti rò ó, nítorí ìgbéraga àti àwọn ohun ìríra tí wọ́n ṣe.
Nĩmeĩkĩrĩire na magĩĩka maũndũ marĩ magigi maitho-inĩ makwa. Nĩ ũndũ ũcio nĩndamaingatire, o ta ũguo muonete.
51 Samaria kò ṣe ìdajì ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Ìwọ ṣe àwọn ohun ìríra ju tirẹ̀ lọ, ìwọ sì jẹ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo pẹ̀lú gbogbo ìwọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe.
Samaria ndehirie nuthu ya mehia marĩa wee wehirie. Wee wĩkĩte maũndũ marĩ magigi maingĩ kũmakĩra, na nĩũtũmĩte aarĩ a maitũguo moneke ta marĩ athingu nĩ ũndũ wa maũndũ macio mothe wĩkĩte.
52 Gba ìtìjú rẹ, nítorí ìwọ ti jẹ́ kí arábìnrin rẹ gba ìdáláre. Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ti burú ju tí wọn lọ, wọn dàbí olódodo ju ìwọ lọ. Nítorí náà rú ìtìjú rẹ, kí o sì gba ẹ̀gàn rẹ pẹ̀lú nítorí ìwọ ti jẹ́ kí àwọn arábìnrin rẹ dàbí olódodo.
Ũrokĩrĩrĩria gũconorithio, nĩgũkorwo nĩũtũmĩte aarĩ a maitũguo moneke ta marĩ athingu. Tondũ mehia maku maarĩ mooru gũkĩra mao, o mekuoneka marĩ athingu gũgũkĩra. Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, igua thoni na ũconoke, nĩgũkorwo nĩũtũmĩte aarĩ a nyũkwa moneke marĩ athingu.
53 “‘Bi o tilẹ̀ jẹ pe èmi yóò mú ìgbèkùn wọn padà, ìgbèkùn Sodomu àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, pẹ̀lú Samaria àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin, nígbà náà ni èmi yóò tún mú ìgbèkùn àwọn òǹdè rẹ wá láàrín wọn,
“‘No rĩrĩ, nĩngacookeria Sodomu ũgaacĩru wake marĩ na airĩtu ake, o na Samaria marĩ na airĩtu ake, na nĩngagũcookeria ũgaacĩru waku o hamwe nao,
54 kí ó bá à le rú ìtìjú rẹ, àti ẹ̀gàn gbogbo ohun tí ìwọ ṣe láti tù wọ́n nínú.
nĩguo ũigue thoni na ũconoke nĩ ũndũ wa maũndũ macio mothe wekire nĩ ũndũ wa kũmahe ũhurũko.
55 Nígbà tí àwọn arábìnrin rẹ, Sodomu àti àwọn ọmọbìnrin rẹ; Samaria àti àwọn ọmọbìnrin rẹ ba padà si ipò tí wọn wà tẹ́lẹ̀, ìgbà náà ni ìwọ náà yóò padà sí ipò àtijọ́ rẹ.
Nao aarĩ acio a maitũguo, Sodomu marĩ na airĩtu ake, na Samaria marĩ na airĩtu ake-rĩ, nĩmagacooka o ta ũrĩa maarĩ mbere; nawe ũrĩ na airĩtu aku nĩmũgacooka o ta ũrĩa mwarĩ mbere.
56 Ìwọ ko tilẹ̀ ní dárúkọ arábìnrin rẹ Sodomu ni ọjọ́ ìgbéraga rẹ,
O na ndũngĩagwetire rĩĩtwa rĩa mwarĩ wa nyũkwa Sodomu mũthenya ũcio wetĩĩaga,
57 kó tó di pé àṣírí ìwà búburú rẹ tú síta, báyìí ìwọ di ẹni ẹ̀gàn lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Edomu, Siria àti gbogbo agbègbè rẹ, àti lọ́dọ̀ àwọn ọmọbìnrin Filistini àti lọ́dọ̀ àwọn tó yí ọ ká, tiwọn si ń kẹ́gàn rẹ.
mbere ya waganu waku kũguũrio. O na kũrĩ ũguo-rĩ, rĩu ũrĩ mũnyarare nĩ airĩtu a Edomu, marĩ hamwe na andũ othe arĩa mariganĩtie nao, o na nĩ airĩtu a Afilisti, acio othe magũthũire na magakũrigiicĩria na mĩena yothe.
58 Èmi yóò gba ẹ̀san ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti àwọn iṣẹ́ ìríra rẹ ní Olúwa wí.’
Wee nĩwe ũgaacookererwo nĩ maciaro ma ũũra-thoni waku, na ma maũndũ marĩa wĩkaga marĩ magigi, ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
59 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, ‘Èmi yóò hùwà sí ọ gẹ́gẹ́ bi ó ṣe tọ́ sí ọ, nítorí ó ti kẹ́gàn ẹ̀jẹ́ nípa dídà májẹ̀mú.
“‘Ũũ nĩguo Mwathani Jehova ekuuga: Nĩngagwĩka o ta ũrĩa wagĩrĩire nĩ gwĩkwo, tondũ nĩũmenete mwĩhĩtwa wakwa na ũndũ wa gũthũkia kĩrĩkanĩro kĩu.
60 Síbẹ̀ èmi yóò rántí májẹ̀mú tí mo bá ọ ṣe nígbà èwe rẹ, èmi yóò sì bá ọ dá májẹ̀mú láéláé.
No rĩrĩ, nĩngaririkana kĩrĩkanĩro kĩrĩa ndarĩkanĩire nawe matukũ-inĩ ma ũnini waku, na nĩngahaanda kĩrĩkanĩro giitũ nawe gĩa gũtũũra.
61 Nígbà náà ni ìwọ yóò rántí àwọn ọ̀nà rẹ ojú yóò sì tì ọ́ nígbà tí mo bá gba àwọn ẹ̀gbọ́n àti àbúrò rẹ obìnrin padà. Fún ọ gẹ́gẹ́ bí ọmọbìnrin, ṣùgbọ́n kì í ṣe lórí májẹ̀mú tí mo bá ọ dá.
Hĩndĩ ĩyo nĩũkaririkana mĩthiĩre yaku, nawe ũconoke rĩrĩa ũkaamũkĩra aarĩ a maitũguo arĩa akũrũ gũgũkĩra na arĩa anini gũgũkĩra. Nĩngamaneana kũrĩ we marĩ ta aarĩ aku, no ti kũringana na kĩrĩkanĩro giitũ nawe.
62 Èmi yóò gbé májẹ̀mú mi kalẹ̀ pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì mọ pé èmi ni Olúwa.
Nĩ ũndũ ũcio nĩngahaanda kĩrĩkanĩro giitũ nawe, na nĩũkamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova.
63 Nígbà tí mo bá sì ti ṣe ètùtù fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ tan, Èmi yóò sì rántí, ojú yóò tì ọ́, ìwọ kò sì ní le ya ẹnu rẹ mọ́ nítorí ìtìjú rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.’”
Ningĩ rĩrĩa ngaakũhoroheria nĩ ũndũ wa maũndũ mothe marĩa wĩkĩte-rĩ, nĩũkaririkana na ũconoke, na ndũgacooka gũtumũra kanua gaku rĩngĩ nĩ ũndũ wa ũrĩa ũconorithĩtio, ũguo nĩguo Mwathani Jehova ekuuga.’”